Òwe 10
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àwọn òwe Solomoni
10 Àwọn òwe Solomoni:
ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn
ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè
ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
3 Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo
ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà,
ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.
5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ,
ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo
ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún
ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,
ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu
ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn
aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè
ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀,
ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye
ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ
ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn,
ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn
ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn
ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.
18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́
ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù
ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà
ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.
21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀
ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,
kì í sì í fi ìdààmú sí i.
23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú
ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;
Olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,
ṣùgbọ́n Olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú
bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,
ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀
ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.
29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo,
ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.
30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé
ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,
ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà,
ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.
Proverbs 10
New International Version
Proverbs of Solomon
10 The proverbs(A) of Solomon:(B)
A wise son brings joy to his father,(C)
but a foolish son brings grief to his mother.
5 He who gathers crops in summer is a prudent son,
but he who sleeps during harvest is a disgraceful son.(J)
8 The wise in heart accept commands,
but a chattering fool comes to ruin.(O)
9 Whoever walks in integrity(P) walks securely,(Q)
but whoever takes crooked paths will be found out.(R)
10 Whoever winks maliciously(S) causes grief,
and a chattering fool comes to ruin.
11 The mouth of the righteous is a fountain of life,(T)
but the mouth of the wicked conceals violence.(U)
12 Hatred stirs up conflict,
but love covers over all wrongs.(V)
13 Wisdom is found on the lips of the discerning,(W)
but a rod is for the back of one who has no sense.(X)
17 Whoever heeds discipline shows the way to life,(AE)
but whoever ignores correction leads others astray.
18 Whoever conceals hatred with lying lips(AF)
and spreads slander is a fool.
19 Sin is not ended by multiplying words,
but the prudent hold their tongues.(AG)
20 The tongue of the righteous is choice silver,
but the heart of the wicked is of little value.
21 The lips of the righteous nourish many,
but fools die for lack of sense.(AH)
23 A fool finds pleasure in wicked schemes,(AL)
but a person of understanding delights in wisdom.
28 The prospect of the righteous is joy,
but the hopes of the wicked come to nothing.(AV)
29 The way of the Lord is a refuge for the blameless,
but it is the ruin of those who do evil.(AW)
30 The righteous will never be uprooted,
but the wicked will not remain in the land.(AX)
Footnotes
- Proverbs 10:6 Or righteous, / but the mouth of the wicked conceals violence
- Proverbs 10:7 See Gen. 48:20.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.