Òwe 15
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
15 Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ yí ìbínú padà
ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ líle máa ń ru ìbínú sókè.
2 Ahọ́n ọlọ́gbọ́n a máa gbé ìmọ̀ jáde
ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń tú ọ̀rọ̀ ọ òmùgọ̀ jáde.
3 Ojú Olúwa wà níbi gbogbo,
Ó ń wo àwọn ẹni búburú àti àwọn ẹni rere.
4 Ahọ́n tí ń mú ìtura wá jẹ́ igi ìyè
ṣùgbọ́n ahọ́n ẹ̀tàn ń pa ẹ̀mí run.
5 Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀
ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
6 Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra,
ṣùgbọ́n èrè àwọn ènìyàn búburú ń mú ìyọnu wá fún wọn.
7 Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀;
ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ fún ọkàn aláìgbọ́n.
8 Olúwa kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburú
ṣùgbọ́n àdúrà olódodo tẹ́ ẹ lọ́rùn.
9 Olúwa kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
ṣùgbọ́n ó fẹ́ràn àwọn tí ń lépa òdodo.
10 Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an,
ẹni tí ó kórìíra ìbáwí yóò kú.
11 Ikú àti ìparun ṣí sílẹ̀ níwájú Olúwa,
mélòó mélòó ní nínú ọkàn àwọn ènìyàn.
12 Ẹlẹ́gàn kò fẹ́ ẹni tí ń ba wí:
kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.
13 Inú dídùn máa ń mú kí ojú túká
ṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.
14 Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀
ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.
15 Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi,
ṣùgbọ́n onínúdídùn ń jẹ àlàáfíà ní ìgbà gbogbo.
16 Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù Olúwa sì wà
ju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.
17 Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wà
sàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.
18 Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀
ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.
19 Ọ̀nà ọ̀lẹ ni ẹ̀gún dí,
ṣùgbọ́n ọ̀nà olódodo já geerege ni.
20 Ọlọ́gbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn,
ṣùgbọ́n aṣiwèrè ènìyàn kẹ́gàn ìyá rẹ̀.
21 Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀;
ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà.
22 Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn;
ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn wà.
23 Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó yẹ
ọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀!
24 Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọ́gbọ́n
láti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú.
25 Olúwa fa ilé onígbèéraga ya lulẹ̀,
ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó onírẹ̀lẹ̀ mọ́ láìyẹ̀.
26 Olúwa kórìíra èrò ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n mímọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹni pípé.
27 Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀
ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè.
28 Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò
ṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde.
29 Olúwa jìnnà sí ènìyàn búburú
ṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo.
30 Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn,
ìròyìn ayọ̀ sì ń mú ìlera wá sínú egungun.
31 Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè,
yóò wà ní àpéjọpọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n.
32 Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀,
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí yóò ní ìmọ̀ sí i.
33 Ìbẹ̀rù Olúwa kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n,
Ìrẹ̀lẹ̀ sì ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
Proverbs 15
New International Version
5 A fool spurns a parent’s discipline,
but whoever heeds correction shows prudence.(K)
6 The house of the righteous contains great treasure,(L)
but the income of the wicked brings ruin.(M)
7 The lips of the wise spread knowledge,(N)
but the hearts of fools are not upright.
10 Stern discipline awaits anyone who leaves the path;
the one who hates correction will die.(T)
12 Mockers resent correction,(W)
so they avoid the wise.
14 The discerning heart seeks knowledge,(Z)
but the mouth of a fool feeds on folly.
15 All the days of the oppressed are wretched,
but the cheerful heart has a continual feast.(AA)
16 Better a little with the fear of the Lord
than great wealth with turmoil.(AB)
17 Better a small serving of vegetables with love
than a fattened calf with hatred.(AC)
19 The way of the sluggard is blocked with thorns,(AF)
but the path of the upright is a highway.
20 A wise son brings joy to his father,(AG)
but a foolish man despises his mother.
21 Folly brings joy to one who has no sense,(AH)
but whoever has understanding keeps a straight course.
24 The path of life leads upward for the prudent
to keep them from going down to the realm of the dead.
25 The Lord tears down the house of the proud,(AN)
but he sets the widow’s boundary stones in place.(AO)
26 The Lord detests the thoughts(AP) of the wicked,(AQ)
but gracious words are pure(AR) in his sight.
27 The greedy bring ruin to their households,
but the one who hates bribes will live.(AS)
29 The Lord is far from the wicked,
but he hears the prayer of the righteous.(AV)
30 Light in a messenger’s eyes brings joy to the heart,
and good news gives health to the bones.(AW)
31 Whoever heeds life-giving correction
will be at home among the wise.(AX)
Footnotes
- Proverbs 15:11 Hebrew Abaddon
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.