Add parallel Print Page Options

19 Ó sàn kí ènìyàn jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ kò lábùkù ju aláìgbọ́n tí ètè rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà.

Kò dára láti ní ìtara láìní ìmọ̀ tàbí kí ènìyàn kánjú kí ó sì ṣìnà.

Ìwà òmùgọ̀ ènìyàn fúnrarẹ̀ a pa ẹ̀mí rẹ̀ run;
    síbẹ̀ ọkàn rẹ̀ yóò máa bínú sí Olúwa.

Ọrọ̀ máa ń fa ọ̀rẹ́ púpọ̀;
    ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ tálákà tún kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

Ajẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà, ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde kò ní lọ lọ́fẹ̀ẹ́.

Ọ̀pọ̀ ń wá ojúrere olórí;
    gbogbo ènìyàn sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ó lawọ́.

Gbogbo ará ilé e tálákà ni ó pa á tì
    mélòó mélòó ni ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí ń sá fún un!
    Bí ó tilẹ̀ ń lé wọn kiri pẹ̀lú ẹ̀bẹ̀,
    kò tilẹ̀ le rí wọn rárá.

Ẹni tí ó gba ọgbọ́n fẹ́ràn ọkàn ara rẹ̀;
    ẹni tí ó bá káràmáṣìkí òye yóò gbèrú.

Ajẹ́rìí èké kì yóò lọ láìjìyà
    ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde yóò parun.

10 Kò yẹ aláìgbọ́n láti máa gbé nínú ọláńlá,
    mélòó mélòó bí ó ti burú tó fún ẹrú láti jẹ ọba lórí ọmọ-aládé.

11 Ọgbọ́n ènìyàn a máa fún un ní sùúrù;
    fún ògo rẹ̀ ni láti fojú fo àṣìṣe dá.

12 Ìbínú ọba dàbí kíké e kìnnìún,
    ṣùgbọ́n ojúrere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko.

13 Aṣiwèrè ọmọ jẹ́ ìparun baba rẹ̀,
    Aya tí ó máa ń jà sì dàbí ọ̀ṣọ̀ọ̀rọ̀ òjò.

14 A máa ń jogún ilé àti ọrọ̀ lọ́dọ̀ òbí
    ṣùgbọ́n aya olóye láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni.

15 Ọ̀lẹ ṣíṣe máa ń fa oorun sísùn fọnfọn,
    ebi yóò sì máa pa ènìyàn tí ó lọ́ra.

16 Ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́ ẹ̀kọ́ pa ẹnu rẹ̀ mọ́
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kẹ́gàn ọ̀nà rẹ̀ yóò kú.

17 Ẹni tí ó ṣàánú tálákà, Olúwa ní ó yá
    yóò sì pín in lérè ohun tí ó ti ṣe.

18 Bá ọmọ rẹ wí nítorí nínú ìyẹn ni ìrètí wà;
    àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ lọ́wọ́ nínú ìparun un rẹ̀.

19 Ènìyàn onínú-fùfù gbọdọ̀ gba èrè ìwà rẹ̀
    bí ìwọ bá gbà á là, ìwọ yóò tún ní láti ṣe é lẹ́ẹ̀kan sí i.

20 Fetí sí ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́
    ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín ìwọ yóò di ọlọ́gbọ́n.

21 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ète inú ọkàn ènìyàn
    ṣùgbọ́n ìfẹ́ Olúwa ní ó máa ń borí.

22 Ohun tí ènìyàn ń fẹ́ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀;
    ó sàn láti jẹ́ tálákà ju òpùrọ́ lọ.

23 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ìyè wá:
    nígbà náà ọkàn ń balẹ̀, láìsí ewu.

24 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ;
    kò tilẹ̀ ní mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.

25 Na ẹlẹ́gàn, òpè yóò sì kọ́gbọ́n;
    bá olóye ènìyàn wí, yóò sì ní ìmọ̀ sí i.

26 Ẹni tí ó ṣìkà sí baba rẹ̀, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde
òun ni ọmọ tí ń ṣe ìtìjú, tí ó sì mú ẹ̀gàn wá.

27 Ọmọ mi, dẹ́kun láti tẹ́tí sí ẹ̀kọ́,
    tí í mú ni ṣìnà kúrò nínú ọ̀rọ̀-ìmọ̀.

28 Ẹlẹ́rìí búburú fi ìdájọ́ ṣẹ̀sín,
    ẹnu ènìyàn búburú sì ń gbé ibi mì.

29 A ti pèsè ìjìyà sílẹ̀ fún ẹlẹ́gàn;
    àti pàṣán fún ẹ̀yìn àwọn aṣiwèrè.

19 Better the poor whose walk is blameless
    than a fool whose lips are perverse.(A)

Desire without knowledge is not good—
    how much more will hasty feet miss the way!(B)

A person’s own folly(C) leads to their ruin,
    yet their heart rages against the Lord.(D)

Wealth attracts many friends,
    but even the closest friend of the poor person deserts them.(E)

A false witness(F) will not go unpunished,(G)
    and whoever pours out lies will not go free.(H)

Many curry favor with a ruler,(I)
    and everyone is the friend of one who gives gifts.(J)

The poor are shunned by all their relatives—
    how much more do their friends avoid them!(K)
Though the poor pursue them with pleading,
    they are nowhere to be found.[a](L)

The one who gets wisdom loves life;
    the one who cherishes understanding will soon prosper.(M)

A false witness will not go unpunished,
    and whoever pours out lies will perish.(N)

10 It is not fitting for a fool(O) to live in luxury—
    how much worse for a slave to rule over princes!(P)

11 A person’s wisdom yields patience;(Q)
    it is to one’s glory to overlook an offense.

12 A king’s rage is like the roar of a lion,(R)
    but his favor is like dew(S) on the grass.(T)

13 A foolish child is a father’s ruin,(U)
    and a quarrelsome wife is like
    the constant dripping of a leaky roof.(V)

14 Houses and wealth are inherited from parents,(W)
    but a prudent wife is from the Lord.(X)

15 Laziness brings on deep sleep,
    and the shiftless go hungry.(Y)

16 Whoever keeps commandments keeps their life,
    but whoever shows contempt for their ways will die.(Z)

17 Whoever is kind to the poor lends to the Lord,(AA)
    and he will reward them for what they have done.(AB)

18 Discipline your children, for in that there is hope;
    do not be a willing party to their death.(AC)

19 A hot-tempered person must pay the penalty;
    rescue them, and you will have to do it again.

20 Listen to advice and accept discipline,(AD)
    and at the end you will be counted among the wise.(AE)

21 Many are the plans in a person’s heart,
    but it is the Lord’s purpose that prevails.(AF)

22 What a person desires is unfailing love[b];
    better to be poor than a liar.

23 The fear of the Lord leads to life;
    then one rests content, untouched by trouble.(AG)

24 A sluggard buries his hand in the dish;
    he will not even bring it back to his mouth!(AH)

25 Flog a mocker, and the simple will learn prudence;
    rebuke the discerning,(AI) and they will gain knowledge.(AJ)

26 Whoever robs their father and drives out their mother(AK)
    is a child who brings shame and disgrace.

27 Stop listening to instruction, my son,(AL)
    and you will stray from the words of knowledge.

28 A corrupt witness mocks at justice,
    and the mouth of the wicked gulps down evil.(AM)

29 Penalties are prepared for mockers,
    and beatings for the backs of fools.(AN)

Footnotes

  1. Proverbs 19:7 The meaning of the Hebrew for this sentence is uncertain.
  2. Proverbs 19:22 Or Greed is a person’s shame