Add parallel Print Page Options

Èrè ìwà rere tí ọgbọ́n ń mú wá

Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,
    tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n
    tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn,
    tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà
    tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa,
    ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,
    láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,
    Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́
    Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.

Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́,
    àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ
    ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́
    òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.

12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
    lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin
    láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú,
    tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́
    tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.

16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin,
    àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀
    tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú
    ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.

20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere
    kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà
    àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà
    a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

Moral Benefits of Wisdom

My son,(A) if you accept my words
    and store up my commands within you,
turning your ear to wisdom
    and applying your heart to understanding(B)
indeed, if you call out for insight(C)
    and cry aloud for understanding,
and if you look for it as for silver
    and search for it as for hidden treasure,(D)
then you will understand the fear of the Lord
    and find the knowledge of God.(E)
For the Lord gives wisdom;(F)
    from his mouth come knowledge and understanding.(G)
He holds success in store for the upright,
    he is a shield(H) to those whose walk is blameless,(I)
for he guards the course of the just
    and protects the way of his faithful ones.(J)

Then you will understand(K) what is right and just
    and fair—every good path.
10 For wisdom will enter your heart,(L)
    and knowledge will be pleasant to your soul.
11 Discretion will protect you,
    and understanding will guard you.(M)

12 Wisdom will save(N) you from the ways of wicked men,
    from men whose words are perverse,
13 who have left the straight paths
    to walk in dark ways,(O)
14 who delight in doing wrong
    and rejoice in the perverseness of evil,(P)
15 whose paths are crooked(Q)
    and who are devious in their ways.(R)

16 Wisdom will save you also from the adulterous woman,(S)
    from the wayward woman with her seductive words,
17 who has left the partner of her youth
    and ignored the covenant she made before God.[a](T)
18 Surely her house leads down to death
    and her paths to the spirits of the dead.(U)
19 None who go to her return
    or attain the paths of life.(V)

20 Thus you will walk in the ways of the good
    and keep to the paths of the righteous.
21 For the upright will live in the land,(W)
    and the blameless will remain in it;
22 but the wicked(X) will be cut off from the land,(Y)
    and the unfaithful will be torn from it.(Z)

Footnotes

  1. Proverbs 2:17 Or covenant of her God