Òwe 23
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ohun àdídùn
23 Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun,
kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
2 Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun,
bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
3 Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀:
nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
4 Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀:
ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
5 Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí?
Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀,
ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.
6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́,
bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
7 Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí:
“Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ;
ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
8 Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde,
ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.
9 Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè;
nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.
10 Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò;
má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
11 Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára;
yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.
12 Fi àyà sí ẹ̀kọ́,
àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
13 Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé,
nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
14 Bí ìwọ fi pàṣán nà án,
ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì.
Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n fún ọmọ rere
15 Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n,
ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
16 Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.
17 Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,
ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa,
ní ọjọ́ gbogbo.
18 Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́;
ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.
19 Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,
kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
20 Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí;
àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
21 Nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà;
ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.
22 Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ,
má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó
23 Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á;
ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
24 Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi:
ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n,
yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
25 Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀,
sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.
26 Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi,
kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
27 Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni;
àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
28 Òun á sì ba ní bùba bí olè,
a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.
29 Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́?
Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
30 Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì;
àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
31 Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n,
nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago,
tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
32 Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò,
a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
33 Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin,
àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
34 Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun,
tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
35 Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí;
wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀:
nígbà wo ni èmi ó jí?
Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”
Proverbs 23
New International Version
Saying 7
23 When you sit to dine with a ruler,
note well what[a] is before you,
2 and put a knife to your throat
if you are given to gluttony.
3 Do not crave his delicacies,(A)
for that food is deceptive.
Saying 8
4 Do not wear yourself out to get rich;
do not trust your own cleverness.
5 Cast but a glance at riches, and they are gone,(B)
for they will surely sprout wings
and fly off to the sky like an eagle.(C)
Saying 9
6 Do not eat the food of a begrudging host,
do not crave his delicacies;(D)
7 for he is the kind of person
who is always thinking about the cost.[b]
“Eat and drink,” he says to you,
but his heart is not with you.
8 You will vomit up the little you have eaten
and will have wasted your compliments.
Saying 10
9 Do not speak to fools,
for they will scorn your prudent words.(E)
Saying 11
10 Do not move an ancient boundary stone(F)
or encroach on the fields of the fatherless,
11 for their Defender(G) is strong;(H)
he will take up their case against you.(I)
Saying 12
12 Apply your heart to instruction(J)
and your ears to words of knowledge.
Saying 13
13 Do not withhold discipline from a child;
if you punish them with the rod, they will not die.
14 Punish them with the rod
and save them from death.(K)
Saying 14
15 My son, if your heart is wise,
then my heart will be glad indeed;
16 my inmost being will rejoice
when your lips speak what is right.(L)
Saying 15
17 Do not let your heart envy(M) sinners,
but always be zealous for the fear of the Lord.
18 There is surely a future hope for you,
and your hope will not be cut off.(N)
Saying 16
19 Listen, my son,(O) and be wise,
and set your heart on the right path:
20 Do not join those who drink too much wine(P)
or gorge themselves on meat,
21 for drunkards and gluttons become poor,(Q)
and drowsiness clothes them in rags.
Saying 17
22 Listen to your father, who gave you life,
and do not despise your mother when she is old.(R)
23 Buy the truth and do not sell it—
wisdom, instruction and insight as well.(S)
24 The father of a righteous child has great joy;
a man who fathers a wise son rejoices in him.(T)
25 May your father and mother rejoice;
may she who gave you birth be joyful!(U)
Saying 18
26 My son,(V) give me your heart
and let your eyes delight in my ways,(W)
27 for an adulterous woman is a deep pit,(X)
and a wayward wife is a narrow well.
28 Like a bandit she lies in wait(Y)
and multiplies the unfaithful among men.
Saying 19
29 Who has woe? Who has sorrow?
Who has strife? Who has complaints?
Who has needless bruises? Who has bloodshot eyes?
30 Those who linger over wine,(Z)
who go to sample bowls of mixed wine.
31 Do not gaze at wine when it is red,
when it sparkles in the cup,
when it goes down smoothly!
32 In the end it bites like a snake
and poisons like a viper.
33 Your eyes will see strange sights,
and your mind will imagine confusing things.
34 You will be like one sleeping on the high seas,
lying on top of the rigging.
35 “They hit me,” you will say, “but I’m not hurt!
They beat me, but I don’t feel it!
When will I wake up
so I can find another drink?”(AA)
Footnotes
- Proverbs 23:1 Or who
- Proverbs 23:7 Or for as he thinks within himself, / so he is; or for as he puts on a feast, / so he is
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.