Òwe 28
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
28 Ènìyàn búburú ń sá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnìkan kò lé e
ṣùgbọ́n olódodo láyà bí i kìnnìún.
2 Nígbà tí orílẹ̀-èdè bá ní orí kunkun, àwọn ọba rẹ̀ a máa pọ̀,
ṣùgbọ́n olóye àti onímọ̀ a máa pa òfin mọ́.
3 Ọba tí ó ni àwọn tálákà lára
dàbí àgbàrá òjò tí ó ń gbá gbogbo ọ̀gbìn lọ.
4 Àwọn tí ó kọ òfin sílẹ̀ a máa gbóríyìn fún ènìyàn búburú
ṣùgbọ́n àwọn tí ó pa òfin mọ́ kọjú ìjà sí ènìyàn búburú.
5 Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn ẹni ibi
ṣùgbọ́n ó yé àwọn tí ń wá Olúwa dáradára.
6 Ó sàn láti jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ jẹ́ aláìlábùkù
ju ọlọ́rọ̀ tí ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla.
7 Ẹni tí ó pa òfin mọ́ jẹ́ olóye ọmọ
ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ẹ́ jẹgúdújẹrá kẹ́gbẹ́ dójútì baba rẹ̀.
8 Ẹni tí ó mú ọrọ̀ rẹ̀ di púpọ̀ nípa èrè àjẹjù
ń kó jọ fún ẹlòmíràn, tí yóò ní àánú àwọn tálákà.
9 Bí ẹnikẹ́ni bá kọ etí ikún sí òfin,
kódà àdúrà rẹ̀ jẹ́ ìríra.
10 Ẹni tí ó mú olódodo rìn ọ̀nà búburú
yóò bọ́ sínú pàkúté ara rẹ̀
ṣùgbọ́n aláìlẹ́gàn yóò gba ogún rere.
11 Ọlọ́rọ̀ ènìyàn le è gbọ́n lójú ara rẹ̀
ṣùgbọ́n tálákà tí ó ní òye rí ìdí, rẹ̀.
12 Nígbà tí olódodo ń lékè ariwo ayọ̀ ta;
ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú gorí òye, àwọn ènìyàn a na pápá bora.
13 Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì yóò ṣe rere,
ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀ máa ń rí àánú gbà.
14 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run nígbà gbogbo
ṣùgbọ́n ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le bọ́ sínú wàhálà.
15 Bí kìnnìún tí ń ké tàbí Beari tí ń halẹ̀
ni ènìyàn búburú tí ń jẹ ọba lórí àwọn aláìlágbára.
16 Ọmọ-aládé tí ó ṣe aláìmòye púpọ̀ ní ń ṣe ìwà ìkà púpọ̀ pẹ̀lú,
ṣùgbọ́n èyí tí ó kórìíra ojúkòkòrò yóò mún ọjọ́ rẹ̀ pẹ́.
17 Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyàn
yóò máa joró rẹ̀ títí ikú
má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.
18 Ẹni tí ń rìn déédéé ní yóò là,
ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà ni yóò ṣubú lójijì.
19 Ẹni tí ó bá ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ lọ́pọ̀lọpọ̀
ṣùgbọ́n ẹni tí ń lé ohun asán yóò kún fún òsì.
20 Olóòtítọ́ ènìyàn yóò rí ìbùkún gbà gan an
ṣùgbọ́n ẹni tí ojú ń kán láti di ọlọ́rọ̀ kì yóò lọ láìjìyà.
21 Ojúsàájú ṣíṣe kò dára,
síbẹ̀ ènìyàn kan ń ṣẹ̀ nítorí òkèlè oúnjẹ kan.
22 Ahun ń sáré àti là
kò sì funra pé òsì dúró de òun.
23 Ẹni tí ó bá ènìyàn kan wí yóò rí ojúrere ni nígbẹ̀yìn
ju ẹni tí ó ní ètè ẹ̀tàn lọ.
24 Ẹni tí ó ja baba tàbí ìyá rẹ̀ lólè
tí ó sì wí pé “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”
irú kan ni òun àti ẹni tí ń pa ni run.
25 Ọ̀kánjúwà ènìyàn a máa dá ìjà sílẹ̀,
ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò gbilẹ̀.
26 Ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀ jẹ́ aláìgbọ́n
ṣùgbọ́n ẹni tí ń rìn nínú ọgbọ́n wà láìléwu.
27 Ẹni tí ó ń fi fún tálákà kì yóò ṣe aláìní ohunkóhun,
ṣùgbọ́n ẹni tí ó di ojú rẹ̀ sí wọn gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ègún.
28 Nígbà tí ènìyàn búburú bá dórí ìjọba, àwọn ènìyàn a na pápá bora;
ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú bá ṣègbé,
àwọn olódodo ń gbilẹ̀ sí i.
Proverbs 28
New International Version
2 When a country is rebellious, it has many rulers,
but a ruler with discernment and knowledge maintains order.
3 A ruler[a] who oppresses the poor
is like a driving rain that leaves no crops.
4 Those who forsake instruction praise the wicked,
but those who heed it resist them.
5 Evildoers do not understand what is right,
but those who seek the Lord understand it fully.
6 Better the poor whose walk is blameless
than the rich whose ways are perverse.(D)
7 A discerning son heeds instruction,
but a companion of gluttons disgraces his father.(E)
8 Whoever increases wealth by taking interest(F) or profit from the poor
amasses it for another,(G) who will be kind to the poor.(H)
9 If anyone turns a deaf ear to my instruction,
even their prayers are detestable.(I)
10 Whoever leads the upright along an evil path
will fall into their own trap,(J)
but the blameless will receive a good inheritance.
11 The rich are wise in their own eyes;
one who is poor and discerning sees how deluded they are.
12 When the righteous triumph, there is great elation;(K)
but when the wicked rise to power, people go into hiding.(L)
13 Whoever conceals their sins(M) does not prosper,
but the one who confesses(N) and renounces them finds mercy.(O)
14 Blessed is the one who always trembles before God,
but whoever hardens their heart falls into trouble.
15 Like a roaring lion or a charging bear
is a wicked ruler over a helpless people.
16 A tyrannical ruler practices extortion,
but one who hates ill-gotten gain will enjoy a long reign.
17 Anyone tormented by the guilt of murder
will seek refuge(P) in the grave;
let no one hold them back.
18 The one whose walk is blameless is kept safe,(Q)
but the one whose ways are perverse will fall(R) into the pit.[b]
19 Those who work their land will have abundant food,
but those who chase fantasies will have their fill of poverty.(S)
20 A faithful person will be richly blessed,
but one eager to get rich will not go unpunished.(T)
22 The stingy are eager to get rich
and are unaware that poverty awaits them.(X)
23 Whoever rebukes a person will in the end gain favor
rather than one who has a flattering tongue.(Y)
24 Whoever robs their father or mother(Z)
and says, “It’s not wrong,”
is partner to one who destroys.(AA)
27 Those who give to the poor will lack nothing,(AF)
but those who close their eyes to them receive many curses.(AG)
28 When the wicked rise to power, people go into hiding;(AH)
but when the wicked perish, the righteous thrive.
Footnotes
- Proverbs 28:3 Or A poor person
- Proverbs 28:18 Syriac (see Septuagint); Hebrew into one
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.