Òwe 29
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
29 Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí
yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
2 Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀
nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.
3 Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀
ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.
4 Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,
ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀
ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.
6 Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀
ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.
7 Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà,
ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.
8 Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè,
ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.
9 Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n
aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.
10 Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin
wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.
11 Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú
ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.
12 Bí olórí bá fetí sí irọ́,
gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.
13 Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí,
Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.
14 Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́
ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.
15 Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n
ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnrarẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.
16 Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀
ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.
17 Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà
yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.
18 Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà,
ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.
19 A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́
bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.
20 Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀?
Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.
21 Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré
yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.
22 Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè,
onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.
23 Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀
ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.
24 Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀,
ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.
25 Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn
ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso,
ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.
27 Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́:
ènìyàn búburú kórìíra olódodo.
Proverbs 29
New International Version
29 Whoever remains stiff-necked(A) after many rebukes
will suddenly be destroyed(B)—without remedy.(C)
3 A man who loves wisdom brings joy to his father,(G)
but a companion of prostitutes squanders his wealth.(H)
4 By justice a king gives a country stability,(I)
but those who are greedy for[a] bribes tear it down.
5 Those who flatter their neighbors
are spreading nets for their feet.(J)
6 Evildoers are snared by their own sin,(K)
but the righteous shout for joy and are glad.
7 The righteous care about justice for the poor,(L)
but the wicked have no such concern.
8 Mockers stir up a city,
but the wise turn away anger.(M)
9 If a wise person goes to court with a fool,
the fool rages and scoffs, and there is no peace.
10 The bloodthirsty hate a person of integrity
and seek to kill the upright.(N)
13 The poor and the oppressor have this in common:
The Lord gives sight to the eyes of both.(S)
14 If a king judges the poor with fairness,
his throne will be established forever.(T)
15 A rod and a reprimand impart wisdom,
but a child left undisciplined disgraces its mother.(U)
16 When the wicked thrive, so does sin,
but the righteous will see their downfall.(V)
17 Discipline your children, and they will give you peace;
they will bring you the delights you desire.(W)
18 Where there is no revelation, people cast off restraint;
but blessed is the one who heeds wisdom’s instruction.(X)
19 Servants cannot be corrected by mere words;
though they understand, they will not respond.
20 Do you see someone who speaks in haste?
There is more hope for a fool than for them.(Y)
21 A servant pampered from youth
will turn out to be insolent.
22 An angry person stirs up conflict,
and a hot-tempered person commits many sins.(Z)
24 The accomplices of thieves are their own enemies;
they are put under oath and dare not testify.(AC)
27 The righteous detest the dishonest;
the wicked detest the upright.(AI)
Footnotes
- Proverbs 29:4 Or who give
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.