Add parallel Print Page Options

Àwọn àǹfààní ọgbọ́n mìíràn

Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.
    Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,
    ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.

Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé
    so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,
    kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
(A)Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere
    ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.

Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ
    má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ;
Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ
    òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.

(B)Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ
    bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ
    àti okun fún àwọn egungun rẹ.

Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,
    pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ
10 Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya
    àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

11 (C)Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa
    má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
12 Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí
    bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,
    ẹni tí ó tún ní òye sí i
14 Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ
    ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;
    kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;
    ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura,
    òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á;
    àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.

19 Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
20 Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà,
    àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.

21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́,
    má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ,
    àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu,
    ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀;
24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù,
    nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì,
    tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
26 Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ,
    kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.

27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ,
    nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,
    “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,”
    nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,
    ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí,
    nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.

31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan
    tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

32 Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà
    ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
33 Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,
    ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
34 (D)Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́,
    ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì,
    ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.

Wisdom Bestows Well-Being

My son,(A) do not forget my teaching,(B)
    but keep my commands in your heart,
for they will prolong your life many years(C)
    and bring you peace and prosperity.(D)

Let love and faithfulness(E) never leave you;
    bind them around your neck,
    write them on the tablet of your heart.(F)
Then you will win favor and a good name
    in the sight of God and man.(G)

Trust in the Lord(H) with all your heart
    and lean not on your own understanding;
in all your ways submit to him,
    and he will make your paths(I) straight.[a](J)

Do not be wise in your own eyes;(K)
    fear the Lord(L) and shun evil.(M)
This will bring health to your body(N)
    and nourishment to your bones.(O)

Honor the Lord with your wealth,
    with the firstfruits(P) of all your crops;
10 then your barns will be filled(Q) to overflowing,
    and your vats will brim over with new wine.(R)

11 My son,(S) do not despise the Lord’s discipline,(T)
    and do not resent his rebuke,
12 because the Lord disciplines those he loves,(U)
    as a father the son he delights in.[b](V)

13 Blessed are those who find wisdom,
    those who gain understanding,
14 for she is more profitable than silver
    and yields better returns than gold.(W)
15 She is more precious than rubies;(X)
    nothing you desire can compare with her.(Y)
16 Long life is in her right hand;(Z)
    in her left hand are riches and honor.(AA)
17 Her ways are pleasant ways,
    and all her paths are peace.(AB)
18 She is a tree of life(AC) to those who take hold of her;
    those who hold her fast will be blessed.(AD)

19 By wisdom(AE) the Lord laid the earth’s foundations,(AF)
    by understanding he set the heavens(AG) in place;
20 by his knowledge the watery depths were divided,
    and the clouds let drop the dew.

21 My son,(AH) do not let wisdom and understanding out of your sight,(AI)
    preserve sound judgment and discretion;
22 they will be life for you,(AJ)
    an ornament to grace your neck.(AK)
23 Then you will go on your way in safety,(AL)
    and your foot will not stumble.(AM)
24 When you lie down,(AN) you will not be afraid;(AO)
    when you lie down, your sleep(AP) will be sweet.
25 Have no fear of sudden disaster
    or of the ruin that overtakes the wicked,
26 for the Lord will be at your side(AQ)
    and will keep your foot(AR) from being snared.(AS)

27 Do not withhold good from those to whom it is due,
    when it is in your power to act.
28 Do not say to your neighbor,
    “Come back tomorrow and I’ll give it to you”—
    when you already have it with you.(AT)
29 Do not plot harm against your neighbor,
    who lives trustfully near you.(AU)
30 Do not accuse anyone for no reason—
    when they have done you no harm.

31 Do not envy(AV) the violent
    or choose any of their ways.

32 For the Lord detests the perverse(AW)
    but takes the upright into his confidence.(AX)
33 The Lord’s curse(AY) is on the house of the wicked,(AZ)
    but he blesses the home of the righteous.(BA)
34 He mocks(BB) proud mockers(BC)
    but shows favor to the humble(BD) and oppressed.
35 The wise inherit honor,
    but fools get only shame.

Footnotes

  1. Proverbs 3:6 Or will direct your paths
  2. Proverbs 3:12 Hebrew; Septuagint loves, / and he chastens everyone he accepts as his child

My son, forget not my law; but let thine heart keep my commandments:

For length of days, and long life, and peace, shall they add to thee.

Let not mercy and truth forsake thee: bind them about thy neck; write them upon the table of thine heart:

So shalt thou find favour and good understanding in the sight of God and man.

Trust in the Lord with all thine heart; and lean not unto thine own understanding.

In all thy ways acknowledge him, and he shall direct thy paths.

Be not wise in thine own eyes: fear the Lord, and depart from evil.

It shall be health to thy navel, and marrow to thy bones.

Honour the Lord with thy substance, and with the firstfruits of all thine increase:

10 So shall thy barns be filled with plenty, and thy presses shall burst out with new wine.

11 My son, despise not the chastening of the Lord; neither be weary of his correction:

12 For whom the Lord loveth he correcteth; even as a father the son in whom he delighteth.

13 Happy is the man that findeth wisdom, and the man that getteth understanding.

14 For the merchandise of it is better than the merchandise of silver, and the gain thereof than fine gold.

15 She is more precious than rubies: and all the things thou canst desire are not to be compared unto her.

16 Length of days is in her right hand; and in her left hand riches and honour.

17 Her ways are ways of pleasantness, and all her paths are peace.

18 She is a tree of life to them that lay hold upon her: and happy is every one that retaineth her.

19 The Lord by wisdom hath founded the earth; by understanding hath he established the heavens.

20 By his knowledge the depths are broken up, and the clouds drop down the dew.

21 My son, let not them depart from thine eyes: keep sound wisdom and discretion:

22 So shall they be life unto thy soul, and grace to thy neck.

23 Then shalt thou walk in thy way safely, and thy foot shall not stumble.

24 When thou liest down, thou shalt not be afraid: yea, thou shalt lie down, and thy sleep shall be sweet.

25 Be not afraid of sudden fear, neither of the desolation of the wicked, when it cometh.

26 For the Lord shall be thy confidence, and shall keep thy foot from being taken.

27 Withhold not good from them to whom it is due, when it is in the power of thine hand to do it.

28 Say not unto thy neighbour, Go, and come again, and to morrow I will give; when thou hast it by thee.

29 Devise not evil against thy neighbour, seeing he dwelleth securely by thee.

30 Strive not with a man without cause, if he have done thee no harm.

31 Envy thou not the oppressor, and choose none of his ways.

32 For the froward is abomination to the Lord: but his secret is with the righteous.

33 The curse of the Lord is in the house of the wicked: but he blesseth the habitation of the just.

34 Surely he scorneth the scorners: but he giveth grace unto the lowly.

35 The wise shall inherit glory: but shame shall be the promotion of fools.