Òwe 6
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìkìlọ̀ láti ṣọ́ra fún ìwà òmùgọ̀
6 Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,
bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
2 bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,
tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté,
3 Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ
níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ:
lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀;
bẹ aládùúgbò rẹ dáradára
4 Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,
tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
5 Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,
bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
6 Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ
kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
7 Kò ní olùdarí,
kò sí alábojútó tàbí ọba,
8 síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò
yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
9 Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?
Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀
11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà
àti àìní bí adigunjalè.
12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,
tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,
ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀
ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀
ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;
yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,
ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i:
17 Ojú ìgbéraga,
Ahọ́n tó ń parọ́
ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
18 ọkàn tí ń pète ohun búburú,
ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
19 Ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu
àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
Ìkìlọ̀ nítorí àgbèrè
20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́
má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé
so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ
22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;
nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ;
nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,
ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,
àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí
ni ọ̀nà sí ìyè.
24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,
kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ
tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,
ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan
kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?
Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;
kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè
nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje
bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;
ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni
33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,
ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,
kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;
yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.
Proverbs 6
New International Version
Warnings Against Folly
6 My son,(A) if you have put up security(B) for your neighbor,(C)
if you have shaken hands in pledge(D) for a stranger,
2 you have been trapped by what you said,
ensnared by the words of your mouth.
3 So do this, my son, to free yourself,
since you have fallen into your neighbor’s hands:
Go—to the point of exhaustion—[a]
and give your neighbor no rest!
4 Allow no sleep to your eyes,
no slumber to your eyelids.(E)
5 Free yourself, like a gazelle(F) from the hand of the hunter,(G)
like a bird from the snare of the fowler.(H)
6 Go to the ant, you sluggard;(I)
consider its ways and be wise!
7 It has no commander,
no overseer or ruler,
8 yet it stores its provisions in summer(J)
and gathers its food at harvest.(K)
9 How long will you lie there, you sluggard?(L)
When will you get up from your sleep?
10 A little sleep, a little slumber,
a little folding of the hands to rest(M)—
11 and poverty(N) will come on you like a thief
and scarcity like an armed man.
12 A troublemaker and a villain,
who goes about with a corrupt mouth,
13 who winks maliciously with his eye,(O)
signals with his feet
and motions with his fingers,(P)
14 who plots evil(Q) with deceit in his heart—
he always stirs up conflict.(R)
15 Therefore disaster will overtake him in an instant;(S)
he will suddenly(T) be destroyed—without remedy.(U)
16 There are six things the Lord hates,(V)
seven that are detestable to him:
17 haughty eyes,(W)
a lying tongue,(X)
hands that shed innocent blood,(Y)
18 a heart that devises wicked schemes,
feet that are quick to rush into evil,(Z)
19 a false witness(AA) who pours out lies(AB)
and a person who stirs up conflict in the community.(AC)
Warning Against Adultery
20 My son,(AD) keep your father’s command
and do not forsake your mother’s teaching.(AE)
21 Bind them always on your heart;
fasten them around your neck.(AF)
22 When you walk, they will guide you;
when you sleep, they will watch over you;
when you awake, they will speak to you.
23 For this command is a lamp,
this teaching is a light,(AG)
and correction and instruction
are the way to life,(AH)
24 keeping you from your neighbor’s wife,
from the smooth talk of a wayward woman.(AI)
25 Do not lust in your heart after her beauty
or let her captivate you with her eyes.
26 For a prostitute can be had for a loaf of bread,
but another man’s wife preys on your very life.(AJ)
27 Can a man scoop fire into his lap
without his clothes being burned?
28 Can a man walk on hot coals
without his feet being scorched?
29 So is he who sleeps(AK) with another man’s wife;(AL)
no one who touches her will go unpunished.
30 People do not despise a thief if he steals
to satisfy his hunger when he is starving.
31 Yet if he is caught, he must pay sevenfold,(AM)
though it costs him all the wealth of his house.
32 But a man who commits adultery(AN) has no sense;(AO)
whoever does so destroys himself.
33 Blows and disgrace are his lot,
and his shame will never(AP) be wiped away.
Footnotes
- Proverbs 6:3 Or Go and humble yourself,
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.