Add parallel Print Page Options

Ọgbọ́n n fi ìpè síta

(A)Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta?
    Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà
    ní ìkóríta, ní ó dúró;
Ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú,
    ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè;
    Mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn,
Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n;
    ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye;
    Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
Ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́,
    nítorí ètè mi kórìíra ibi.
Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́,
    kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀
Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà;
    wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà,
    ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
11 Nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ,
    kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.

12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye;
    mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi
    mo kórìíra ìgbéraga àti agídí,
    ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi
    mo ní òye àti agbára.
15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso
    tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára
16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso
    àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi
    àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà
    ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ;
    ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,
    ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
21 Mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi
    mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.

22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀.
    Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
23 A ti yàn mí láti ayérayé,
    láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi
    nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn,
    ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀
    tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn,
    nígbà tí ó fi òṣùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
28 Nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè
    tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
29 Nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun
    kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀,
    àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀
    mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́,
    mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá
    mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.

32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi,
    ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́,
33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n;
    má ṣe pa á tì sápá kan.
34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi,
    tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́,
    tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè
    ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára
    gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”

Wisdom’s Call

Does not wisdom call out?(A)
    Does not understanding raise her voice?
At the highest point along the way,
    where the paths meet, she takes her stand;
beside the gate leading into the city,
    at the entrance, she cries aloud:(B)
“To you, O people, I call out;(C)
    I raise my voice to all mankind.
You who are simple,(D) gain prudence;(E)
    you who are foolish, set your hearts on it.[a]
Listen, for I have trustworthy things to say;
    I open my lips to speak what is right.
My mouth speaks what is true,(F)
    for my lips detest wickedness.
All the words of my mouth are just;
    none of them is crooked or perverse.
To the discerning all of them are right;
    they are upright to those who have found knowledge.
10 Choose my instruction instead of silver,
    knowledge rather than choice gold,(G)
11 for wisdom is more precious(H) than rubies,
    and nothing you desire can compare with her.(I)

12 “I, wisdom, dwell together with prudence;
    I possess knowledge and discretion.(J)
13 To fear the Lord(K) is to hate evil;(L)
    I hate(M) pride and arrogance,
    evil behavior and perverse speech.
14 Counsel and sound judgment are mine;
    I have insight, I have power.(N)
15 By me kings reign
    and rulers(O) issue decrees that are just;
16 by me princes govern,(P)
    and nobles—all who rule on earth.[b]
17 I love those who love me,(Q)
    and those who seek me find me.(R)
18 With me are riches and honor,(S)
    enduring wealth and prosperity.(T)
19 My fruit is better than fine gold;(U)
    what I yield surpasses choice silver.(V)
20 I walk in the way of righteousness,(W)
    along the paths of justice,
21 bestowing a rich inheritance on those who love me
    and making their treasuries full.(X)

22 “The Lord brought me forth as the first of his works,[c][d]
    before his deeds of old;
23 I was formed long ages ago,
    at the very beginning, when the world came to be.
24 When there were no watery depths, I was given birth,
    when there were no springs overflowing with water;(Y)
25 before the mountains were settled in place,(Z)
    before the hills, I was given birth,(AA)
26 before he made the world or its fields
    or any of the dust of the earth.(AB)
27 I was there when he set the heavens in place,(AC)
    when he marked out the horizon(AD) on the face of the deep,
28 when he established the clouds above(AE)
    and fixed securely the fountains of the deep,(AF)
29 when he gave the sea its boundary(AG)
    so the waters would not overstep his command,(AH)
and when he marked out the foundations of the earth.(AI)
30     Then I was constantly[e] at his side.(AJ)
I was filled with delight day after day,
    rejoicing always in his presence,
31 rejoicing in his whole world
    and delighting in mankind.(AK)

32 “Now then, my children, listen(AL) to me;
    blessed are(AM) those who keep my ways.(AN)
33 Listen to my instruction and be wise;
    do not disregard it.
34 Blessed are those who listen(AO) to me,
    watching daily at my doors,
    waiting at my doorway.
35 For those who find me(AP) find life(AQ)
    and receive favor from the Lord.(AR)
36 But those who fail to find me harm themselves;(AS)
    all who hate me love death.”(AT)

Footnotes

  1. Proverbs 8:5 Septuagint; Hebrew foolish, instruct your minds
  2. Proverbs 8:16 Some Hebrew manuscripts and Septuagint; other Hebrew manuscripts all righteous rulers
  3. Proverbs 8:22 Or way; or dominion
  4. Proverbs 8:22 Or The Lord possessed me at the beginning of his work; or The Lord brought me forth at the beginning of his work
  5. Proverbs 8:30 Or was the artisan; or was a little child