Add parallel Print Page Options

Àwọn àǹfààní ọgbọ́n mìíràn

Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.
    Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,
    ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.

Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé
    so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,
    kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
(A)Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere
    ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.

Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ
    má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ;
Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ
    òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.

(B)Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ
    bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ
    àti okun fún àwọn egungun rẹ.

Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,
    pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ
10 Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya
    àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

11 (C)Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa
    má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
12 Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí
    bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,
    ẹni tí ó tún ní òye sí i
14 Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ
    ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;
    kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;
    ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura,
    òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á;
    àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.

19 Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
20 Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà,
    àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.

21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́,
    má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ,
    àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu,
    ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀;
24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù,
    nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì,
    tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
26 Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ,
    kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.

27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ,
    nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,
    “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,”
    nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,
    ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí,
    nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.

31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan
    tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

32 Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà
    ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
33 Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,
    ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
34 (D)Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́,
    ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì,
    ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.