Add parallel Print Page Options

Ìkìlọ̀ láti ṣọ́ra fún ìwà òmùgọ̀

Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,
    bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,
    tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté,
Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ
    níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ:
lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀;
    bẹ aládùúgbò rẹ dáradára
Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,
    tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,
    bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.

Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ
    kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
Kò ní olùdarí,
    kò sí alábojútó tàbí ọba,
síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò
    yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.

Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?
    Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
    ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀
11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà
    àti àìní bí adigunjalè.

12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,
    tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,
    ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀
    ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀
    ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;
    yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,

ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i:

17 Ojú ìgbéraga,

Ahọ́n tó ń parọ́

ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,

18 ọkàn tí ń pète ohun búburú,

ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,

19 Ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu

àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.

Ìkìlọ̀ nítorí àgbèrè

20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́
    má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé
    so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ
22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;
    nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ;
    nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,
    ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,
    àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí
    ni ọ̀nà sí ìyè.
24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,
    kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.

25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ
    tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.

26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,
    ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan
    kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?
    Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;
    kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.

30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè
    nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje
    bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;
    ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni
33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,
    ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.

34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,
    kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;
    yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.