Add parallel Print Page Options

Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú
    pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn
    nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí mi
    síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó
    ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká
    pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,
    bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;
    ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,
    ó kọ àdúrà mi.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;
    ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.

10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,
    bí i kìnnìún tí ó sápamọ́.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀
    ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ
    ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.

13 Ó fa ọkàn mí ya
    pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;
    wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò
    àti ìdààmú bí omi.

16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi;
    ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;
    mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ
    àti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,
    ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Mo ṣèrántí wọn,
    ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn
    àti nítorí náà ní mo nírètí.

22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,
    nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;
    títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;
    nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.

25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,
    sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Ó dára kí a ní sùúrù
    fún ìgbàlà Olúwa.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà
    nígbà tí ó wà ní èwe.

28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,
    nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—
    ìrètí sì lè wà.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,
    sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.

31 Ènìyàn kò di ìtanù
    lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,
    nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá
    tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.

34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀
    gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀
    níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ.
36 Láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,
    Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.

37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀
    tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ
    ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn
    nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?

40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò,
    kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè
    sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀
    ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.

43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;
    ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ
    pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn
    láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn
    gbòòrò sí wa.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun,
    nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò
    nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49 Ojú mi kò dá fún omijé,
    láì sinmi,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò ṣíjú wolẹ̀
    láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi
    nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.

52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí
    dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò
    wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Orí mi kún fún omi,
    mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.

55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,
    láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi: “Má ṣe di etí rẹ
    sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,
    o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”

58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,
    o ra ẹ̀mí mi padà.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi
    Gbé ẹjọ́ mi ró!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,
    gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.

61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn
    àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi—
62 Ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ
    sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,
    wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.

64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn
    fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,
    kí o sì fi wọ́n ré.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,
    lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

[a]I am the man who has seen affliction(A)
    by the rod of the Lord’s wrath.(B)
He has driven me away and made me walk
    in darkness(C) rather than light;
indeed, he has turned his hand against me(D)
    again and again, all day long.

He has made my skin and my flesh grow old(E)
    and has broken my bones.(F)
He has besieged me and surrounded me
    with bitterness(G) and hardship.(H)
He has made me dwell in darkness
    like those long dead.(I)

He has walled me in so I cannot escape;(J)
    he has weighed me down with chains.(K)
Even when I call out or cry for help,(L)
    he shuts out my prayer.(M)
He has barred(N) my way with blocks of stone;
    he has made my paths crooked.(O)

10 Like a bear lying in wait,
    like a lion(P) in hiding,(Q)
11 he dragged me from the path and mangled(R) me
    and left me without help.
12 He drew his bow(S)
    and made me the target(T) for his arrows.(U)

13 He pierced(V) my heart
    with arrows from his quiver.(W)
14 I became the laughingstock(X) of all my people;(Y)
    they mock me in song(Z) all day long.
15 He has filled me with bitter herbs
    and given me gall to drink.(AA)

16 He has broken my teeth with gravel;(AB)
    he has trampled me in the dust.(AC)
17 I have been deprived of peace;
    I have forgotten what prosperity is.
18 So I say, “My splendor is gone
    and all that I had hoped from the Lord.”(AD)

19 I remember my affliction and my wandering,
    the bitterness(AE) and the gall.(AF)
20 I well remember them,
    and my soul is downcast(AG) within me.(AH)
21 Yet this I call to mind
    and therefore I have hope:

22 Because of the Lord’s great love(AI) we are not consumed,(AJ)
    for his compassions never fail.(AK)
23 They are new every morning;
    great is your faithfulness.(AL)
24 I say to myself, “The Lord is my portion;(AM)
    therefore I will wait for him.”

25 The Lord is good to those whose hope is in him,
    to the one who seeks him;(AN)
26 it is good to wait quietly(AO)
    for the salvation of the Lord.(AP)
27 It is good for a man to bear the yoke
    while he is young.

28 Let him sit alone in silence,(AQ)
    for the Lord has laid it on him.
29 Let him bury his face in the dust(AR)
    there may yet be hope.(AS)
30 Let him offer his cheek to one who would strike him,(AT)
    and let him be filled with disgrace.(AU)

31 For no one is cast off
    by the Lord forever.(AV)
32 Though he brings grief, he will show compassion,
    so great is his unfailing love.(AW)
33 For he does not willingly bring affliction
    or grief to anyone.(AX)

34 To crush underfoot
    all prisoners in the land,
35 to deny people their rights
    before the Most High,(AY)
36 to deprive them of justice—
    would not the Lord see such things?(AZ)

37 Who can speak and have it happen
    if the Lord has not decreed it?(BA)
38 Is it not from the mouth of the Most High
    that both calamities and good things come?(BB)
39 Why should the living complain
    when punished for their sins?(BC)

40 Let us examine our ways and test them,(BD)
    and let us return to the Lord.(BE)
41 Let us lift up our hearts and our hands
    to God in heaven,(BF) and say:
42 “We have sinned and rebelled(BG)
    and you have not forgiven.(BH)

43 “You have covered yourself with anger and pursued(BI) us;
    you have slain without pity.(BJ)
44 You have covered yourself with a cloud(BK)
    so that no prayer(BL) can get through.(BM)
45 You have made us scum(BN) and refuse
    among the nations.

46 “All our enemies have opened their mouths
    wide(BO) against us.(BP)
47 We have suffered terror and pitfalls,(BQ)
    ruin and destruction.(BR)
48 Streams of tears(BS) flow from my eyes(BT)
    because my people are destroyed.(BU)

49 My eyes will flow unceasingly,
    without relief,(BV)
50 until the Lord looks down
    from heaven and sees.(BW)
51 What I see brings grief to my soul
    because of all the women of my city.

52 Those who were my enemies without cause
    hunted me like a bird.(BX)
53 They tried to end my life in a pit(BY)
    and threw stones at me;
54 the waters closed over my head,(BZ)
    and I thought I was about to perish.(CA)

55 I called on your name, Lord,
    from the depths(CB) of the pit.(CC)
56 You heard my plea:(CD) “Do not close your ears
    to my cry for relief.”
57 You came near(CE) when I called you,
    and you said, “Do not fear.”(CF)

58 You, Lord, took up my case;(CG)
    you redeemed my life.(CH)
59 Lord, you have seen the wrong done to me.(CI)
    Uphold my cause!(CJ)
60 You have seen the depth of their vengeance,
    all their plots against me.(CK)

61 Lord, you have heard their insults,(CL)
    all their plots against me—
62 what my enemies whisper and mutter
    against me all day long.(CM)
63 Look at them! Sitting or standing,
    they mock me in their songs.(CN)

64 Pay them back what they deserve, Lord,
    for what their hands have done.(CO)
65 Put a veil over their hearts,(CP)
    and may your curse be on them!
66 Pursue(CQ) them in anger and destroy them
    from under the heavens of the Lord.

Footnotes

  1. Lamentations 3:1 This chapter is an acrostic poem; the verses of each stanza begin with the successive letters of the Hebrew alphabet, and the verses within each stanza begin with the same letter.