Add parallel Print Page Options

Orin ọpẹ́ Dafidi

16 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run. Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.

Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan. Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.

Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa:

(A)Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀,
    ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i,
    Ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀
10 Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́;
    jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀;
    E wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.

12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe,
    iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
13 A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀,
    àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
14 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa;
    ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.

15 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé,
    ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹgbẹ̀rún ìran,
16 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu,
    ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
17 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu,
    gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
18 “Sí ọ, ni Èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani.
    Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”

19 Nígbà tí wọn kéré ní iye,
    wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
20 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè
    láti ìjọba kan sí èkejì.
21 Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú;
    nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
22 “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni ààmì òróró mi;
    Má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”

23 (B)Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé;
    ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.

25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ Jùlọ;
    òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà,
    ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀;
    agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.

28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè,
    ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀;
    gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀.
Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
30     Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé!
    Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.

31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn;
    Jẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀;
    Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin,
    Wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa,
    nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.

34 (C)Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára;
    ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
35 (D)Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run Olùgbàlà a wa;
    kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,
kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ,
    kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
36 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
    láé àti láéláé.

Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé “Àmín,” wọ́n sì “Yin Olúwa.”

37 Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà. 38 Ó fi Obedi-Edomu àti méjì-dínláàdọ́rin (68) ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.

39 Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni. 40 Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli. 41 Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa Nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé 42 Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.

43 Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.

Ministering Before the Ark(A)(B)(C)

16 They brought the ark of God and set it inside the tent that David had pitched(D) for it, and they presented burnt offerings and fellowship offerings before God. After David had finished sacrificing the burnt offerings and fellowship offerings, he blessed(E) the people in the name of the Lord. Then he gave a loaf of bread, a cake of dates and a cake of raisins(F) to each Israelite man and woman.

He appointed some of the Levites to minister(G) before the ark of the Lord, to extol,[a] thank, and praise the Lord, the God of Israel: Asaph was the chief, and next to him in rank were Zechariah, then Jaaziel,[b] Shemiramoth, Jehiel, Mattithiah, Eliab, Benaiah, Obed-Edom and Jeiel. They were to play the lyres and harps, Asaph was to sound the cymbals, and Benaiah and Jahaziel the priests were to blow the trumpets regularly before the ark of the covenant of God.

That day David first appointed Asaph and his associates to give praise(H) to the Lord in this manner:

Give praise(I) to the Lord, proclaim his name;
    make known among the nations(J) what he has done.
Sing to him, sing praise(K) to him;
    tell of all his wonderful acts.
10 Glory in his holy name;(L)
    let the hearts of those who seek the Lord rejoice.
11 Look to the Lord and his strength;
    seek(M) his face always.

12 Remember(N) the wonders(O) he has done,
    his miracles,(P) and the judgments he pronounced,
13 you his servants, the descendants of Israel,
    his chosen ones, the children of Jacob.
14 He is the Lord our God;
    his judgments(Q) are in all the earth.

15 He remembers[c](R) his covenant forever,
    the promise he made, for a thousand generations,
16 the covenant(S) he made with Abraham,
    the oath he swore to Isaac.
17 He confirmed it to Jacob(T) as a decree,
    to Israel as an everlasting covenant:
18 “To you I will give the land of Canaan(U)
    as the portion you will inherit.”

19 When they were but few in number,(V)
    few indeed, and strangers in it,
20 they[d] wandered(W) from nation to nation,
    from one kingdom to another.
21 He allowed no one to oppress them;
    for their sake he rebuked kings:(X)
22 “Do not touch my anointed ones;
    do my prophets(Y) no harm.”

23 Sing to the Lord, all the earth;
    proclaim his salvation day after day.
24 Declare his glory(Z) among the nations,
    his marvelous deeds among all peoples.

25 For great is the Lord and most worthy of praise;(AA)
    he is to be feared(AB) above all gods.(AC)
26 For all the gods of the nations are idols,
    but the Lord made the heavens.(AD)
27 Splendor and majesty are before him;
    strength and joy are in his dwelling place.

28 Ascribe to the Lord, all you families of nations,
    ascribe to the Lord glory and strength.(AE)
29 Ascribe to the Lord the glory due his name;(AF)
    bring an offering and come before him.
Worship the Lord in the splendor of his[e] holiness.(AG)
30     Tremble(AH) before him, all the earth!
    The world is firmly established; it cannot be moved.(AI)

31 Let the heavens rejoice, let the earth be glad;(AJ)
    let them say among the nations, “The Lord reigns!(AK)
32 Let the sea resound, and all that is in it;(AL)
    let the fields be jubilant, and everything in them!
33 Let the trees(AM) of the forest sing,
    let them sing for joy before the Lord,
    for he comes to judge(AN) the earth.

34 Give thanks(AO) to the Lord, for he is good;(AP)
    his love endures forever.(AQ)
35 Cry out, “Save us, God our Savior;(AR)
    gather us and deliver us from the nations,
that we may give thanks to your holy name,
    and glory in your praise.”
36 Praise be to the Lord, the God of Israel,(AS)
    from everlasting to everlasting.

Then all the people said “Amen” and “Praise the Lord.”

37 David left Asaph and his associates before the ark of the covenant of the Lord to minister there regularly, according to each day’s requirements.(AT) 38 He also left Obed-Edom(AU) and his sixty-eight associates to minister with them. Obed-Edom son of Jeduthun, and also Hosah,(AV) were gatekeepers.

39 David left Zadok(AW) the priest and his fellow priests before the tabernacle of the Lord at the high place in Gibeon(AX) 40 to present burnt offerings to the Lord on the altar of burnt offering regularly, morning and evening, in accordance with everything written in the Law(AY) of the Lord, which he had given Israel. 41 With them were Heman(AZ) and Jeduthun and the rest of those chosen and designated by name to give thanks to the Lord, “for his love endures forever.” 42 Heman and Jeduthun were responsible for the sounding of the trumpets and cymbals and for the playing of the other instruments for sacred song.(BA) The sons of Jeduthun(BB) were stationed at the gate.

43 Then all the people left, each for their own home, and David returned home to bless his family.

Footnotes

  1. 1 Chronicles 16:4 Or petition; or invoke
  2. 1 Chronicles 16:5 See 15:18,20; Hebrew Jeiel, possibly another name for Jaaziel.
  3. 1 Chronicles 16:15 Some Septuagint manuscripts (see also Psalm 105:8); Hebrew Remember
  4. 1 Chronicles 16:20 One Hebrew manuscript, Septuagint and Vulgate (see also Psalm 105:12); most Hebrew manuscripts inherit, / 19 though you are but few in number, / few indeed, and strangers in it.” / 20 They
  5. 1 Chronicles 16:29 Or Lord with the splendor of