Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi

23 Wọ̀nyí sì ni ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi.

“Dafidi ọmọ Jese,
    àní ọkùnrin tí a ti gbéga,
ẹni ààmì òróró Ọlọ́run Jakọbu,
    àti olórin dídùn Israẹli wí pé:

“Ẹ̀mí Olúwa sọ ọ̀rọ̀ nípa mi,
    ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ ní ahọ́n mi.
Ọlọ́run Israẹli ni,
    àpáta Israẹli sọ fún mi pé:
‘Ẹnìkan ti ń ṣe alákòóso ènìyàn lódodo,
    tí ń ṣàkóso ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Yóò sì dàbí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là,
    òwúrọ̀ tí kò ní ìkùùkuu,
nígbà tí koríko tútù
    bá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’

“Lóòtítọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run,
    ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun,
    tí a túnṣe nínú ohun gbogbo,
tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi,
    ilé mi kò lè ṣe kí ó má dàgbà.
Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Beliali yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣá tì,
    nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóò
    fi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká;
    wọ́n ó jóná lúúlúú níbìkan náà.”

Iṣẹ́ àwọn alágbára tí Dafidi ní

(A)Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn akọni ọkùnrin tí Dafidi ní:

Joṣebu-Basṣebeti ará Takemoniti ni olórí àwọn Balógun, òun sì ni akọni rẹ̀ tí ó pa ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn lẹ́ẹ̀kan náà.

Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Eleasari ọmọ Dodo ará Ahohi, ọ̀kan nínú àwọn alágbára ọkùnrin mẹ́ta ti ó wà pẹ̀lú Dafidi, nígbà tí wọ́n pe àwọn Filistini ní ìjà, àwọn ọkùnrin Israẹli sì ti lọ kúrò. 10 Òun sì dìde, ó sì kọlu àwọn Filistini títí ọwọ́ fi kún un, ọwọ́ rẹ̀ sì lẹ̀ mọ́ idà; Olúwa sì ṣiṣẹ́ ìgbàlà ńlá lọ́jọ́ náà, àwọn ènìyàn sì padà bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ láti kó ìkógun.

11 Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Ṣamma ọmọ Agee ará Harari, àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ láti piyẹ́, oko kan sì wà níbẹ̀ tí ó kún fun lẹntili: àwọn ọmọ-ogun Israẹli sì sá kúrò níwájú àwọn Filistini. 12 Ṣamma sì dúró láàrín méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbà á sílẹ̀, ó sì pa àwọn Filistini Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.

13 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀, wọ́n sì tọ Dafidi wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Adullamu: ọ̀wọ́ àwọn Filistini sì dó sí Àfonífojì Refaimu. 14 Dafidi sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Filistini sì wà ní Bẹtilẹhẹmu nígbà náà. 15 Dafidi sì ń pòǹgbẹ, ó wí báyìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kànga tí ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè.” 16 Àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta sì la ogún àwọn Filistini lọ, wọ́n sì fa omi láti inú kànga Bẹtilẹhẹmu wá, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè, wọ́n sì mú tọ Dafidi wá: òun kò sì fẹ́ mu nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tú u sílẹ̀ fún Olúwa. 17 Òun sì wí pé, “Kí a má rí, Olúwa, tí èmi ó fi ṣe èyí; ṣé èyí ni ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkùnrin tí ó lọ tí àwọn tí ẹ̀mí wọn lọ́wọ́?” Nítorí náà òun kò sì fẹ́ mú un.

Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ṣe.

18 Abiṣai, arákùnrin Joabu, ọmọ Seruiah, òun náà ni pàtàkì nínú àwọn mẹ́ta. Òun ni ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè sí ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, ó sì pa wọ́n, ó sì ní orúkọ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. 19 Ọlọ́lá jùlọ ni òun jẹ́ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta: ó sì jẹ́ olórí fún wọn: ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ìṣáájú.

20 Benaiah, ọmọ Jehoiada, ọmọ akọni ọkùnrin kan tí Kabṣeeli, ẹni tí ó pọ̀ ní iṣẹ́ agbára, òun pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu; ó sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ó sì pa kìnnìún kan nínú ihò lákoko òjò-dídì. 21 Ó sì pa ará Ejibiti kan, ọkùnrin tí ó dára láti wò: ará Ejibiti náà sì ní ọ̀kọ̀ kan ní ọwọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n Benaiah sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ, pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́, ó sì gba ọ̀kọ̀ náà lọ́wọ́ ará Ejibiti náà, ó sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa á. 22 Nǹkan wọ̀nyí ní Benaiah ọmọ Jehoiada ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà. 23 Nínú àwọn ọgbọ̀n (30) náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dafidi sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.

24 Ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n (30) náà:

Asaheli arákùnrin Joabu sì Jásí

Elhanani ọmọ Dodo ti Bẹtilẹhẹmu;

25 Ṣamma ará Haroditi,

Elika ará Harodi.

26 Helesi ará Palti,

Ira ọmọ Ikẹsi ará Tekoa;

27 Abieseri ará Anatoti,

Sibekai ará Huṣati;

28 Salmoni ará Ahohi,

Maharai ará Netofa;

29 Heledi ọmọ Baanah, ará Netofa,

Ittai ọmọ Ribai to Gibeah ti àwọn ọmọ Benjamini;

30 Benaiah ará Piratoni,

Hiddai ti Àfonífojì Gaaṣi,

31 Abi-Alboni ará Arbati,

Asmafeti Barhumiti;

32 Eliaba ará Ṣaalboni,

àwọn ọmọ Jaṣeni,

Jonatani; 33 ọmọ Ṣamma ará Harari,

Ahiamu ọmọ Ṣarari ará Harari;

34 Elifeleti ọmọ Ahasbai, ọmọ ará Maakati,

Eliamu ọmọ Ahitofeli ará Giloni;

35 Hesro ará Karmeli,

Paarai ará Arba;

36 Igali ọmọ Natani ti Ṣoba,

Bani ará Gadi;

37 Seleki ará Ammoni,

Naharai ará Beeroti, ẹni tí ń ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah;

38 Ira ará Itri,

Garebu ará Itri.

39 Uriah ará Hiti.

Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́tà-dínlógójì.

David’s Last Words

23 These are the last words of David:

“The inspired utterance of David son of Jesse,
    the utterance of the man exalted(A) by the Most High,
the man anointed(B) by the God of Jacob,
    the hero of Israel’s songs:

“The Spirit(C) of the Lord spoke through me;
    his word was on my tongue.
The God of Israel spoke,
    the Rock(D) of Israel said to me:
‘When one rules over people in righteousness,(E)
    when he rules in the fear(F) of God,(G)
he is like the light(H) of morning(I) at sunrise(J)
    on a cloudless morning,
like the brightness after rain(K)
    that brings grass from the earth.’

“If my house were not right with God,
    surely he would not have made with me an everlasting covenant,(L)
    arranged and secured in every part;
surely he would not bring to fruition my salvation
    and grant me my every desire.
But evil men are all to be cast aside like thorns,(M)
    which are not gathered with the hand.
Whoever touches thorns
    uses a tool of iron or the shaft of a spear;
    they are burned up where they lie.”

David’s Mighty Warriors(N)

These are the names of David’s mighty warriors:(O)

Josheb-Basshebeth,[a](P) a Tahkemonite,[b] was chief of the Three; he raised his spear against eight hundred men, whom he killed[c] in one encounter.

Next to him was Eleazar son of Dodai(Q) the Ahohite.(R) As one of the three mighty warriors, he was with David when they taunted the Philistines gathered at Pas Dammim[d] for battle. Then the Israelites retreated, 10 but Eleazar stood his ground and struck down the Philistines till his hand grew tired and froze to the sword. The Lord brought about a great victory that day. The troops returned to Eleazar, but only to strip the dead.

11 Next to him was Shammah son of Agee the Hararite. When the Philistines banded together at a place where there was a field full of lentils, Israel’s troops fled from them. 12 But Shammah took his stand in the middle of the field. He defended it and struck the Philistines down, and the Lord brought about a great victory.

13 During harvest time, three of the thirty chief warriors came down to David at the cave of Adullam,(S) while a band of Philistines was encamped in the Valley of Rephaim.(T) 14 At that time David was in the stronghold,(U) and the Philistine garrison was at Bethlehem.(V) 15 David longed for water and said, “Oh, that someone would get me a drink of water from the well near the gate of Bethlehem!” 16 So the three mighty warriors broke through the Philistine lines, drew water from the well near the gate of Bethlehem and carried it back to David. But he refused to drink it; instead, he poured(W) it out before the Lord. 17 “Far be it from me, Lord, to do this!” he said. “Is it not the blood(X) of men who went at the risk of their lives?” And David would not drink it.

Such were the exploits of the three mighty warriors.

18 Abishai(Y) the brother of Joab son of Zeruiah was chief of the Three.[e] He raised his spear against three hundred men, whom he killed, and so he became as famous as the Three. 19 Was he not held in greater honor than the Three? He became their commander, even though he was not included among them.

20 Benaiah(Z) son of Jehoiada, a valiant fighter from Kabzeel,(AA) performed great exploits. He struck down Moab’s two mightiest warriors. He also went down into a pit on a snowy day and killed a lion. 21 And he struck down a huge Egyptian. Although the Egyptian had a spear in his hand, Benaiah went against him with a club. He snatched the spear from the Egyptian’s hand and killed him with his own spear. 22 Such were the exploits of Benaiah son of Jehoiada; he too was as famous as the three mighty warriors. 23 He was held in greater honor than any of the Thirty, but he was not included among the Three. And David put him in charge of his bodyguard.

24 Among the Thirty were:

Asahel(AB) the brother of Joab,

Elhanan son of Dodo from Bethlehem,

25 Shammah the Harodite,(AC)

Elika the Harodite,

26 Helez(AD) the Paltite,

Ira(AE) son of Ikkesh from Tekoa,

27 Abiezer(AF) from Anathoth,(AG)

Sibbekai[f] the Hushathite,

28 Zalmon the Ahohite,

Maharai(AH) the Netophathite,(AI)

29 Heled[g](AJ) son of Baanah the Netophathite,

Ithai son of Ribai from Gibeah(AK) in Benjamin,

30 Benaiah the Pirathonite,(AL)

Hiddai[h] from the ravines of Gaash,(AM)

31 Abi-Albon the Arbathite,

Azmaveth the Barhumite,(AN)

32 Eliahba the Shaalbonite,

the sons of Jashen,

Jonathan 33 son of[i] Shammah the Hararite,

Ahiam son of Sharar[j] the Hararite,

34 Eliphelet son of Ahasbai the Maakathite,(AO)

Eliam(AP) son of Ahithophel(AQ) the Gilonite,

35 Hezro the Carmelite,(AR)

Paarai the Arbite,

36 Igal son of Nathan from Zobah,(AS)

the son of Hagri,[k]

37 Zelek the Ammonite,

Naharai the Beerothite,(AT) the armor-bearer of Joab son of Zeruiah,

38 Ira the Ithrite,(AU)

Gareb the Ithrite

39 and Uriah(AV) the Hittite.

There were thirty-seven in all.

Footnotes

  1. 2 Samuel 23:8 Hebrew; some Septuagint manuscripts suggest Ish-Bosheth, that is, Esh-Baal (see also 1 Chron. 11:11 Jashobeam).
  2. 2 Samuel 23:8 Probably a variant of Hakmonite (see 1 Chron. 11:11)
  3. 2 Samuel 23:8 Some Septuagint manuscripts (see also 1 Chron. 11:11); Hebrew and other Septuagint manuscripts Three; it was Adino the Eznite who killed eight hundred men
  4. 2 Samuel 23:9 See 1 Chron. 11:13; Hebrew gathered there.
  5. 2 Samuel 23:18 Most Hebrew manuscripts (see also 1 Chron. 11:20); two Hebrew manuscripts and Syriac Thirty
  6. 2 Samuel 23:27 Some Septuagint manuscripts (see also 21:18; 1 Chron. 11:29); Hebrew Mebunnai
  7. 2 Samuel 23:29 Some Hebrew manuscripts and Vulgate (see also 1 Chron. 11:30); most Hebrew manuscripts Heleb
  8. 2 Samuel 23:30 Hebrew; some Septuagint manuscripts (see also 1 Chron. 11:32) Hurai
  9. 2 Samuel 23:33 Some Septuagint manuscripts (see also 1 Chron. 11:34); Hebrew does not have son of.
  10. 2 Samuel 23:33 Hebrew; some Septuagint manuscripts (see also 1 Chron. 11:35) Sakar
  11. 2 Samuel 23:36 Some Septuagint manuscripts (see also 1 Chron. 11:38); Hebrew Haggadi