Amosi 2
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
2 (A)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí ó ti sun ún, di eérú,
egungun ọba Edomu
2 Èmi yóò rán iná sí orí Moabu
èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.
Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo
pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè
3 Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò
Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”
ni Olúwa wí.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀
wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́
Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà
òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé
5 Èmi yóò rán iná sí orí Juda
èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
Ìdájọ́ tí yóò wá sórí Israẹli
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Wọ́n ta olódodo fún fàdákà
àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀
bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀
tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára
Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà
Láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́
8 Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ
Lórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́ ẹ̀jẹ́
ní ilé òrìṣà wọn
wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 “Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn
gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari.
Òun sì le koko bí igi óákù
mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá
àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún
láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín
àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri
èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?”
ni Olúwa wí.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu
e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀
bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ
alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀
jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀
bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin
kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ
yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,”
ni Olúwa wí.
Amos 2
New International Version
2 This is what the Lord says:
“For three sins of Moab,(A)
even for four, I will not relent.
Because he burned to ashes(B)
the bones of Edom’s king,
2 I will send fire on Moab
that will consume the fortresses of Kerioth.[a](C)
Moab will go down in great tumult
amid war cries(D) and the blast of the trumpet.(E)
3 I will destroy her ruler(F)
and kill all her officials with him,”(G)
says the Lord.(H)
4 This is what the Lord says:
“For three sins of Judah,(I)
even for four, I will not relent.
Because they have rejected the law(J) of the Lord
and have not kept his decrees,(K)
because they have been led astray(L) by false gods,[b](M)
the gods[c] their ancestors followed,(N)
5 I will send fire(O) on Judah
that will consume the fortresses(P) of Jerusalem.(Q)”
Judgment on Israel
6 This is what the Lord says:
“For three sins of Israel,
even for four, I will not relent.(R)
They sell the innocent for silver,
and the needy for a pair of sandals.(S)
7 They trample on the heads of the poor
as on the dust of the ground
and deny justice to the oppressed.
Father and son use the same girl
and so profane my holy name.(T)
8 They lie down beside every altar
on garments taken in pledge.(U)
In the house of their god
they drink wine(V) taken as fines.(W)
9 “Yet I destroyed the Amorites(X) before them,
though they were tall(Y) as the cedars
and strong as the oaks.(Z)
I destroyed their fruit above
and their roots(AA) below.
10 I brought you up out of Egypt(AB)
and led(AC) you forty years in the wilderness(AD)
to give you the land of the Amorites.(AE)
11 “I also raised up prophets(AF) from among your children
and Nazirites(AG) from among your youths.
Is this not true, people of Israel?”
declares the Lord.
12 “But you made the Nazirites drink wine
and commanded the prophets not to prophesy.(AH)
13 “Now then, I will crush you
as a cart crushes when loaded with grain.(AI)
14 The swift will not escape,(AJ)
the strong(AK) will not muster their strength,
and the warrior will not save his life.(AL)
15 The archer(AM) will not stand his ground,
the fleet-footed soldier will not get away,
and the horseman(AN) will not save his life.(AO)
16 Even the bravest warriors(AP)
will flee naked on that day,”
declares the Lord.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.