Add parallel Print Page Options

Àṣẹ láti jáde kúrò ní Horebu

Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah: ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu. (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)

Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn. Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.

Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:

Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó. Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori: Ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate. Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín: Ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”

Yíyan àwọn olórí

(A)Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé. 10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run. 11 Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí. 12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín? 13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”

14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”

15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín: olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín. 16 (B)Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé: Ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò. 17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́: Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ. 18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.

A rán àwọn Ayọ́lẹ̀wò jáde

19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea. 20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa. 21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, Ẹ má sì ṣe fòyà.”

22 (C)Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”

23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. 24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí Àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò. 25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”

Ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa

26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín. 27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run. 28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’ ”

29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn. 30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín 31 (D)àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”

32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín, 33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.

34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé: 35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín. 36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”

37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà, 38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà. 39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà. 40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun pupa.”

41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.

42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’ ”

43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà. 44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma. 45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín. 46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.

The Command to Leave Horeb

These are the words Moses spoke to all Israel in the wilderness east of the Jordan(A)—that is, in the Arabah(B)—opposite Suph, between Paran(C) and Tophel, Laban, Hazeroth and Dizahab. (It takes eleven days to go from Horeb(D) to Kadesh Barnea(E) by the Mount Seir(F) road.)(G)

In the fortieth year,(H) on the first day of the eleventh month,(I) Moses proclaimed(J) to the Israelites all that the Lord had commanded him concerning them. This was after he had defeated Sihon(K) king of the Amorites,(L) who reigned in Heshbon,(M) and at Edrei had defeated Og(N) king of Bashan, who reigned in Ashtaroth.(O)

East of the Jordan in the territory of Moab,(P) Moses began to expound this law, saying:

The Lord our God said to us(Q) at Horeb,(R) “You have stayed long enough(S) at this mountain. Break camp and advance into the hill country of the Amorites;(T) go to all the neighboring peoples in the Arabah,(U) in the mountains, in the western foothills, in the Negev(V) and along the coast, to the land of the Canaanites(W) and to Lebanon,(X) as far as the great river, the Euphrates.(Y) See, I have given you this land(Z).(AA) Go in and take possession of the land the Lord swore(AB) he would give to your fathers—to Abraham, Isaac and Jacob—and to their descendants after them.”

The Appointment of Leaders

At that time I said to you, “You are too heavy a burden(AC) for me to carry alone.(AD) 10 The Lord your God has increased(AE) your numbers(AF) so that today you are as numerous(AG) as the stars in the sky.(AH) 11 May the Lord, the God of your ancestors, increase(AI) you a thousand times and bless you as he has promised!(AJ) 12 But how can I bear your problems and your burdens and your disputes all by myself?(AK) 13 Choose some wise, understanding and respected men(AL) from each of your tribes, and I will set them over you.”

14 You answered me, “What you propose to do is good.”

15 So I took(AM) the leading men of your tribes,(AN) wise and respected men,(AO) and appointed them to have authority over you—as commanders(AP) of thousands, of hundreds, of fifties and of tens and as tribal officials.(AQ) 16 And I charged your judges at that time, “Hear the disputes between your people and judge(AR) fairly,(AS) whether the case is between two Israelites or between an Israelite and a foreigner residing among you.(AT) 17 Do not show partiality(AU) in judging; hear both small and great alike. Do not be afraid of anyone,(AV) for judgment belongs to God. Bring me any case too hard for you, and I will hear it.”(AW) 18 And at that time I told you everything you were to do.(AX)

Spies Sent Out

19 Then, as the Lord our God commanded us, we set out from Horeb and went toward the hill country of the Amorites(AY) through all that vast and dreadful wilderness(AZ) that you have seen, and so we reached Kadesh Barnea.(BA) 20 Then I said to you, “You have reached the hill country of the Amorites, which the Lord our God is giving us. 21 See, the Lord your God has given you the land. Go up and take possession(BB) of it as the Lord, the God of your ancestors, told you. Do not be afraid;(BC) do not be discouraged.”(BD)

22 Then all of you came to me and said, “Let us send men ahead to spy(BE) out the land(BF) for us and bring back a report about the route we are to take and the towns we will come to.”

23 The idea seemed good to me; so I selected(BG) twelve of you, one man from each tribe. 24 They left and went up into the hill country, and came to the Valley of Eshkol(BH) and explored it. 25 Taking with them some of the fruit of the land, they brought it down to us and reported,(BI) “It is a good land(BJ) that the Lord our God is giving us.”(BK)

Rebellion Against the Lord

26 But you were unwilling to go up;(BL) you rebelled(BM) against the command of the Lord your God. 27 You grumbled(BN) in your tents and said, “The Lord hates us; so he brought us out of Egypt to deliver us into the hands of the Amorites to destroy us. 28 Where can we go? Our brothers have made our hearts melt in fear. They say, ‘The people are stronger and taller(BO) than we are; the cities are large, with walls up to the sky. We even saw the Anakites(BP) there.’”

29 Then I said to you, “Do not be terrified; do not be afraid(BQ) of them.(BR) 30 The Lord your God, who is going before you, will fight(BS) for you, as he did for you in Egypt, before your very eyes, 31 and in the wilderness. There you saw how the Lord your God carried(BT) you, as a father carries his son, all the way you went until you reached this place.”(BU)

32 In spite of this,(BV) you did not trust(BW) in the Lord your God, 33 who went ahead of you on your journey, in fire by night and in a cloud by day,(BX) to search(BY) out places for you to camp and to show you the way you should go.

34 When the Lord heard(BZ) what you said, he was angry(CA) and solemnly swore:(CB) 35 “No one from this evil generation shall see the good land(CC) I swore to give your ancestors, 36 except Caleb(CD) son of Jephunneh. He will see it, and I will give him and his descendants the land he set his feet on, because he followed the Lord wholeheartedly.(CE)

37 Because of you the Lord became angry(CF) with me also and said, “You shall not enter(CG) it, either. 38 But your assistant, Joshua(CH) son of Nun, will enter it. Encourage(CI) him, because he will lead(CJ) Israel to inherit(CK) it. 39 And the little ones that you said would be taken captive,(CL) your children who do not yet know(CM) good from bad—they will enter the land. I will give it to them and they will take possession of it. 40 But as for you, turn around and set out toward the desert along the route to the Red Sea.[a](CN)

41 Then you replied, “We have sinned against the Lord. We will go up and fight, as the Lord our God commanded us.” So every one of you put on his weapons, thinking it easy to go up into the hill country.

42 But the Lord said to me, “Tell them, ‘Do not go up and fight, because I will not be with you. You will be defeated by your enemies.’”(CO)

43 So I told you, but you would not listen. You rebelled against the Lord’s command and in your arrogance you marched up into the hill country. 44 The Amorites who lived in those hills came out against you; they chased you like a swarm of bees(CP) and beat you down from Seir(CQ) all the way to Hormah.(CR) 45 You came back and wept before the Lord,(CS) but he paid no attention(CT) to your weeping and turned a deaf ear(CU) to you. 46 And so you stayed in Kadesh(CV) many days—all the time you spent there.

Footnotes

  1. Deuteronomy 1:40 Or the Sea of Reeds