Add parallel Print Page Options

12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ààmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.

13 “ ‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọpọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù. 14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde. 15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù. 16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.

Read full chapter

12 Also I gave them my Sabbaths(A) as a sign(B) between us,(C) so they would know that I the Lord made them holy.(D)

13 “‘Yet the people of Israel rebelled(E) against me in the wilderness. They did not follow my decrees but rejected my laws(F)—by which the person who obeys them will live—and they utterly desecrated my Sabbaths.(G) So I said I would pour out my wrath(H) on them and destroy(I) them in the wilderness.(J) 14 But for the sake of my name I did what would keep it from being profaned(K) in the eyes of the nations in whose sight I had brought them out.(L) 15 Also with uplifted hand I swore(M) to them in the wilderness that I would not bring them into the land I had given them—a land flowing with milk and honey, the most beautiful of all lands(N) 16 because they rejected my laws(O) and did not follow my decrees and desecrated my Sabbaths. For their hearts(P) were devoted to their idols.(Q)

Read full chapter

16 (A)(B) Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.

17 (C)(D) Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.

18 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.

19 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.

20 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.

Read full chapter

16 “Honor your father(A) and your mother,(B) as the Lord your God has commanded you, so that you may live long(C) and that it may go well with you in the land the Lord your God is giving you.

17 “You shall not murder.(D)

18 “You shall not commit adultery.(E)

19 “You shall not steal.(F)

20 “You shall not give false testimony against your neighbor.(G)

Read full chapter

(A)Àwọn òfin, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò,” bí òfin mìíràn bá sì wà, ni a papọ̀ ṣọ̀kan nínú òfin kan yìí: “Fẹ́ ẹnìkéjì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ̀.”

Read full chapter

The commandments, “You shall not commit adultery,” “You shall not murder,” “You shall not steal,” “You shall not covet,”[a](A) and whatever other command there may be, are summed up(B) in this one command: “Love your neighbor as yourself.”[b](C)

Read full chapter

Footnotes

  1. Romans 13:9 Exodus 20:13-15,17; Deut. 5:17-19,21
  2. Romans 13:9 Lev. 19:18

11 (A)Nítorí ẹni tí ó wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà,” òun ni ó sì wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.” Ǹjẹ́ bí ìwọ kò ṣe panṣágà, ṣùgbọ́n tí ìwọ pànìyàn, ìwọ jásí arúfin.

Read full chapter

11 For he who said, “You shall not commit adultery,”[a](A) also said, “You shall not murder.”[b](B) If you do not commit adultery but do commit murder, you have become a lawbreaker.

Read full chapter

Footnotes

  1. James 2:11 Exodus 20:14; Deut. 5:18
  2. James 2:11 Exodus 20:13; Deut. 5:17