Add parallel Print Page Options

Ìkòkò ìdáná náà

24 Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: “Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an. Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“ ‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná:
    Gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀,
    gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá.
    Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀
Mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran.
    Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀;
sì jẹ́ kí ó hó dáradára
    sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.

“ ‘Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí:

“ ‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà,
    fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀,
tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀!
    Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí
    má ṣe ṣà wọ́n mú.

“ ‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀;
    à á sí orí àpáta kan lásán
kò dà á sí orí ilẹ̀,
    níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san
    mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán,
    kí o ma bà á wà ni bíbò.

“ ‘Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“ ‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà!
    Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Nítorí náà kó igi náà jọ sí i,
    kí o sì fi iná sí i.
Ṣe ẹran náà dáradára,
    fi tùràrí dùn ún;
    kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná
    kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n
àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀
    kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ:
    èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀,
    èérí náà gan an yóò wà nínú iná.

13 “ ‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.

14 “ ‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’ ”

Ìyàwó Esekiẹli kú

15 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé: 16 “Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀. 17 Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ: má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”

18 Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.

19 Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”

20 Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: 21 Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà. 22 Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà. 23 Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín. 24 Esekiẹli yóò jẹ ààmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’

25 “Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn, 26 ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ 27 Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ ààmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”

Jerusalem as a Cooking Pot

24 In the ninth year, in the tenth month on the tenth day, the word of the Lord came to me:(A) “Son of man, record(B) this date, this very date, because the king of Babylon has laid siege to Jerusalem this very day.(C) Tell this rebellious people(D) a parable(E) and say to them: ‘This is what the Sovereign Lord says:

“‘Put on the cooking pot;(F) put it on
    and pour water into it.
Put into it the pieces of meat,
    all the choice pieces—the leg and the shoulder.
Fill it with the best of these bones;(G)
    take the pick of the flock.(H)
Pile wood beneath it for the bones;
    bring it to a boil
    and cook the bones in it.(I)

“‘For this is what the Sovereign Lord says:

“‘Woe(J) to the city of bloodshed,(K)
    to the pot now encrusted,
    whose deposit will not go away!
Take the meat out piece by piece
    in whatever order(L) it comes.(M)

“‘For the blood she shed is in her midst:
    She poured it on the bare rock;
she did not pour it on the ground,
    where the dust would cover it.(N)
To stir up wrath and take revenge
    I put her blood on the bare rock,
    so that it would not be covered.

“‘Therefore this is what the Sovereign Lord says:

“‘Woe to the city of bloodshed!
    I, too, will pile the wood high.
10 So heap on the wood
    and kindle the fire.
Cook the meat well,
    mixing in the spices;
    and let the bones be charred.
11 Then set the empty pot on the coals
    till it becomes hot and its copper glows,
so that its impurities may be melted
    and its deposit burned away.(O)
12 It has frustrated all efforts;
    its heavy deposit has not been removed,
    not even by fire.

13 “‘Now your impurity is lewdness. Because I tried to cleanse you but you would not be cleansed(P) from your impurity, you will not be clean again until my wrath against you has subsided.(Q)

14 “‘I the Lord have spoken.(R) The time has come for me to act.(S) I will not hold back; I will not have pity,(T) nor will I relent.(U) You will be judged according to your conduct and your actions,(V) declares the Sovereign Lord.(W)’”

Ezekiel’s Wife Dies

15 The word of the Lord came to me: 16 “Son of man, with one blow(X) I am about to take away from you the delight of your eyes.(Y) Yet do not lament or weep or shed any tears.(Z) 17 Groan quietly;(AA) do not mourn for the dead. Keep your turban(AB) fastened and your sandals(AC) on your feet; do not cover your mustache and beard(AD) or eat the customary food of mourners.(AE)

18 So I spoke to the people in the morning, and in the evening my wife died. The next morning I did as I had been commanded.(AF)

19 Then the people asked me, “Won’t you tell us what these things have to do with us?(AG) Why are you acting like this?”

20 So I said to them, “The word of the Lord came to me: 21 Say to the people of Israel, ‘This is what the Sovereign Lord says: I am about to desecrate my sanctuary(AH)—the stronghold in which you take pride,(AI) the delight of your eyes,(AJ) the object of your affection. The sons and daughters(AK) you left behind will fall by the sword.(AL) 22 And you will do as I have done. You will not cover your mustache and beard(AM) or eat the customary food of mourners.(AN) 23 You will keep your turbans(AO) on your heads and your sandals(AP) on your feet. You will not mourn(AQ) or weep but will waste away(AR) because of[a] your sins and groan among yourselves.(AS) 24 Ezekiel(AT) will be a sign(AU) to you; you will do just as he has done. When this happens, you will know that I am the Sovereign Lord.’

25 “And you, son of man, on the day I take away their stronghold, their joy and glory, the delight of their eyes,(AV) their heart’s desire,(AW) and their sons and daughters(AX) as well— 26 on that day a fugitive will come to tell you(AY) the news. 27 At that time your mouth will be opened; you will speak with him and will no longer be silent.(AZ) So you will be a sign to them, and they will know that I am the Lord.(BA)

Footnotes

  1. Ezekiel 24:23 Or away in