Add parallel Print Page Options

Ìpohùnréré ẹkún fún Tire

27 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé: “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún fún Tire. Sọ fún Tire, tí a tẹ̀dó sí ẹnu-bodè Òkun, oníṣòwò àwọn orílẹ̀-èdè fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù. ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí:

“ ‘Ìwọ Tire wí pé
    “Ẹwà mi pé.”
Ààlà rẹ wà ní àárín Òkun;
    àwọn ọ̀mọ̀lé rẹ ti mú ẹwà rẹ pé.
Wọn ṣe gbogbo pákó rẹ
    ní igi junifa láti Seniri;
wọ́n ti mú igi kedari láti Lebanoni wá
    láti fi ṣe òpó ọkọ̀ fún ọ.
Nínú igi óákù ti Baṣani
    ní wọn ti fi gbẹ́ ìtukọ̀ ọ̀pá rẹ̀;
ìjókòó rẹ ni wọn fi eyín erin ṣe pẹ̀lú
    igi bokisi láti erékùṣù Kittimu wá
Ọ̀gbọ̀ dáradára aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ láti Ejibiti wá
    ni èyí tí ìwọ ta láti fi ṣe àsíá ọkọ̀ rẹ;
    aṣọ aláró àti elése àlùkò
láti erékùṣù ti Eliṣa
    ni èyí tí a fi bò ó
Àwọn ará ìlú Sidoni àti Arfadi ni àwọn atukọ̀ rẹ̀
    àwọn ọlọ́gbọ́n ẹ̀rọ rẹ, ìwọ Tire,
    ni àwọn atukọ̀ rẹ.
Àwọn àgbàgbà Gebali,
    àti àwọn ọlọ́gbọ́n ibẹ̀,
wà nínú ọkọ̀ bí òṣìṣẹ́ atukọ̀ rẹ,
    gbogbo ọkọ̀ ojú Òkun
àti àwọn atukọ̀ Òkun
    wá pẹ̀lú rẹ láti dòwò pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.

10 “ ‘Àwọn ènìyàn Persia, Ludi àti Puti
    wà nínú jagunjagun rẹ
àwọn ẹgbẹ́ ọmọ-ogun rẹ.
    Wọ́n gbé asà àti àṣíborí wọn ró
sára ògiri rẹ,
    wọn fi ẹwà rẹ hàn.
11 Àwọn ènìyàn Arfadi àti Heleki
    wà lórí odi rẹ yíká;
àti àwọn akọni Gamadi,
    wà nínú ilé ìṣọ́ rẹ.
Wọ́n fi àwọn asà wọn kọ ara odi rẹ;
    wọn ti mú ẹwà rẹ pé.

12 “ ‘Tarṣiṣi ṣòwò pẹ̀lú rẹ torí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ tí ó ní; wọn ṣe ìpààrọ̀ fàdákà, irin idẹ àti òjé fún ọjà títà rẹ̀.

13 “ ‘Àwọn ará Giriki, Tubali, Jafani àti Meṣeki, ṣòwò pẹ̀lú rẹ: wọ́n fi ẹrù àti ohun èlò idẹ ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọrọ̀ rẹ.

14 “ ‘Àwọn ti ilé Beti-Togarma ṣe ìpààrọ̀ ẹṣin-ìṣiṣẹ́, ẹṣin ogun àti ìbáaka ṣòwò ní ọjà rẹ.

15 “ ‘Àwọn ènìyàn Dedani ni àwọn oníṣòwò rẹ, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù ni wọ́n jẹ́ oníbàárà rẹ̀; wọ́n mú eyín erin àti igi eboni san owó rẹ.

16 “ ‘Aramu ṣòwò pẹ̀lú nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ òwò rẹ̀; wọn ṣe ìpààrọ̀ (turikuoṣe) òkúta iyebíye, òwú elése àlùkò, aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́, aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ìlẹ̀kẹ̀ iyùn pupa fún ọjà títà rẹ.

17 “ ‘Juda àti Israẹli, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọn ṣe ìpààrọ̀ ọkà, Minniti, àkàrà àdídùn; pannagi, oyin, epo àti ìkunra olóòórùn dídùn ni wọ́n fi ná ọjà rẹ.

18 “ ‘Damasku, ni oníṣòwò rẹ, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọjà tí ó ṣe àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀; ní ti ọtí wáìnì tí Helboni, àti irun àgùntàn funfun láti Sahari, 19 àti ìdẹ̀ ọtí wáìnì láti Isali, ohun wíwọ̀: irin dídán, kasia àti kálàmù ni àwọn ohun pàṣípàrọ̀ fún ọjà rẹ.

20 “ ‘Dedani ni oníṣòwò rẹ ní aṣọ ìjókòó-lẹ́sin fún ẹṣin-gígùn.

21 “ ‘Àwọn ará Arabia àti gbogbo àwọn ọmọ-aládé Kedari àwọn ni àwọn oníbàárà rẹ: ní ti ọ̀dọ́-àgùntàn, àgbò àti ewúrẹ́, nínú ìwọ̀nyí ni wọ́n ti jẹ́ oníbàárà rẹ.

22 “ ‘Àwọn oníṣòwò ti Ṣeba àti Raama, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọ́n ta onírúurú tùràrí olóòórùn dídùn dáradára ní ọjà rẹ, àti àwọn òkúta iyebíye àti wúrà.

23 “ ‘Harani àti Kanneh àti Edeni, àwọn oníṣòwò Ṣeba, Asiria àti Kilmadi, ni àwọn oníṣòwò rẹ. 24 Wọ̀nyí ní oníbàárà rẹ ní onírúurú nǹkan: aṣọ aláró, àti oníṣẹ́-ọnà àti àpótí aṣọ olówó iyebíye, tí a fi okùn dì, tí a sì fi igi Kedari ṣe, nínú àwọn ilé-ìtajà rẹ.

25 “ ‘Àwọn ọkọ̀ Tarṣiṣi ní èrò
    ní ọjà rẹ
a ti mú ọ gbilẹ̀
    a sì ti ṣe ọ́ lógo
    ní àárín gbùngbùn Òkun
26 Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọ
    wá sínú omi ńlá.
Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́
    ní àárín gbùngbùn Òkun.
27 Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ,
    àwọn ìṣúra rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ.
Àwọn oníbàárà rẹ àti gbogbo àwọn
    jagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹ
àti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹ
    tí ó wà ní àárín rẹ
yóò rì sínú àárín gbùngbùn Òkun
    ní ọjọ́ ìparun rẹ.
28 Ilẹ̀ etí Òkun yóò mì
    nítorí ìró igbe àwọn atukọ̀ rẹ.
29 Gbogbo àwọn alájẹ̀,
    àwọn atukọ̀ Òkun
àti àwọn atọ́kọ̀ ojú Òkun;
    yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn,
    wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.
30 Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọ
    wọn yóò sì sọkún kíkorò lé ọ lórí
wọn yóò ku eruku lé orí ara wọn
    wọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.
31 Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹ
    wọn yóò wọ aṣọ yíya
wọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lú
    ìkorò ọkàn nítorí rẹ
    pẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.
32 Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùnréré ẹkún fún ọ
    wọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé:
“Ta ni ó dàbí Tire
    èyí tí ó parun ní àárín Òkun?”
33 Nígbà tí ọjà títà rẹ ti Òkun jáde wá
    ìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè lọ́rùn
ìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹ
    sọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.
34 Ní ìsinsin yìí tí Òkun fọ ọ túútúú
    nínú ibú omi;
nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ
    ní àárín rẹ,
    ni yóò ṣubú.
35 Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbé
    ní erékùṣù náà sí ọ
jìnnìjìnnì yóò bo àwọn ọba wọn,
    ìyọnu yóò sì han ní ojú wọn.
36 Àwọn oníṣòwò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè dún bí ejò sí ọ
    ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù
    ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’ ”

A Lament Over Tyre

27 The word of the Lord came to me: “Son of man, take up a lament(A) concerning Tyre. Say to Tyre,(B) situated at the gateway to the sea,(C) merchant of peoples on many coasts, ‘This is what the Sovereign Lord says:

“‘You say, Tyre,
    “I am perfect in beauty.(D)
Your domain was on the high seas;
    your builders brought your beauty to perfection.(E)
They made all your timbers
    of juniper from Senir[a];(F)
they took a cedar from Lebanon(G)
    to make a mast for you.
Of oaks(H) from Bashan
    they made your oars;
of cypress wood[b] from the coasts of Cyprus(I)
    they made your deck, adorned with ivory.
Fine embroidered linen(J) from Egypt was your sail
    and served as your banner;
your awnings were of blue and purple(K)
    from the coasts of Elishah.(L)
Men of Sidon and Arvad(M) were your oarsmen;
    your skilled men, Tyre, were aboard as your sailors.(N)
Veteran craftsmen of Byblos(O) were on board
    as shipwrights to caulk your seams.
All the ships of the sea(P) and their sailors
    came alongside to trade for your wares.

10 “‘Men of Persia,(Q) Lydia(R) and Put(S)
    served as soldiers in your army.
They hung their shields(T) and helmets on your walls,
    bringing you splendor.
11 Men of Arvad and Helek
    guarded your walls on every side;
men of Gammad
    were in your towers.
They hung their shields around your walls;
    they brought your beauty to perfection.(U)

12 “‘Tarshish(V) did business with you because of your great wealth of goods;(W) they exchanged silver, iron, tin and lead for your merchandise.

13 “‘Greece,(X) Tubal and Meshek(Y) did business with you; they traded human beings(Z) and articles of bronze for your wares.

14 “‘Men of Beth Togarmah(AA) exchanged chariot horses, cavalry horses and mules for your merchandise.

15 “‘The men of Rhodes[c](AB) traded with you, and many coastlands(AC) were your customers; they paid you with ivory(AD) tusks and ebony.

16 “‘Aram[d](AE) did business with you because of your many products; they exchanged turquoise,(AF) purple fabric, embroidered work, fine linen,(AG) coral(AH) and rubies for your merchandise.

17 “‘Judah and Israel traded with you; they exchanged wheat(AI) from Minnith(AJ) and confections,[e] honey, olive oil and balm(AK) for your wares.(AL)

18 “‘Damascus(AM) did business with you because of your many products and great wealth of goods.(AN) They offered wine from Helbon, wool from Zahar 19 and casks of wine from Izal(AO) in exchange for your wares: wrought iron, cassia(AP) and calamus.

20 “‘Dedan(AQ) traded in saddle blankets with you.

21 “‘Arabia(AR) and all the princes of Kedar(AS) were your customers; they did business with you in lambs, rams and goats.

22 “‘The merchants of Sheba(AT) and Raamah traded with you; for your merchandise they exchanged the finest of all kinds of spices(AU) and precious stones, and gold.(AV)

23 “‘Harran,(AW) Kanneh and Eden(AX) and merchants of Sheba, Ashur(AY) and Kilmad traded with you. 24 In your marketplace they traded with you beautiful garments, blue fabric, embroidered work and multicolored rugs with cords twisted and tightly knotted.

25 “‘The ships of Tarshish(AZ) serve
    as carriers for your wares.
You are filled with heavy cargo
    as you sail the sea.(BA)
26 Your oarsmen take you
    out to the high seas.
But the east wind(BB) will break you to pieces
    far out at sea.
27 Your wealth,(BC) merchandise and wares,
    your mariners, sailors and shipwrights,
your merchants and all your soldiers,
    and everyone else on board
will sink into the heart of the sea(BD)
    on the day of your shipwreck.
28 The shorelands will quake(BE)
    when your sailors cry out.
29 All who handle the oars
    will abandon their ships;
the mariners and all the sailors
    will stand on the shore.
30 They will raise their voice
    and cry bitterly over you;
they will sprinkle dust(BF) on their heads
    and roll(BG) in ashes.(BH)
31 They will shave their heads(BI) because of you
    and will put on sackcloth.
They will weep(BJ) over you with anguish of soul
    and with bitter mourning.(BK)
32 As they wail and mourn over you,
    they will take up a lament(BL) concerning you:
“Who was ever silenced like Tyre,
    surrounded by the sea?(BM)
33 When your merchandise went out on the seas,(BN)
    you satisfied many nations;
with your great wealth(BO) and your wares
    you enriched the kings of the earth.
34 Now you are shattered by the sea
    in the depths of the waters;
your wares and all your company
    have gone down with you.(BP)
35 All who live in the coastlands(BQ)
    are appalled(BR) at you;
their kings shudder with horror
    and their faces are distorted with fear.(BS)
36 The merchants among the nations scoff at you;(BT)
    you have come to a horrible end
    and will be no more.(BU)’”

Footnotes

  1. Ezekiel 27:5 That is, Mount Hermon
  2. Ezekiel 27:6 Targum; the Masoretic Text has a different division of the consonants.
  3. Ezekiel 27:15 Septuagint; Hebrew Dedan
  4. Ezekiel 27:16 Most Hebrew manuscripts; some Hebrew manuscripts and Syriac Edom
  5. Ezekiel 27:17 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.