Add parallel Print Page Options

Òpépé igi Sedari ni Lebanoni

31 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá: “Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀:

“ ‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni
    Lebanoni ní ìgbà kan rí,
pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà;
    tí ó ga sókè,
    òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
Omi mú un dàgbàsókè:
    orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè;
àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká,
    ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío
    ju gbogbo igi orí pápá lọ;
ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i:
    àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn,
    wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
(A)Ẹyẹ ojú ọ̀run
    kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀
gbogbo ẹranko igbó
    ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀;
gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá
    ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́,
    pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀,
nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀
    sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
(B)Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run
    kò lè è bò ó mọ́lẹ̀;
tàbí kí àwọn igi junifa
    ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀,
tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀,
    kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run
    tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
Mo mú kí ó ní ẹwà
    pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọpọ̀
tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni
    tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.

10 “ ‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí; Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga, 11 Mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan, 12 àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀. 13 Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀. 14 Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.

15 “ ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà; Mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. 16 Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. 17 Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa.

18 “ ‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.

“ ‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’ ”

Pharaoh as a Felled Cedar of Lebanon

31 In the eleventh year,(A) in the third month on the first day, the word of the Lord came to me:(B) “Son of man, say to Pharaoh king of Egypt and to his hordes:

“‘Who can be compared with you in majesty?
Consider Assyria,(C) once a cedar in Lebanon,(D)
    with beautiful branches overshadowing the forest;
it towered on high,
    its top above the thick foliage.(E)
The waters(F) nourished it,
    deep springs made it grow tall;
their streams flowed
    all around its base
and sent their channels
    to all the trees of the field.(G)
So it towered higher(H)
    than all the trees of the field;
its boughs increased
    and its branches grew long,
    spreading because of abundant waters.(I)
All the birds of the sky
    nested in its boughs,
all the animals of the wild
    gave birth(J) under its branches;
all the great nations
    lived in its shade.(K)
It was majestic in beauty,
    with its spreading boughs,
for its roots went down
    to abundant waters.(L)
The cedars(M) in the garden of God
    could not rival it,
nor could the junipers
    equal its boughs,
nor could the plane trees(N)
    compare with its branches—
no tree in the garden of God
    could match its beauty.(O)
I made it beautiful
    with abundant branches,
the envy of all the trees of Eden(P)
    in the garden of God.(Q)

10 “‘Therefore this is what the Sovereign Lord says: Because the great cedar towered over the thick foliage, and because it was proud(R) of its height, 11 I gave it into the hands of the ruler of the nations, for him to deal with according to its wickedness. I cast it aside,(S) 12 and the most ruthless of foreign nations(T) cut it down and left it. Its boughs fell on the mountains and in all the valleys;(U) its branches lay broken in all the ravines of the land. All the nations of the earth came out from under its shade and left it.(V) 13 All the birds settled on the fallen tree, and all the wild animals lived among its branches.(W) 14 Therefore no other trees by the waters are ever to tower proudly on high, lifting their tops above the thick foliage. No other trees so well-watered are ever to reach such a height; they are all destined(X) for death,(Y) for the earth below, among mortals who go down to the realm of the dead.(Z)

15 “‘This is what the Sovereign Lord says: On the day it was brought down to the realm of the dead I covered the deep springs with mourning for it; I held back its streams, and its abundant waters were restrained. Because of it I clothed Lebanon with gloom, and all the trees of the field withered away.(AA) 16 I made the nations tremble(AB) at the sound of its fall when I brought it down to the realm of the dead to be with those who go down to the pit. Then all the trees(AC) of Eden,(AD) the choicest and best of Lebanon, the well-watered trees, were consoled(AE) in the earth below.(AF) 17 They too, like the great cedar, had gone down to the realm of the dead, to those killed by the sword,(AG) along with the armed men who lived in its shade among the nations.

18 “‘Which of the trees of Eden can be compared with you in splendor and majesty? Yet you, too, will be brought down with the trees of Eden to the earth below; you will lie among the uncircumcised,(AH) with those killed by the sword.

“‘This is Pharaoh and all his hordes, declares the Sovereign Lord.’”