Add parallel Print Page Options

Olórí àwọn ìdílé tí ó padà pẹ̀lú Esra

Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:

Nínú àwọn ọmọ Finehasi:

Gerṣomu;

nínú àwọn ọmọ Itamari:

Daniẹli;

nínú àwọn ọmọ Dafidi:

Hattusi, nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah;

nínú àwọn ọmọ Paroṣi:

Sekariah, àti pé àádọ́jọ (150) ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;

nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu:

Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba (200) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

nínú àwọn ọmọ Sattu:

Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún (300) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

nínú àwọn ọmọ Adini:

Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta (50) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

nínú àwọn ọmọ Elamu:

Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin (70) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

nínú àwọn ọmọ Ṣefatia:

Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin (80) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

nínú àwọn ọmọ Joabu:

Ọbadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó-lé-nígba ó-dinméjì (218) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

10 nínú àwọn ọmọ Bani:

Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ 160 ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

11 nínú àwọn ọmọ Bebai:

Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin 28 méjì-dínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;

12 nínú àwọn ọmọ Asgadi:

Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà (110) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

13 nínú àwọn ọmọ Adonikami:

àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta (60) ọkùnrin pẹ̀lú wọn;

14 nínú àwọn ọmọ Bigfai:

Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin 70 ọkùnrin pẹ̀lú wọn.

Ìpadà sí Jerusalẹmu

15 Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀. 16 Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀, 17 mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa. 18 Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òṣùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjì-dínlógún. 19 Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin. 20 Wọ́n sì tún mú ogúnlénígba (220) àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.

21 Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa. 22 Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.” 23 Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.

24 Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn, 25 mo sì fi òṣùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa. 26 Mo fi òṣùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta (650) tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà, 27 ogún (20) ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún (1,000) dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.

28 Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín. 29 Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òṣùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.” 30 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.

31 Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa. 32 Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.

33 Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú. 34 Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.

35 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìn-dínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tà-dínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa. 36 Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.

List of the Family Heads Returning With Ezra

These are the family heads and those registered with them who came up with me from Babylon during the reign of King Artaxerxes:(A)

of the descendants of Phinehas, Gershom;

of the descendants of Ithamar, Daniel;

of the descendants of David, Hattush of the descendants of Shekaniah;(B)

of the descendants of Parosh,(C) Zechariah, and with him were registered 150 men;

of the descendants of Pahath-Moab,(D) Eliehoenai son of Zerahiah, and with him 200 men;

of the descendants of Zattu,[a] Shekaniah son of Jahaziel, and with him 300 men;

of the descendants of Adin,(E) Ebed son of Jonathan, and with him 50 men;

of the descendants of Elam, Jeshaiah son of Athaliah, and with him 70 men;

of the descendants of Shephatiah, Zebadiah son of Michael, and with him 80 men;

of the descendants of Joab, Obadiah son of Jehiel, and with him 218 men;

10 of the descendants of Bani,[b] Shelomith son of Josiphiah, and with him 160 men;

11 of the descendants of Bebai, Zechariah son of Bebai, and with him 28 men;

12 of the descendants of Azgad, Johanan son of Hakkatan, and with him 110 men;

13 of the descendants of Adonikam,(F) the last ones, whose names were Eliphelet, Jeuel and Shemaiah, and with them 60 men;

14 of the descendants of Bigvai, Uthai and Zakkur, and with them 70 men.

The Return to Jerusalem

15 I assembled them at the canal that flows toward Ahava,(G) and we camped there three days. When I checked among the people and the priests, I found no Levites(H) there. 16 So I summoned Eliezer, Ariel, Shemaiah, Elnathan, Jarib, Elnathan, Nathan, Zechariah and Meshullam, who were leaders, and Joiarib and Elnathan, who were men of learning, 17 and I ordered them to go to Iddo, the leader in Kasiphia. I told them what to say to Iddo and his fellow Levites, the temple servants(I) in Kasiphia, so that they might bring attendants to us for the house of our God. 18 Because the gracious hand of our God was on us,(J) they brought us Sherebiah,(K) a capable man, from the descendants of Mahli son of Levi, the son of Israel, and Sherebiah’s sons and brothers, 18 in all; 19 and Hashabiah, together with Jeshaiah from the descendants of Merari, and his brothers and nephews, 20 in all. 20 They also brought 220 of the temple servants(L)—a body that David and the officials had established to assist the Levites. All were registered by name.

21 There, by the Ahava Canal,(M) I proclaimed a fast, so that we might humble ourselves before our God and ask him for a safe journey(N) for us and our children, with all our possessions. 22 I was ashamed to ask the king for soldiers(O) and horsemen to protect us from enemies on the road, because we had told the king, “The gracious hand of our God is on everyone(P) who looks to him, but his great anger is against all who forsake him.(Q) 23 So we fasted(R) and petitioned our God about this, and he answered our prayer.

24 Then I set apart twelve of the leading priests, namely, Sherebiah,(S) Hashabiah and ten of their brothers, 25 and I weighed out(T) to them the offering of silver and gold and the articles that the king, his advisers, his officials and all Israel present there had donated for the house of our God. 26 I weighed out to them 650 talents[c] of silver, silver articles weighing 100 talents,[d] 100 talents[e] of gold, 27 20 bowls of gold valued at 1,000 darics,[f] and two fine articles of polished bronze, as precious as gold.

28 I said to them, “You as well as these articles are consecrated to the Lord.(U) The silver and gold are a freewill offering to the Lord, the God of your ancestors. 29 Guard them carefully until you weigh them out in the chambers of the house of the Lord in Jerusalem before the leading priests and the Levites and the family heads of Israel.” 30 Then the priests and Levites received the silver and gold and sacred articles that had been weighed out to be taken to the house of our God in Jerusalem.

31 On the twelfth day of the first month we set out from the Ahava Canal(V) to go to Jerusalem. The hand of our God was on us,(W) and he protected us from enemies and bandits along the way. 32 So we arrived in Jerusalem, where we rested three days.(X)

33 On the fourth day, in the house of our God, we weighed out(Y) the silver and gold and the sacred articles into the hands of Meremoth(Z) son of Uriah, the priest. Eleazar son of Phinehas was with him, and so were the Levites Jozabad(AA) son of Jeshua and Noadiah son of Binnui.(AB) 34 Everything was accounted for by number and weight, and the entire weight was recorded at that time.

35 Then the exiles who had returned from captivity sacrificed burnt offerings to the God of Israel: twelve bulls(AC) for all Israel,(AD) ninety-six rams, seventy-seven male lambs and, as a sin offering,[g] twelve male goats.(AE) All this was a burnt offering to the Lord. 36 They also delivered the king’s orders(AF) to the royal satraps and to the governors of Trans-Euphrates,(AG) who then gave assistance to the people and to the house of God.(AH)

Footnotes

  1. Ezra 8:5 Some Septuagint manuscripts (also 1 Esdras 8:32); Hebrew does not have Zattu.
  2. Ezra 8:10 Some Septuagint manuscripts (also 1 Esdras 8:36); Hebrew does not have Bani.
  3. Ezra 8:26 That is, about 24 tons or about 22 metric tons
  4. Ezra 8:26 That is, about 3 3/4 tons or about 3.4 metric tons
  5. Ezra 8:26 That is, about 3 3/4 tons or about 3.4 metric tons
  6. Ezra 8:27 That is, about 19 pounds or about 8.4 kilograms
  7. Ezra 8:35 Or purification offering