Add parallel Print Page Options

Abramu gba Lọti là

14 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí nì ni Soari) jagun. Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí Àfonífojì Siddimu (Òkun iyọ̀). Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.

Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu, àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù. Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (èyí yìí ni Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.

Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu, láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún). 10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà-ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè. 11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ. 12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.

13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀. 14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó-lé-lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn (318), ó sì lépa wọn títí dé Dani. 15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku. 16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.

17 (A)Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní Àfonífojì Ṣafe (èyí tí ó túmọ̀ sí Àfonífojì Ọba).

18 Melkisedeki ọba Salẹmu (Jerusalẹmu) sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo. 19 Ó sì súre fún Abramu wí pé,

“Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo
    Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,
    tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.”

Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.

21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”

22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè, 23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’ 24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

Abram Rescues Lot

14 At the time when Amraphel was king of Shinar,[a](A) Arioch king of Ellasar, Kedorlaomer(B) king of Elam(C) and Tidal king of Goyim, these kings went to war against Bera king of Sodom, Birsha king of Gomorrah, Shinab king of Admah, Shemeber king of Zeboyim,(D) and the king of Bela (that is, Zoar).(E) All these latter kings joined forces in the Valley of Siddim(F) (that is, the Dead Sea Valley(G)). For twelve years they had been subject to Kedorlaomer,(H) but in the thirteenth year they rebelled.

In the fourteenth year, Kedorlaomer(I) and the kings allied with him went out and defeated the Rephaites(J) in Ashteroth Karnaim, the Zuzites in Ham, the Emites(K) in Shaveh Kiriathaim and the Horites(L) in the hill country of Seir,(M) as far as El Paran(N) near the desert. Then they turned back and went to En Mishpat (that is, Kadesh),(O) and they conquered the whole territory of the Amalekites,(P) as well as the Amorites(Q) who were living in Hazezon Tamar.(R)

Then the king of Sodom, the king of Gomorrah,(S) the king of Admah, the king of Zeboyim(T) and the king of Bela (that is, Zoar)(U) marched out and drew up their battle lines in the Valley of Siddim(V) against Kedorlaomer(W) king of Elam,(X) Tidal king of Goyim, Amraphel king of Shinar and Arioch king of Ellasar—four kings against five. 10 Now the Valley of Siddim(Y) was full of tar(Z) pits, and when the kings of Sodom and Gomorrah(AA) fled, some of the men fell into them and the rest fled to the hills.(AB) 11 The four kings seized all the goods(AC) of Sodom and Gomorrah and all their food; then they went away. 12 They also carried off Abram’s nephew Lot(AD) and his possessions, since he was living in Sodom.

13 A man who had escaped came and reported this to Abram the Hebrew.(AE) Now Abram was living near the great trees of Mamre(AF) the Amorite, a brother[b] of Eshkol(AG) and Aner, all of whom were allied with Abram. 14 When Abram heard that his relative(AH) had been taken captive, he called out the 318 trained(AI) men born in his household(AJ) and went in pursuit as far as Dan.(AK) 15 During the night Abram divided his men(AL) to attack them and he routed them, pursuing them as far as Hobah, north of Damascus.(AM) 16 He recovered(AN) all the goods(AO) and brought back his relative Lot and his possessions, together with the women and the other people.

17 After Abram returned from defeating Kedorlaomer(AP) and the kings allied with him, the king of Sodom(AQ) came out to meet him in the Valley of Shaveh (that is, the King’s Valley).(AR)

18 Then Melchizedek(AS) king of Salem(AT) brought out bread(AU) and wine.(AV) He was priest of God Most High,(AW) 19 and he blessed Abram,(AX) saying,

“Blessed be Abram by God Most High,(AY)
    Creator of heaven and earth.(AZ)
20 And praise be to God Most High,(BA)
    who delivered your enemies into your hand.”

Then Abram gave him a tenth of everything.(BB)

21 The king of Sodom(BC) said to Abram, “Give me the people and keep the goods(BD) for yourself.”

22 But Abram said to the king of Sodom,(BE) “With raised hand(BF) I have sworn an oath to the Lord, God Most High,(BG) Creator of heaven and earth,(BH) 23 that I will accept nothing belonging to you,(BI) not even a thread or the strap of a sandal, so that you will never be able to say, ‘I made Abram rich.’ 24 I will accept nothing but what my men have eaten and the share that belongs to the men who went with me—to Aner, Eshkol and Mamre.(BJ) Let them have their share.”

Footnotes

  1. Genesis 14:1 That is, Babylonia; also in verse 9
  2. Genesis 14:13 Or a relative; or an ally