Add parallel Print Page Options

Ìkìlọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn

Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan. Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i, kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnrarẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀. Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ ààmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.

Jesu bí arákùnrin rẹ̀

Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí. (A)Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé:

“Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀,
    tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?
Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ;
    ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé,
    ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ:
    Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.”

Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀ Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.

10 Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà. 11 Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá: Nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin. 12 (B)Àti wí pé,

“Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi,
    ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”

13 (C)Àti pẹ̀lú,

“Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.”

Àti pẹ̀lú,

“Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”

14 Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù. 15 Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù. 16 (D)Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún. 17 Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn. 18 Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.

Warning to Pay Attention

We must pay the most careful attention, therefore, to what we have heard, so that we do not drift away.(A) For since the message spoken(B) through angels(C) was binding, and every violation and disobedience received its just punishment,(D) how shall we escape if we ignore so great a salvation?(E) This salvation, which was first announced by the Lord,(F) was confirmed to us by those who heard him.(G) God also testified to it by signs, wonders and various miracles,(H) and by gifts of the Holy Spirit(I) distributed according to his will.(J)

Jesus Made Fully Human

It is not to angels that he has subjected the world to come, about which we are speaking. But there is a place where someone(K) has testified:

“What is mankind that you are mindful of them,
    a son of man that you care for him?(L)
You made them a little[a] lower than the angels;
    you crowned them with glory and honor
    and put everything under their feet.”[b][c](M)

In putting everything under them,[d] God left nothing that is not subject to them.[e] Yet at present we do not see everything subject to them.[f] But we do see Jesus, who was made lower than the angels for a little while, now crowned with glory and honor(N) because he suffered death,(O) so that by the grace of God he might taste death for everyone.(P)

10 In bringing many sons and daughters to glory, it was fitting that God, for whom and through whom everything exists,(Q) should make the pioneer of their salvation perfect through what he suffered.(R) 11 Both the one who makes people holy(S) and those who are made holy(T) are of the same family. So Jesus is not ashamed to call them brothers and sisters.[g](U) 12 He says,

“I will declare your name to my brothers and sisters;
    in the assembly I will sing your praises.”[h](V)

13 And again,

“I will put my trust in him.”[i](W)

And again he says,

“Here am I, and the children God has given me.”[j](X)

14 Since the children have flesh and blood,(Y) he too shared in their humanity(Z) so that by his death he might break the power(AA) of him who holds the power of death—that is, the devil(AB) 15 and free those who all their lives were held in slavery by their fear(AC) of death. 16 For surely it is not angels he helps, but Abraham’s descendants.(AD) 17 For this reason he had to be made like them,[k](AE) fully human in every way, in order that he might become a merciful(AF) and faithful high priest(AG) in service to God,(AH) and that he might make atonement for the sins of the people.(AI) 18 Because he himself suffered when he was tempted, he is able to help those who are being tempted.(AJ)

Footnotes

  1. Hebrews 2:7 Or them for a little while
  2. Hebrews 2:8 Psalm 8:4-6
  3. Hebrews 2:8 Or You made him a little lower than the angels;/ you crowned him with glory and honor/ and put everything under his feet.”
  4. Hebrews 2:8 Or him
  5. Hebrews 2:8 Or him
  6. Hebrews 2:8 Or him
  7. Hebrews 2:11 The Greek word for brothers and sisters (adelphoi) refers here to believers, both men and women, as part of God’s family; also in verse 12; and in 3:1, 12; 10:19; 13:22.
  8. Hebrews 2:12 Psalm 22:22
  9. Hebrews 2:13 Isaiah 8:17
  10. Hebrews 2:13 Isaiah 8:18
  11. Hebrews 2:17 Or like his brothers