Add parallel Print Page Options

10 Israẹli jẹ́ igi àjàrà tó gbilẹ̀
    ó ń so èso fún ara rẹ̀
Bí èso rẹ̀ ṣe ń pọ̀
    bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ pẹpẹ sí i
bí ilẹ̀ rẹ̀ ṣe ń ṣe rere
    o bu ọlá fún òkúta ìyàsọ́tọ̀ ère rẹ̀.
Ọkàn wọn kún fún ìtànjẹ
    báyìí wọ́n gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn.
Olúwa yóò wó pẹpẹ wọn palẹ̀
    yóò sì pa gbogbo òkúta ìyàsọ́tọ̀ wọn run.

Nígbà náà ni wọn yóò wí pé, “A kò ní ọba
    nítorí tí a kò bọ̀wọ̀ fún Olúwa
ṣùgbọ́n bí a tilẹ̀ ní ọba,
    kí ni yóò ṣe fún wa?”
Wọ́n ṣe ìlérí púpọ̀,
    wọ́n ṣe ìbúra èké,
    wọ́n da májẹ̀mú;
báyìí ni ìdájọ́ hù sókè bí igi ìwọ̀ ni aporo oko,
    bi i koríko májèlé láàrín oko tí a ro.
Àwọn ènìyàn tí ń gbé Samaria bẹ̀rù
    nítorí ère abo màlúù tó wà ní Beti-Afeni
Àwọn ènìyàn rẹ̀ yóò ṣọ̀fọ̀ le e lórí
    bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà rẹ̀
Gbogbo àwọn tó láyọ̀ sì dídán rẹ̀,
    nítorí tí a ti mú lọ sí ìgbèkùn.
A ó gbé lọ sí Asiria
    gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún ọba ńlá
a ó dójútì Efraimu;
    ojú yóò ti Israẹli nítorí ìgbìmọ̀ rẹ̀
Bí igi tó léfòó lórí omi ni
    Samaria àti àwọn ọba rẹ yóò sàn lọ.
(A)Àwọn ibi gíga tí ẹ tí ń hùwà búburú ni a o parun—
    èyí ni ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli.
Ẹ̀gún ọ̀gàn àti ẹ̀gún òṣùṣú yóò hù jáde,
    yóò sì bo àwọn pẹpẹ wọn.
Wọn yóò sọ fún àwọn òkè gíga pé, “Bò wá mọ́lẹ̀!”
    àti fún àwọn òkè kéékèèkéé pé, “Ṣubú lù wá!”

“Láti ìgbà Gibeah, ni ó ti ṣẹ̀, ìwọ Israẹli
    ìwọ sì tún wà níbẹ̀.
Ǹjẹ́ ogun kò lé
    ẹ̀yin aṣebi ni Gibeah bá bí?
10 Nígbà tó bá tẹ́ mi lọ́rùn, èmi yóò fi ìyà jẹ wọ́n;
    orílẹ̀-èdè yóò kó ra wọn jọ wọ́n ó sì dojúkọ wọn
    Láti fi wọn sínú ìdè nítorí ìlọ́po ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 Efraimu jẹ́ ọmọ abo màlúù tí a tí kọ́,
    to si fẹ́ràn láti máa pa ọkà;
lórí ọrun rẹ̀ tó lẹ́wà ni
    èmi ó dí ẹrù wúwo lé.
Èmi yóò mú kí a gun Efraimu bí ẹṣin
    Juda yóò tú ilẹ̀,
    Jakọbu yóò sì fọ́ ògúlùtu rẹ̀.
12 (B)Ẹ gbin òdòdó fún ara yín,
    kí ẹ sì ká èso ìfẹ́ àìlópin,
Ẹ tu ilẹ̀ yín tí a kò ro,
    nítorí pé ó ti tó àsìkò láti wá Olúwa,
títí tí yóò fi dé,
    tí yóò sì rọ òjò òdodo lé yín lórí.
13 Ṣùgbọ́n ẹ tí gbin búburú ẹ si ka ibi,
    Ẹ ti jẹ èso èké
nítorí ẹ tí gbẹ́kẹ̀lé agbára yín
    àti àwọn ọ̀pọ̀ jagunjagun yín
14 Ariwo ogun yóò bo àwọn ènìyàn yín
    kí gbogbo odi agbára yín ba le parun.
Gẹ́gẹ́ bí Ṣalmani ṣe pa Beti-Arbeli run lọ́jọ́ ogun,
    nígbà tí a gbé àwọn ìyá ṣánlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn
15 Báyìí ni a o sì ṣe sí ọ, ìwọ Beteli,
    nítorí pé ìwà búburú yín ti pọ̀jù.
Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́ náà,
    a o pa ọba Israẹli run pátápátá.

10 Israel was a spreading vine;(A)
    he brought forth fruit for himself.
As his fruit increased,
    he built more altars;(B)
as his land prospered,(C)
    he adorned his sacred stones.(D)
Their heart is deceitful,(E)
    and now they must bear their guilt.(F)
The Lord will demolish their altars(G)
    and destroy their sacred stones.(H)

Then they will say, “We have no king
    because we did not revere the Lord.
But even if we had a king,
    what could he do for us?”
They make many promises,
    take false oaths(I)
    and make agreements;(J)
therefore lawsuits spring up
    like poisonous weeds(K) in a plowed field.
The people who live in Samaria fear
    for the calf-idol(L) of Beth Aven.[a](M)
Its people will mourn over it,
    and so will its idolatrous priests,(N)
those who had rejoiced over its splendor,
    because it is taken from them into exile.(O)
It will be carried to Assyria(P)
    as tribute(Q) for the great king.(R)
Ephraim will be disgraced;(S)
    Israel will be ashamed(T) of its foreign alliances.
Samaria’s king will be destroyed,(U)
    swept away like a twig on the surface of the waters.
The high places(V) of wickedness[b](W) will be destroyed—
    it is the sin of Israel.
Thorns(X) and thistles will grow up
    and cover their altars.(Y)
Then they will say to the mountains, “Cover us!”(Z)
    and to the hills, “Fall on us!”(AA)

“Since the days of Gibeah,(AB) you have sinned,(AC) Israel,
    and there you have remained.[c]
Will not war again overtake
    the evildoers in Gibeah?
10 When I please, I will punish(AD) them;
    nations will be gathered against them
    to put them in bonds for their double sin.
11 Ephraim is a trained heifer
    that loves to thresh;
so I will put a yoke(AE)
    on her fair neck.
I will drive Ephraim,
    Judah must plow,
    and Jacob must break up the ground.
12 Sow(AF) righteousness(AG) for yourselves,
    reap the fruit of unfailing love,
and break up your unplowed ground;(AH)
    for it is time to seek(AI) the Lord,
until he comes
    and showers his righteousness(AJ) on you.
13 But you have planted wickedness,
    you have reaped evil,(AK)
    you have eaten the fruit of deception.(AL)
Because you have depended on your own strength
    and on your many warriors,(AM)
14 the roar of battle will rise against your people,
    so that all your fortresses will be devastated(AN)
as Shalman(AO) devastated Beth Arbel on the day of battle,
    when mothers were dashed to the ground with their children.(AP)
15 So will it happen to you, Bethel,
    because your wickedness is great.
When that day dawns,
    the king of Israel will be completely destroyed.(AQ)

Footnotes

  1. Hosea 10:5 Beth Aven means house of wickedness (a derogatory name for Bethel, which means house of God).
  2. Hosea 10:8 Hebrew aven, a reference to Beth Aven (a derogatory name for Bethel); see verse 5.
  3. Hosea 10:9 Or there a stand was taken