Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Babeli

13 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli

    èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí:
Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu,
    kígbe sí wọn, pè wọ́n
    láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi,
    mo ti pe àwọn jagunjagun mi
láti gbé ìbínú mi jáde
    àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.

Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè,
    gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn
Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba,
    gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè!
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ
    àwọn jagunjagun fún ogun.
Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré,
    láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá
Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀,
    láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.

Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí,
    yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ,
    ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú,
    ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú,
wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí.
    Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà
    ojú wọn á sì gbinájẹ.

Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀
    ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú
àti ìrunú gbígbóná—
    láti sọ ilẹ̀ náà dahoro,
    àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
10 (B)Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn
    kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn
    àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀,
    àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga
    èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn
    ju ojúlówóo wúrà lọ,
    yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì;
    ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀
láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.

14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀,
    gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́,
ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ,
    ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu,
    gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn,
    gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó
    àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.

17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn,
    àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà
    tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀;
    wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé
    tàbí kí wọn ṣíjú àánú wo àwọn ọmọdé.
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba
    ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli
ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́
    tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran;
    Ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́,
    olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
21 (C)Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀,
    àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn,
níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé
    níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn,
    àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.

14 Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu,

    yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i
    yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn.
Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn,
    wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n
    wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn.
Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè
    gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin
ní ilẹ̀ Olúwa.
    Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn
    wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.

Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà, ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé:

    Báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin!
    Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà,
    ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀
    pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró,
nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè
    pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà,
    wọ́n bú sí orin.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn
    igi kedari ti Lebanoni
ń yọ̀ lórí rẹ wí pé,
    “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí,
    kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”

Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè
    láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀
ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ
    gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé
ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn
    gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Gbogbo wọn yóò dáhùn,
    wọn yóò wí fún ọ wí pé,
“Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú
    ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì,
    pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ,
àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ
    àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12 Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá,
    ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà!
A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé
    Ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé,
    “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run;
Èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè
    ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run,
Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ
    ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀;
    Èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ
    lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun.

16 Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ,
    wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ:
“Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì
    tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù,
    tí ó sì pa ìlú ńláńlá rẹ̀ run
    tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”

18 Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀
    ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì
    gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀,
àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀,
    àwọn tí idà ti gún,
àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun.
    Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 A kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn,
    nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́
    o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ.

Ìran àwọn ìkà
    ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ
    nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn,
    wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀
    kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.

22 “Èmi yóò dìde sókè sí wọn,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà,
    àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,”
    ni Olúwa wí.
23 Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí
    àti sí irà;
Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a,
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Ìṣubú Babeli

47 (A)“Sọ̀kalẹ̀, jókòó nínú eruku,
    wúńdíá ọmọbìnrin Babeli;
jókòó ní ilẹ̀ láìsí ìtẹ́,
    ọmọbìnrin àwọn ará Babeli.
    A kì yóò pè ọ́ ní aláìlókun àti ẹlẹgẹ́ mọ́.
Mú òkúta-ọlọ kí o sì lọ ìyẹ̀fun;
    mú ìbòjú rẹ kúrò.
Ká aṣọ ẹsẹ̀ rẹ sókè, ká aṣọ itan,
    kí o sì la odò wọ̀n-ọn-nì kọjá.
Ìhòhò rẹ ni a ó sí síta
    àti ìtìjú rẹ ni a ó ṣí sílẹ̀.
Èmi yóò sì gba ẹ̀san;
    Èmi kì yóò sì dá ẹnìkan sí.”

Olùràpadà wa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀
    òun ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.

“Jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, lọ sínú òkùnkùn,
    ọmọbìnrin àwọn ará Babeli;
a kì yóò pè ọ́ ní ọbabìnrin
    àwọn ilẹ̀ ọba mọ́.
Inú bí mi sí àwọn ènìyàn mi
    tí mo sì ba ogún mi jẹ́;
Mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́,
    Ìwọ kò sì ṣíjú àánú wò wọ́n.
Lórí àwọn arúgbó pẹ̀lú
    ní o gbé àjàgà tí ó wúwo lé.
Ìwọ wí pé, ‘Èmi yóò tẹ̀síwájú títí láé—
    ọbabìnrin ayérayé!’
Ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi nǹkan wọ̀nyí
    tàbí kí o ronú nípa ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀.

(B)“Nísinsin yìí, tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ oníwọ̀ra ẹ̀dá
    tí o kẹ̀tẹ̀ǹfẹ̀ nínú ààbò rẹ
tí o sì ń sọ fún ara rẹ pé,
    ‘Èmi ni, kò sì ṣí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.
Èmi kì yóò di opó
    tàbí kí n pàdánù àwọn ọmọ.’
(C)Méjèèjì yìí ni yóò wá sórí rẹ
    láìpẹ́ jọjọ, ní ọjọ́ kan náà:
pípàdánù ọmọ àti dídi opó.
    Wọn yóò wá sórí rẹ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́,
pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ìṣe oṣó rẹ
    àti àwọn èpè rẹ tí ko lágbára.
10 Ìwọ ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ìwà ìkà rẹ
    ó sì ti wí pé, ‘kò sí ẹni tí ó rí mi?’
Ọgbọ́n àti òye rẹ ti ṣì ọ́ lọ́nà
    nígbà tí o wí fún ara rẹ pé,
    ‘Èmi ni, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.’
11 Ìparun yóò dé bá ọ
    bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò mọ ọ̀nà láti ré e kúrò.
Àjálù kan yóò ṣubú lù ọ́
    tí o kì yóò le è fi ètùtù ré kúrò;
òfò kan tí o kò le faradà ni
    yóò wá lójijì sí oríì rẹ.

12 “Tẹ̀síwájú nígbà náà, pẹ̀lú àfọ̀ṣẹ rẹ
    àti pẹ̀lú ìwà oṣó rẹ gbogbo,
tí o ti ń ṣiṣẹ́ fún láti ìgbà èwe rẹ wá.
    Bóyá o le è ṣàṣeyọrí,
    bóyá o le è dá rúgúdù sílẹ̀.
13 Gbogbo ìmọ̀ràn tí o ti gbà ni
    ó ti sọ ọ́ di akúrẹtẹ̀!
Jẹ́ kí àwọn awòràwọ̀ rẹ bọ́ síwájú,
    Àwọn awòràwọ̀ tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀
láti oṣù dé oṣù,
    jẹ́ kí wọ́n gbà ọ́ lọ́wọ́ ohun tí ó ń bọ̀ wá bá ọ.
14 Lóòótọ́ wọ́n dàbí ìṣẹ́pẹ́ igi;
    iná ni yóò jó wọn dànù.
Wọn kò kúkú lè gba ara wọn là
    lọ́wọ́ agbára iná náà.
Kò sí èédú láti mú ara ẹnikẹ́ni gbóná
    níhìn-ín kò sí iná tí ènìyàn le jókòó tì.
15 Gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe fún ọ nìyìí
    gbogbo èyí ní o tí ṣíṣẹ́ pẹ̀lú u rẹ̀
tí o sì ti ń rù kiri láti ìgbà èwe.
    Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ń lọ nínú àṣìṣe rẹ̀;
    kò sí ẹyọ ẹnìkan tí ó lè gbà ọ́.

Àsọtẹ́lẹ̀ ní ti Babeli

50 (A)Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:

“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde,
    kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀
    ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé,
‘a kó Babeli,
    ojú tí Beli,
    a fọ́ Merodaki túútúú,
ojú ti àwọn ère rẹ̀,
    a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò
    sì máa gbóguntì wọ́n.
Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò
    sá kúrò ní ìlú yìí.

“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,”
    ni Olúwa wí,
“Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá,
àwọn, àti àwọn ọmọ Juda,
    wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí
    Olúwa Ọlọ́run wọn
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn
    yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a
darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé,
    tí a kì yóò gbàgbé.

“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù,
    àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà,
wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè
    wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré,
    wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ
    àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi
nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé
    òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’

“Jáde kúrò ní Babeli,
    ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀,
    kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Nítorí pé èmi yóò ru,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè
ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀;
    Láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò
    dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo
    àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú
ìfẹ́ wọn ṣẹ,”
    ni Olúwa wí.

11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀,
    ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn
fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù,
    ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ
    yóò sì gba ìtìjú.
Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
    ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé;
    ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀.
Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò
    fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.

14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli
    àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà.
    Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Kígbe mọ-ọn ní gbogbo ọ̀nà!
    Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀,
níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa,
    gbẹ̀san lára rẹ̀.
    Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli,
    àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè!
Nítorí idà àwọn aninilára
    jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀,
    kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.

17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri,
    kìnnìún sì ti lé e lọ.
Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ,
    àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli
    fa egungun rẹ̀ ya.”

18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí;

“Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli
    padà wá pápá oko tútù rẹ̀
òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani,
    a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè
    Efraimu àti ní Gileadi
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,”
    ni Olúwa wí,
“À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli,
ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun;
    àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan
    nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.

21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn
    tí ó ń gbé ní Pekodi.
Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,”
    ni Olúwa
    “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà
    ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó,
    lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé!
    Báwo ní Babeli ti di ahoro
    ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀
    fún ọ ìwọ Babeli,
kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀,
    o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde,
    nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun
    ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo,
    sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀,
    ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà,
Kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun,
    ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ,
    jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n!
    Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé,
    àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá,
    sì sọ ní Sioni,
Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san,
    ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.

29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli,
    ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà.
Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀
    gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe,
ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga
    Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀
    yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn
ológun lẹ́nu mọ́,”
    Olúwa wí.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,”
    ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,
“nítorí ọjọ́ rẹ ti dé,
    àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò
    sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde.
Èmi yóò tan iná ní ìlú náà,
    èyí tí yóò sì jo run.”

33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ:

“A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli
    lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú.
Gbogbo àwọn tí ó kó wọn
    nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin
    wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára,
    Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀.
Yóò sì gbe ìjà wọn jà,
    kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà;
    ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.

35 “Idà lórí àwọn Babeli!”
    ni Olúwa wí,
“lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli,
    àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké
    wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun,
    wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀
    àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀.
Wọn yóò di obìnrin.
    Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ.
    Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère,
    àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.

39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù
    pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀,
abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀,
    a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé,
    bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba
    Sodomu àti Gomorra
pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,”
    ni Olúwa wí,
    “kì yóò sí ẹni tí yóò gbé ibẹ̀.

41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá;
    orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń
    gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun,
    wọ́n burú wọn kò sì ní àánú.
Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ.
    Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,
    ọwọ́ wọn sì rọ,
    ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani
    sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,
    Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.
Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?
    Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?
    Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”

45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí
    Olúwa sọ nípa Babeli
ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì
    sí Babeli; n ó sì pa
    agbo ẹran wọn run.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé;
    a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì,
a sì gbọ́ igbe náà
    láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

51 Ohùn ti Olúwa wí nìyìí:

“Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè
    sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli
    láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo;
wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà
    ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀
    jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀;
má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin
    sí, pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú
    ní Babeli tí wọn yóò sì
    fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni
    Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn
    kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.

(B)“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà
    fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
Àsìkò àti gbẹ̀san Ọlọ́run ni èyí,
    yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
(C)Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa;
    ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí.
Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀,
    wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́;
    Ẹ hu fun un!
Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ,
bóyá yóò le wo ọ́ sàn.

“ ‘À bá ti wo Babeli sàn,
    ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀,
kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè,
    ó ga àní títí dé òfúrufú.’

10 “ ‘Olúwa ti dá wa láre,
    wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa
    Ọlọ́run wa ti ṣe.’

11 “Ṣe ọfà rẹ ní mímú,
    mú apata!
    Olúwa ti ru ọba Media sókè,
nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run.
    Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Gbé àsíá sókè sí odi Babeli!
    Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí,
ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri,
    ẹ ṣètò àwọn tí yóò sápamọ́
Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde,
    òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 (D)Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,
    tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,
    àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,
    Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,
    wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.

15 “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,
    o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,
    o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Nígbà tí ará omi ọ̀run hó
    ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.
Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,
    ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.

17 “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ
    tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù
alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.
    Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.
18 Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà,
    nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí;
    nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,
àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún,
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

20 “Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi,
    ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú,
    èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;
    èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú
    èmi ó pa awakọ̀
22 Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,
    pẹ̀lú rẹ, mo pa
àgbàlagbà àti ọmọdé,
    Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn,
    àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú,
èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú,
    èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.

24 “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,”

    ni Olúwa wí.
25 “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun
    ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,”
    ni Olúwa wí.
“Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ,
    èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta,
    Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 A kò ní mú òkúta kankan láti
    ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí
fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di
    ahoro títí ayé,”
    Olúwa wí.

27 “Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà!
    Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀,
    pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́:
    Ararati, Minini àti Aṣkenasi.
Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,
    rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀,
    àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀,
àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 Ilẹ̀ wárìrì síhìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé
    ète Olúwa, sí Babeli dúró
láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà
    tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Gbogbo àwọn jagunjagun
    Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn.
Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.
    Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,
    gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn
    láti sọ fún ọba Babeli pé
    gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́
    ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”

33 Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí:

“Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”

34 “Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run,
    ó ti mú kí ìdààmú bá wa,
ó ti sọ wá di àgbá òfìfo.
    Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì.
Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀,
    lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,”
    èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí.
“Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,”
    ni Jerusalẹmu wí.

36 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:

“Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí
    ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san,
    èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 Babeli yóò parun pátápátá,
    yóò sì di ihò àwọn akátá,
    ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù
    bí ọmọ kìnnìún.
39 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè,
    èmi yóò ṣe àsè fún wọn,
èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó
    tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín,
lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,”
    ni Olúwa wí.
40 “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn
    tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.

41 “Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.
    Irú ìpayà wo ni yóò bá
    Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Òkun yóò ru borí Babeli,
    gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,
    ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn
    kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli
    àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì.
    Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́.
    Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.

45 “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀
    ẹ̀yin ènìyàn mi!
Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ!
    Sá fún ìbínú ńlá Ọlọ́run.
46 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú
    tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí
a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa;
    àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí,
òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá
    ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Nítorí ìgbà náà yóò wá
    dandan nígbà tí èmi
yóò fi ìyà jẹ àwọn
    òrìṣà Babeli, gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì
    gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,
    yóò sì kọrin lórí Babeli:
nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,”
    ni Olúwa wí.

49 “Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli,
    gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró:
    Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè,
    ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”

51 “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:
    ìtìjú ti bò wá lójú
    nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”

52 “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,
    “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀:
    àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀
53 Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,
    bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ,
síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,”
    Olúwa wí.

54 “Ìró igbe láti Babeli,
    àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ,
    ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀;
    àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀,
    àní sórí Babeli;
a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn:
    nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa,
    yóò san án nítòótọ́.
57 Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí,
    àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀
àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀,
    wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,”
    ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

58 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá,
    ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun:
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán,
    àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná,
    tí àárẹ̀ sì mú wọn.”

59 Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó. 60 Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli. 61 Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. 62 Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’ 63 (E)Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate. 64 Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’ ”

Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.