Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ ní ti Damasku

17 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Damasku:

    “Kíyèsi i, Damasku kò ní jẹ́ ìlú mọ́
    ṣùgbọ́n yóò padà di ààtàn.
Àwọn ìlú Aroeri ni a ó kọ̀sílẹ̀
    fún àwọn agbo ẹran tí yóò máa sùn síbẹ̀,
    láìsí ẹni tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Ìlú olódi ni yóò pòórá kúrò ní Efraimu,
    àti agbára ọba kúrò ní Damasku;
àwọn àṣẹ́kù Aramu yóò dá
    gẹ́gẹ́ bí ògo ti àwọn Israẹli,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Read full chapter

Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Damasku

23 Nípa Damasku,

“Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn,
    wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà
    láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a,
ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora
    bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀;
    ìlú tí mo dunnú sí.
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ
    yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo
àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa
    ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,”
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku,
    yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”

Read full chapter

Ìdájọ́ lórí àwọn ọ̀tá Israẹli

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀:

Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki,
    Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀;
nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn,
    àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.

Read full chapter