Isaiah 17:1-3
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ ní ti Damasku
17 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Damasku:
“Kíyèsi i, Damasku kò ní jẹ́ ìlú mọ́
ṣùgbọ́n yóò padà di ààtàn.
2 Àwọn ìlú Aroeri ni a ó kọ̀sílẹ̀
fún àwọn agbo ẹran tí yóò máa sùn síbẹ̀,
láìsí ẹni tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
3 Ìlú olódi ni yóò pòórá kúrò ní Efraimu,
àti agbára ọba kúrò ní Damasku;
àwọn àṣẹ́kù Aramu yóò dá
gẹ́gẹ́ bí ògo ti àwọn Israẹli,”
ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Jeremiah 49:23-27
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Damasku
23 Nípa Damasku,
“Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn,
wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà
láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a,
ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora
bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀;
ìlú tí mo dunnú sí.
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ
yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo
àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa
ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,”
ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku,
yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
Sekariah 9:1
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìdájọ́ lórí àwọn ọ̀tá Israẹli
9 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀:
Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki,
Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀;
nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn,
àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.