Isaiah 23:14
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
14 Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi;
wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!
Esekiẹli 27:26-30
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
26 Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọ
wá sínú omi ńlá.
Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́
ní àárín gbùngbùn Òkun.
27 Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ,
àwọn ìṣúra rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ.
Àwọn oníbàárà rẹ àti gbogbo àwọn
jagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹ
àti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹ
tí ó wà ní àárín rẹ
yóò rì sínú àárín gbùngbùn Òkun
ní ọjọ́ ìparun rẹ.
28 Ilẹ̀ etí Òkun yóò mì
nítorí ìró igbe àwọn atukọ̀ rẹ.
29 Gbogbo àwọn alájẹ̀,
àwọn atukọ̀ Òkun
àti àwọn atọ́kọ̀ ojú Òkun;
yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn,
wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.
30 Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọ
wọn yóò sì sọkún kíkorò lé ọ lórí
wọn yóò ku eruku lé orí ara wọn
wọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.