Add parallel Print Page Options

Ègbé ni fún Efraimu

28 Ègbé ni fún adé ìgbéraga,
    fún àwọn ọ̀mùtí Efraimu,
àti fún ìtànná rírọ, ẹwà ògo rẹ̀,
    tí ó tò sí orí àfonífojì ẹlẹ́tù lójú
    àti sí ìlú náà
    ìgbéraga àwọn tí ọtí wáìnì ń pa tí a rẹ̀ sílẹ̀
Kíyèsi i, Olúwa ní ẹnìkan tí ó le, tí ó sì lágbára,
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ yìnyín àti bí ìjì apanirun,
gẹ́gẹ́ bí àrọ̀dá òjò àti òjò tí ó mú ìkún omi wá,
    òun yóò fi tipátipá sọ ọ́ sílẹ̀.
Adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí Efraimu,
    ni a ó fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Òdòdó tí ó ń rọ náà tí í ṣe ẹwà ògo rẹ̀,
    tí ó tò sí orí àfonífojì ẹlẹ́tù lójú,
yóò dàbí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó pọ́n ṣáájú ìkórè
    bí ẹnikẹ́ni bá ti rí i tí ó sì mú un ní ọwọ́ rẹ̀,
    òun a sì mì ín.

Ní ọjọ́ náà Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    yóò jẹ́ adé tí ó lógo,
àti adé tí ó lẹ́wà
    fún àwọn ènìyàn rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù.
Òun yóò sì jẹ́ ẹ̀mí ìdájọ́ òdodo
    fún ẹni tí ó jókòó ní ìtẹ́ ìdájọ́
àti orísun agbára
    fún àwọn ẹni tí ó ń dá ogun padà ní ẹnu ibodè.

Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n fún ọtí wáìnì
    wọ́n pòòrì fún ọtí líle,
Àwọn àlùfáà àti wòlíì ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n fún ọtí líle
    wọ́n ta gíẹ́ gíẹ́ fún ọtí wáìnì
wọ́n ń lọ́ bìrì bìrì fún ọtí líle,
    wọ́n ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nígbà tí wọ́n ń ríran,
    wọ́n kọsẹ̀ nígbà tí wọ́n ń mú ìpinnu wá.
Gbogbo orí tábìlì ni ó kún fún èébì
    kò sì ṣí ibìkan tí kò sí ẹ̀gbin.

“Ta ni ẹni náà tí ó ń gbìyànjú àti kọ́?
    Ta ni ó sì ń ṣàlàyé ìròyìn in rẹ̀ fún?
Sí àwọn ọmọdé tí a já lẹ́nu ọmú wọn,
    sí àwọn tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gbà lẹ́nu ọmú.
10 Nítorí tí í ṣe: báyìí ni orí
    Ṣe, kí o si túnṣe, ṣe kí o si túnṣe,
àṣẹ n gorí àṣẹ, àṣẹ n gorí àṣẹ
    díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn.”

11 (A)Ó dára báyìí, pẹ̀lú ètè àjèjì àti ahọ́n àìmọ̀
    Ọlọ́run yóò bá àwọn ènìyàn yìí sọ̀rọ̀
12 (B)àwọn tí ó sọ fún wí pé,
    “Èyí ni ibi ìsinmi, jẹ́ kí àwọn aláàárẹ̀ sinmi”;
àti pé, “èyí ni ibi ìsinmi”
    ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sílẹ̀.
13 Fún ìdí èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa sí wọn yóò di pé
    Ṣe, kí o si túnṣe, ṣe kí o si túnṣe,
àṣẹ n gorí àṣẹ, àṣẹ n gorí àṣẹ
    díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn
bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò lọ tí wọn yóò tún ṣubú sẹ́yìn,
    wọn yóò fi ara pa, wọn yóò bọ́ sínú okùn
    a ó sì gbá wọn mú.

14 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn,
    tí ń jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní Jerusalẹmu.
15 Ẹ fọ́n pé, “Àwa ti bá ikú mulẹ̀,
    pẹ̀lú ibojì ni àwa ti jọ ṣe àdéhùn.
Nígbà tí ìbáwí gbígbóná fẹ́ kọjá,
    kò le kàn wá lára,
nítorí a ti fi irọ́ ṣe ààbò o wa
    àti àìṣòótọ́ ibi ìpamọ́ wa.”

16 (C)Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Kíyèsi i, èmi gbé òkúta kan lélẹ̀ ní Sioni, òkúta tí a dánwò,
    òkúta igun ilé iyebíye fún ìpìlẹ̀ tí ó dájú;
ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé
    kì yóò ní ìfòyà.
17 Èmi yóò fi ìdájọ́ ṣe okùn òṣùwọ̀n
    àti òdodo òjé òṣùwọ̀n;
yìnyín yóò gbá ààbò yín dànù àti irọ́,
    omi yóò sì kún bo gbogbo ibi tí
    ẹ ń fi ara pamọ́ sí mọ́lẹ̀.
18 Májẹ̀mú yín tí ẹ bá ikú dá ni a ó fa igi lé;
    àdéhùn yín pẹ̀lú ibojì ni kì yóò dúró.
Nígbà tí ìbínú gbígbóná náà bá fẹ́ kọjá,
    a ó ti ipa rẹ̀ lù yín bolẹ̀.
19 Nígbàkúgbà tí ó bá ti wá ni
    yóò máa gbé ọ lọ,
ni àràárọ̀, ní ọ̀sán àti ní òru,
    ni yóò máa fẹ́ kọjá lọ.”

Ìmòye ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yìí
    yóò máa mú ìpayà ńlá wá.
20 Ibùsùn kúrú púpọ̀ fún ìnara lé lórí,
    ìbora kò fẹ̀ tó láti yí ara yín ká.
21 Olúwa yóò dìde sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe
    ní òkè Peraṣimu
yóò ru ara rẹ̀ sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe
    ní Àfonífojì Gibeoni—
láti ṣe iṣẹ́ rẹ̀, abàmì iṣẹ́ ẹ rẹ̀,
    yóò ṣe iṣẹ́ rẹ̀, àní àjèjì iṣẹ́ rẹ̀.
22 Ní ìsinsin yìí ẹ dákẹ́ ẹlẹ́yà ṣíṣe,
    bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìdè e yín yóò le sí i;
Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ fún mi
    nípa àṣẹ ìparun ti ó ti pa lórí gbogbo ilẹ̀ náà.

23 Tẹ́tí kí o sì gbọ́ ohùn mi,
    fi ara balẹ̀ kí o sì gbọ́ ohun tí mo sọ.
24 Nígbà tí àgbẹ̀ kan bá tu ilẹ̀ láti gbìn
    yóò ha máa tulẹ̀ títí bi?
Ǹjẹ́ yóò ha máa tu ilẹ̀ kí
    ó sì máa jọ̀ ọ́ títí lọ bí?
25 Nígbà tí òun bá ti tẹ́ ojú ilẹ̀ rẹ̀ pẹrẹsẹ
    òun kò ha ń fúnrúgbìn dílì
kí ó sì fúnrúgbìn kummini ká?
    Kí ó sì gbin alikama lẹ́sẹẹsẹ,
barle tí a yàn,
    àti spelti ní ipò rẹ̀?
26 Ọlọ́run rẹ̀ tọ́ ọ ṣọ́nà
    ó sì kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ ní ọ̀nà tó tọ́.

27 Nítorí a kò fi ohun èlò ìpakà dili,
    bẹ́ẹ̀ ni a kì í yí kẹ̀kẹ́ ẹrù kiri lórí kummini;
ṣùgbọ́n ọ̀pá ni a fi ń pa dili jáde,
    ọ̀gọ ni a sì lu kummini.
28 A gbọdọ̀ lọ ìyẹ̀fun kí a tó ṣe àkàrà;
    bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì í máa pa á lọ títí láé.
Bí ó tilẹ̀ yí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ìpakà a rẹ̀ lórí i rẹ̀,
    àwọn ẹṣin rẹ̀ kò le lọ̀ ọ́.
29 Gbogbo èyí pẹ̀lú ti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá,
    oníyanu ní ìmọ̀ràn àti ológo ní ọgbọ́n.

Woe to the Leaders of Ephraim and Judah

28 Woe(A) to that wreath, the pride of Ephraim’s(B) drunkards,
    to the fading flower, his glorious beauty,
set on the head of a fertile valley(C)
    to that city, the pride of those laid low by wine!(D)
See, the Lord has one who is powerful(E) and strong.
    Like a hailstorm(F) and a destructive wind,(G)
like a driving rain and a flooding(H) downpour,
    he will throw it forcefully to the ground.
That wreath, the pride of Ephraim’s(I) drunkards,
    will be trampled(J) underfoot.
That fading flower, his glorious beauty,
    set on the head of a fertile valley,(K)
will be like figs(L) ripe before harvest—
    as soon as people see them and take them in hand,
    they swallow them.

In that day(M) the Lord Almighty
    will be a glorious(N) crown,(O)
a beautiful wreath
    for the remnant(P) of his people.
He will be a spirit of justice(Q)
    to the one who sits in judgment,(R)
a source of strength
    to those who turn back the battle(S) at the gate.

And these also stagger(T) from wine(U)
    and reel(V) from beer:
Priests(W) and prophets(X) stagger from beer
    and are befuddled with wine;
they reel from beer,
    they stagger when seeing visions,(Y)
    they stumble when rendering decisions.
All the tables are covered with vomit(Z)
    and there is not a spot without filth.

“Who is it he is trying to teach?(AA)
    To whom is he explaining his message?(AB)
To children weaned(AC) from their milk,(AD)
    to those just taken from the breast?
10 For it is:
    Do this, do that,
    a rule for this, a rule for that[a];
    a little here, a little there.(AE)

11 Very well then, with foreign lips and strange tongues(AF)
    God will speak to this people,(AG)
12 to whom he said,
    “This is the resting place, let the weary rest”;(AH)
and, “This is the place of repose”—
    but they would not listen.
13 So then, the word of the Lord to them will become:
    Do this, do that,
    a rule for this, a rule for that;
    a little here, a little there(AI)
so that as they go they will fall backward;
    they will be injured(AJ) and snared and captured.(AK)

14 Therefore hear the word of the Lord,(AL) you scoffers(AM)
    who rule this people in Jerusalem.
15 You boast, “We have entered into a covenant with death,(AN)
    with the realm of the dead we have made an agreement.
When an overwhelming scourge sweeps by,(AO)
    it cannot touch us,
for we have made a lie(AP) our refuge
    and falsehood[b] our hiding place.(AQ)

16 So this is what the Sovereign Lord says:

“See, I lay a stone in Zion,(AR) a tested stone,(AS)
    a precious cornerstone for a sure foundation;(AT)
the one who relies on it
    will never be stricken with panic.(AU)
17 I will make justice(AV) the measuring line
    and righteousness the plumb line;(AW)
hail(AX) will sweep away your refuge, the lie,
    and water will overflow(AY) your hiding place.
18 Your covenant with death will be annulled;
    your agreement with the realm of the dead will not stand.(AZ)
When the overwhelming scourge sweeps by,(BA)
    you will be beaten down(BB) by it.
19 As often as it comes it will carry you away;(BC)
    morning after morning,(BD) by day and by night,
    it will sweep through.”

The understanding of this message
    will bring sheer terror.(BE)
20 The bed is too short to stretch out on,
    the blanket too narrow to wrap around you.(BF)
21 The Lord will rise up as he did at Mount Perazim,(BG)
    he will rouse himself as in the Valley of Gibeon(BH)
to do his work,(BI) his strange work,
    and perform his task, his alien task.
22 Now stop your mocking,(BJ)
    or your chains will become heavier;
the Lord, the Lord Almighty, has told me
    of the destruction decreed(BK) against the whole land.(BL)

23 Listen(BM) and hear my voice;
    pay attention and hear what I say.
24 When a farmer plows for planting,(BN) does he plow continually?
    Does he keep on breaking up and working the soil?
25 When he has leveled the surface,
    does he not sow caraway and scatter cumin?(BO)
Does he not plant wheat in its place,[c]
    barley(BP) in its plot,[d]
    and spelt(BQ) in its field?
26 His God instructs him
    and teaches(BR) him the right way.

27 Caraway is not threshed(BS) with a sledge,(BT)
    nor is the wheel of a cart rolled over cumin;
caraway is beaten out with a rod,(BU)
    and cumin with a stick.
28 Grain must be ground to make bread;
    so one does not go on threshing it forever.
The wheels of a threshing cart(BV) may be rolled over it,
    but one does not use horses to grind grain.
29 All this also comes from the Lord Almighty,
    whose plan is wonderful,(BW)
    whose wisdom is magnificent.(BX)

Footnotes

  1. Isaiah 28:10 Hebrew / sav lasav sav lasav / kav lakav kav lakav (probably meaningless sounds mimicking the prophet’s words); also in verse 13
  2. Isaiah 28:15 Or false gods
  3. Isaiah 28:25 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.
  4. Isaiah 28:25 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.