Add parallel Print Page Options

Ìjọba òdodo náà

32 Wò ó, ọba kan yóò jẹ nínú òdodo
    àwọn olórí yóò máa fi ìdájọ́ ṣe àkóso.
Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò jẹ́ bí ibi ìṣápamọ́ kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́
    àti ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì,
gẹ́gẹ́ bí odò omi ní ilẹ̀ aṣálẹ̀,
    àti bí òjìji àpáta ńlá ní ilẹ̀ gbígbẹ.

Nígbà náà ni ojú àwọn tí ó rí kò ní padé mọ́,
    àti etí àwọn tí ó gbọ́ yóò tẹ́tí sílẹ̀.
Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè,
    àti ahọ́n tí ń kólòlò ni yóò là geerege.
A kò ní pe òmùgọ̀ ní ọlọ́lá mọ́
    tàbí kí a fi ọ̀wọ̀ tí ó ga jù fún aláìlóòótọ́ ènìyàn.
Nítorí òmùgọ̀ sọ̀rọ̀ òmùgọ̀,
    ọkàn rẹ̀ kún fún ìwà ibi:
òun hùwà àìwà-bí-Ọlọ́run
    ó sì ń tan àṣìṣe tí ó kan Olúwa kalẹ̀;
ẹni ebi ń pa ló fi sílẹ̀ lófo
    àti fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ
    ni ó mú omi kúrò.
Ibi ni gbogbo ọgbọ́n àwọn ìkà ènìyàn jẹ́,
    ó ń gba èrò búburú
láti fi ọ̀rọ̀ èké pa tálákà run,
    bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀bẹ̀ aláìní sì tọ̀nà.
Ṣùgbọ́n ọlọ́lá ènìyàn a máa pète ohun ńlá
    àti nípa èrò rere ni yóò dúró.

Àwọn obìnrin Jerusalẹmu

Ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ti gba ìtẹ́lọ́rùn gidi
    ẹ dìde kí ẹ tẹ́tí sí mi,
ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ọkàn yín ti balẹ̀,
    ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ!
10 Ní ó lé díẹ̀ ní ọdún kan
    ẹ̀yin tí ọkàn an yín balẹ̀ yóò wárìrì;
ìkórè àjàrà kò ní múnádóko,
    bẹ́ẹ̀ ni ìkórè èso kò ní sí.
11 Wárìrì, ẹ̀yin obìnrin onítẹ̀lọ́rùn
    bẹ̀rù, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ẹ rò pé ọkàn yín balẹ̀!
Ẹ bọ́ aṣọ yín kúrò,
    ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ yín.
12 Ẹ lu ọmú yín fún pápá ìgbádùn náà,
    fún àwọn àjàrà eléso
13 àti fún ilẹ̀ àwọn ènìyàn mi
    ilẹ̀ tí ó ti kún fún ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n—
bẹ́ẹ̀ ni, kẹ́dùn fún gbogbo ilé ìtura
    àti fún ìlú àríyá yìí.
14 Ilé olódi ni a ó kọ̀sílẹ̀,
    ìlù aláriwo ni a ó kọ̀ tì;
ilé olódi àti ilé ìṣọ́ ni yóò di ihò títí láéláé,
    ìdùnnú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti pápá
oko fún àwọn ẹran ọ̀sìn,
15 títí a ó fi tú Ẹ̀mí sí wa lórí láti òkè wá,
    àti ti aṣálẹ̀ tí yóò dí pápá oko ọlọ́ràá
    àti tí pápá ọlọ́ràá yóò dàbí ẹgàn.
16 Ẹ̀tọ́ yóò máa gbé ní inú aṣálẹ̀
    àti òdodo yóò sì máa gbé ní pápá oko ọlọ́ràá.
17 Èso òdodo náà yóò sì jẹ́ àlàáfíà;
    àbájáde òdodo yóò sì jẹ́ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé títí láé.
18 Àwọn ènìyàn mi yóò máa gbé ní ibùgbé àlàáfíà,
    ní ibùgbé ìdánilójú,
    ní àwọn ibi ìsinmi tí ó parọ́rọ́.
19 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé yìnyín ti tẹ́jú igbó pẹrẹsẹ
    àti tí ojú ìlú ti tẹ́ pẹrẹsẹ pátápátá,
20 báwo ni ẹ ó ti jẹ́ alábùkún tó,
    nípa gbígbin irúgbìn sí ipa odò gbogbo,
àti nípa jíjẹ́ kí àwọn màlúù yín àti
    àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ jẹ láìsí ìdíwọ́.

The Kingdom of Righteousness

32 See, a king(A) will reign in righteousness
    and rulers will rule with justice.(B)
Each one will be like a shelter(C) from the wind
    and a refuge from the storm,(D)
like streams of water(E) in the desert(F)
    and the shadow of a great rock in a thirsty land.

Then the eyes of those who see will no longer be closed,(G)
    and the ears(H) of those who hear will listen.
The fearful heart will know and understand,(I)
    and the stammering tongue(J) will be fluent and clear.
No longer will the fool(K) be called noble
    nor the scoundrel be highly respected.
For fools speak folly,(L)
    their hearts are bent on evil:(M)
They practice ungodliness(N)
    and spread error(O) concerning the Lord;
the hungry they leave empty(P)
    and from the thirsty they withhold water.
Scoundrels use wicked methods,(Q)
    they make up evil schemes(R)
to destroy the poor with lies,
    even when the plea of the needy(S) is just.(T)
But the noble make noble plans,
    and by noble deeds(U) they stand.(V)

The Women of Jerusalem

You women(W) who are so complacent,
    rise up and listen(X) to me;
you daughters who feel secure,(Y)
    hear what I have to say!
10 In little more than a year(Z)
    you who feel secure will tremble;
the grape harvest will fail,(AA)
    and the harvest of fruit will not come.
11 Tremble,(AB) you complacent women;
    shudder, you daughters who feel secure!(AC)
Strip off your fine clothes(AD)
    and wrap yourselves in rags.(AE)
12 Beat your breasts(AF) for the pleasant fields,
    for the fruitful vines(AG)
13 and for the land of my people,
    a land overgrown with thorns and briers(AH)
yes, mourn(AI) for all houses of merriment
    and for this city of revelry.(AJ)
14 The fortress(AK) will be abandoned,
    the noisy city deserted;(AL)
citadel and watchtower(AM) will become a wasteland forever,
    the delight of donkeys,(AN) a pasture for flocks,(AO)
15 till the Spirit(AP) is poured on us from on high,
    and the desert becomes a fertile field,(AQ)
    and the fertile field seems like a forest.(AR)
16 The Lord’s justice(AS) will dwell in the desert,(AT)
    his righteousness(AU) live in the fertile field.
17 The fruit of that righteousness(AV) will be peace;(AW)
    its effect will be quietness and confidence(AX) forever.
18 My people will live in peaceful(AY) dwelling places,
    in secure homes,(AZ)
    in undisturbed places of rest.(BA)
19 Though hail(BB) flattens the forest(BC)
    and the city is leveled(BD) completely,
20 how blessed you will be,
    sowing(BE) your seed by every stream,(BF)
    and letting your cattle and donkeys range free.(BG)