Add parallel Print Page Options

Ìdájọ́ Ọlọ́run lòdì sí àwọn orílẹ̀-èdè

34 (A)Súnmọ́ tòsí,
    ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti gbọ́,
tẹ́tí sílẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn
    jẹ́ kí ayé gbọ́,
àti ẹ̀kún rẹ̀,
    ayé àti ohun gbogbo tí ó ti inú rẹ̀ jáde.
Nítorí ìbínú Olúwa ń bẹ
    lára gbogbo orílẹ̀-èdè,
àti ìrunú rẹ̀ lórí gbogbo ogun wọn:
    o ti fi wọ́n fún pípa,
Àwọn ti a pa nínú wọn
    ni a ó sì jù sóde,
òórùn wọn yóò ti inú òkú wọn jáde,
    àwọn òkè ńlá yóò sì yọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ wọn
(B)Gbogbo àwọn ogun ọ̀run ni yóò di yíyọ́,
    a ó sì ká àwọn ọ̀run jọ bí i tákàdá,
gbogbo ogun wọn yóò si ṣubú lulẹ̀,
    bí ewé ti n bọ́ kúrò lára àjàrà,
    àti bí i bíbọ́ èso lára igi ọ̀pọ̀tọ́.

Nítorí ti a rẹ idà mi ní ọ̀run,
    kíyèsi í, yóò sọ̀kalẹ̀ wá sórí Edomu,
    sórí àwọn ènìyàn tí mo ti parun fún ìdájọ́.
Idà Olúwa kún fún ẹ̀jẹ̀
    a mú un sanra fún ọ̀rá,
àti fún ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́,
    fún ọ̀rá ìwé àgbò—
nítorí Olúwa ni ìrúbọ kan ní Bosra,
    àti ìpakúpa ńlá kan ní ilẹ̀ Edomu.
Àti àwọn àgbáǹréré yóò
    ba wọn sọ̀kalẹ̀ wá,
àti àwọn ẹgbọrọ màlúù
    pẹ̀lú àwọn akọ màlúù,
ilé wọn ni a ó fi ẹ̀jẹ̀ rin,
    a ó sì fi ọ̀rá sọ ekuru wọn di ọlọ́ràá.

Nítorí ọjọ́ ẹ̀san Olúwa ni,
    àti ọdún ìsanpadà,
    nítorí ọ̀ràn Sioni.
(C)Odò rẹ̀ ni a ó sì sọ di ọ̀dà,
    àti eruku rẹ̀ di imí-ọjọ́,
    ilẹ̀ rẹ̀ yóò sì di ọ̀dà tí ń jóná.
10 A kì yóò pa á ní òru tàbí ní ọ̀sán,
    èéfín rẹ̀ yóò gòkè láéláé:
yóò dahoro láti ìran dé ìran,
    kò sí ẹnìkan tí yóò là á kọjá láé
àti láéláé.
11 Òwìwí aginjù, àti àkàlà ni yóò ni ín,
    àti òwìwí àti ẹyẹ ìwò ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
Ọlọ́run yóò sì na sórí Edomu
    okùn ìwọ̀n ìparun
    àti òkúta òfo.
12 Ní ti àwọn ìjòyè rẹ̀
    ẹnìkan kì yóò sí níbẹ̀
tiwọn ó pè wá sí ìjọba,
    gbogbo àwọn olórí i rẹ̀ yóò sì di asán.
13 Ẹ̀gún yóò sì hù jáde
    nínú àwọn ààfin rẹ̀ wọ̀nyí,
ẹ̀gún ọ̀gán nínú ìlú olódi rẹ̀.
    Yóò jẹ́ ibùgbé àwọn akátá
    àti àgbàlá fún àwọn òwìwí.
14 Àwọn ẹranko ijù àti àwọn ìkookò ni yóò pàdé,
àti ewúrẹ́ igbó kan yóò máa kọ sí èkejì rẹ̀,
    iwin yóò máa gbé ibẹ̀ pẹ̀lú,
    yóò sì rí ibi ìsinmi fún ara rẹ̀.
15 Òwìwí yóò tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ síbẹ̀,
    yóò yé, yóò sì pa,
yóò sì kójọ lábẹ́ òjìji rẹ̀:
    àwọn gúnnugún yóò péjọ síbẹ̀ pẹ̀lú,
    olúkúlùkù pẹ̀lú ẹnìkejì rẹ̀.

16 Ẹ wá a nínú ìwé Olúwa, ẹ sì kà á:

Ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí kì yóò yẹ̀,
    kò sí ọ̀kan tí yóò fẹ́ èkejì rẹ̀ kù:
nítorí Olúwa ti pàṣẹ
    ẹnu rẹ̀ ló sì fi kó wọn jọ
    Ẹ̀mí rẹ̀ ló sì fi tò wọ́n jọ.
17 Ó ti di ìbò fún wọn,
    ọwọ́ rẹ̀ sì ti pín in fún wọn
nípa títa okùn,
    wọn ó jogún rẹ̀ láéláé,
láti ìran dé ìran
    ni wọn ó máa gbé inú rẹ̀.

Judgment Against the Nations

34 Come near, you nations, and listen;(A)
    pay attention, you peoples!(B)
Let the earth(C) hear, and all that is in it,
    the world, and all that comes out of it!(D)
The Lord is angry with all nations;
    his wrath(E) is on all their armies.
He will totally destroy[a](F) them,
    he will give them over to slaughter.(G)
Their slain(H) will be thrown out,
    their dead bodies(I) will stink;(J)
    the mountains will be soaked with their blood.(K)
All the stars in the sky will be dissolved(L)
    and the heavens rolled up(M) like a scroll;
all the starry host will fall(N)
    like withered(O) leaves from the vine,
    like shriveled figs from the fig tree.

My sword(P) has drunk its fill in the heavens;
    see, it descends in judgment on Edom,(Q)
    the people I have totally destroyed.(R)
The sword(S) of the Lord is bathed in blood,
    it is covered with fat—
the blood of lambs and goats,
    fat from the kidneys of rams.
For the Lord has a sacrifice(T) in Bozrah(U)
    and a great slaughter(V) in the land of Edom.
And the wild oxen(W) will fall with them,
    the bull calves and the great bulls.(X)
Their land will be drenched with blood,(Y)
    and the dust will be soaked with fat.

For the Lord has a day(Z) of vengeance,(AA)
    a year of retribution,(AB) to uphold Zion’s cause.
Edom’s streams will be turned into pitch,
    her dust into burning sulfur;(AC)
    her land will become blazing pitch!
10 It will not be quenched(AD) night or day;
    its smoke will rise forever.(AE)
From generation to generation(AF) it will lie desolate;(AG)
    no one will ever pass through it again.
11 The desert owl[b](AH) and screech owl[c] will possess it;
    the great owl[d] and the raven(AI) will nest there.
God will stretch out over Edom(AJ)
    the measuring line of chaos(AK)
    and the plumb line(AL) of desolation.
12 Her nobles will have nothing there to be called a kingdom,
    all her princes(AM) will vanish(AN) away.
13 Thorns(AO) will overrun her citadels,
    nettles and brambles her strongholds.(AP)
She will become a haunt for jackals,(AQ)
    a home for owls.(AR)
14 Desert creatures(AS) will meet with hyenas,(AT)
    and wild goats will bleat to each other;
there the night creatures(AU) will also lie down
    and find for themselves places of rest.
15 The owl will nest there and lay eggs,
    she will hatch them, and care for her young
    under the shadow of her wings;(AV)
there also the falcons(AW) will gather,
    each with its mate.

16 Look in the scroll(AX) of the Lord and read:

None of these will be missing,(AY)
    not one will lack her mate.
For it is his mouth(AZ) that has given the order,(BA)
    and his Spirit will gather them together.
17 He allots their portions;(BB)
    his hand distributes them by measure.
They will possess it forever
    and dwell there from generation to generation.(BC)

Footnotes

  1. Isaiah 34:2 The Hebrew term refers to the irrevocable giving over of things or persons to the Lord, often by totally destroying them; also in verse 5.
  2. Isaiah 34:11 The precise identification of these birds is uncertain.
  3. Isaiah 34:11 The precise identification of these birds is uncertain.
  4. Isaiah 34:11 The precise identification of these birds is uncertain.

Ọjọ́ ẹ̀san àti ìràpadà Ọlọ́run

63 (A)Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá,
    ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá?
Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀,
    tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀?

    “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo
    tí ó ní ipa láti gbàlà.”

Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa
    gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?

(B)“Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì;
    láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi.
Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi
    mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi
ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi,
    mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi
    àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé
Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́.
    Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́;
nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi
    àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi;
    nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu
    mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”

Read full chapter

God’s Day of Vengeance and Redemption

63 Who is this coming from Edom,(A)
    from Bozrah,(B) with his garments stained crimson?(C)
Who is this, robed in splendor,
    striding forward in the greatness of his strength?(D)

“It is I, proclaiming victory,
    mighty to save.”(E)

Why are your garments red,
    like those of one treading the winepress?(F)

“I have trodden the winepress(G) alone;
    from the nations no one was with me.
I trampled(H) them in my anger
    and trod them down in my wrath;(I)
their blood spattered my garments,(J)
    and I stained all my clothing.
It was for me the day of vengeance;(K)
    the year for me to redeem had come.
I looked, but there was no one(L) to help,
    I was appalled that no one gave support;
so my own arm(M) achieved salvation for me,
    and my own wrath sustained me.(N)
I trampled(O) the nations in my anger;
    in my wrath I made them drunk(P)
    and poured their blood(Q) on the ground.”

Read full chapter

Àsọtẹ́lẹ̀ Ní ti Edomu

(A)Nípa Edomu:

Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani?
    Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè?
    Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
Yípadà kí o sálọ, sápamọ́ sínú ihò,
    ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani,
nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau,
    ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá;
    ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀?
Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní
    kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò,
    èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn,
nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́.
    Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti
àwọn ará ilé rẹ yóò parun.
    Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀
    èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn.
    Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”

12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un. 13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”

14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
    A rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé,
    Ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.

15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di
    kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo;
    ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú
    ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ;
ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta,
    tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga
síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì;
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,”
    ni Olúwa wí.
17 “Edomu yóò di ahoro
    gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì
    fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu
    àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú
tí ó wà ní àyíká rẹ,”
    Olúwa wí.
“Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀;
    kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.

19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,
    Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.
Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?
    Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?
Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”

20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí
    Olúwa ní fún Edomu, ohun tí
ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani.
    Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde.
    Pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn,
    a ó gbọ́ igbe wọn
    ní Òkun pupa.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀,
    yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra.
Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun
    Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.

Read full chapter

A Message About Edom(A)(B)

Concerning Edom:(C)

This is what the Lord Almighty says:

“Is there no longer wisdom in Teman?(D)
    Has counsel perished from the prudent?
    Has their wisdom decayed?
Turn and flee, hide in deep caves,(E)
    you who live in Dedan,(F)
for I will bring disaster on Esau
    at the time when I punish him.
If grape pickers came to you,
    would they not leave a few grapes?
If thieves came during the night,
    would they not steal only as much as they wanted?
10 But I will strip Esau bare;
    I will uncover his hiding places,(G)
    so that he cannot conceal himself.
His armed men are destroyed,
    also his allies and neighbors,
    so there is no one(H) to say,
11 ‘Leave your fatherless children;(I) I will keep them alive.
    Your widows(J) too can depend on me.’”

12 This is what the Lord says: “If those who do not deserve to drink the cup(K) must drink it, why should you go unpunished?(L) You will not go unpunished, but must drink it. 13 I swear(M) by myself,” declares the Lord, “that Bozrah(N) will become a ruin and a curse,[a] an object of horror(O) and reproach;(P) and all its towns will be in ruins forever.”(Q)

14 I have heard a message from the Lord;
    an envoy was sent to the nations to say,
“Assemble yourselves to attack it!
    Rise up for battle!”

15 “Now I will make you small among the nations,
    despised by mankind.
16 The terror you inspire
    and the pride(R) of your heart have deceived you,
you who live in the clefts of the rocks,(S)
    who occupy the heights of the hill.
Though you build your nest(T) as high as the eagle’s,
    from there I will bring you down,”
declares the Lord.
17 “Edom will become an object of horror;(U)
    all who pass by will be appalled and will scoff
    because of all its wounds.(V)
18 As Sodom(W) and Gomorrah(X) were overthrown,
    along with their neighboring towns,”
says the Lord,
“so no one will live there;
    no people will dwell(Y) in it.

19 “Like a lion(Z) coming up from Jordan’s thickets(AA)
    to a rich pastureland,
I will chase Edom from its land in an instant.
    Who is the chosen one I will appoint for this?
Who is like(AB) me and who can challenge me?(AC)
    And what shepherd(AD) can stand against me?”

20 Therefore, hear what the Lord has planned against Edom,(AE)
    what he has purposed(AF) against those who live in Teman:(AG)
The young of the flock(AH) will be dragged away;
    their pasture will be appalled at their fate.(AI)
21 At the sound of their fall the earth will tremble;(AJ)
    their cry(AK) will resound to the Red Sea.[b]
22 Look! An eagle will soar and swoop(AL) down,
    spreading its wings over Bozrah.(AM)
In that day the hearts of Edom’s warriors(AN)
    will be like the heart of a woman in labor.(AO)

Read full chapter

Footnotes

  1. Jeremiah 49:13 That is, its name will be used in cursing (see 29:22); or, others will see that it is cursed.
  2. Jeremiah 49:21 Or the Sea of Reeds

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Edomu

12 (A)“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀, 13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú. 14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi: wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’ ”

Read full chapter

A Prophecy Against Edom

12 “This is what the Sovereign Lord says: ‘Because Edom(A) took revenge on Judah and became very guilty by doing so, 13 therefore this is what the Sovereign Lord says: I will stretch out my hand(B) against Edom and kill both man and beast.(C) I will lay it waste, and from Teman(D) to Dedan(E) they will fall by the sword.(F) 14 I will take vengeance on Edom by the hand of my people Israel, and they will deal with Edom in accordance with my anger(G) and my wrath; they will know my vengeance, declares the Sovereign Lord.’”(H)

Read full chapter

Àsọtẹ́lẹ̀ si Edomu

35 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá: “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i Kí o sì sọ wí pé: ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro. Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.

“ ‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó, nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ. Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ: àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ. Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé; Kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.

10 “ ‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi Olúwa wà níbẹ̀, 11 nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ. 12 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.” 13 Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ. 14 Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro 15 Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa.’ ”

A Prophecy Against Edom

35 The word of the Lord came to me: “Son of man, set your face against Mount Seir;(A) prophesy against it and say: ‘This is what the Sovereign Lord says: I am against you, Mount Seir, and I will stretch out my hand(B) against you and make you a desolate waste.(C) I will turn your towns into ruins(D) and you will be desolate. Then you will know that I am the Lord.(E)

“‘Because you harbored an ancient hostility and delivered the Israelites over to the sword(F) at the time of their calamity,(G) the time their punishment reached its climax,(H) therefore as surely as I live, declares the Sovereign Lord, I will give you over to bloodshed(I) and it will pursue you.(J) Since you did not hate bloodshed, bloodshed will pursue you. I will make Mount Seir a desolate waste(K) and cut off from it all who come and go.(L) I will fill your mountains with the slain; those killed by the sword will fall on your hills and in your valleys and in all your ravines.(M) I will make you desolate forever;(N) your towns will not be inhabited. Then you will know that I am the Lord.(O)

10 “‘Because you have said, “These two nations and countries will be ours and we will take possession(P) of them,” even though I the Lord was there, 11 therefore as surely as I live, declares the Sovereign Lord, I will treat you in accordance with the anger(Q) and jealousy you showed in your hatred of them and I will make myself known among them when I judge you.(R) 12 Then you will know that I the Lord have heard all the contemptible things you have said against the mountains of Israel. You said, “They have been laid waste and have been given over to us to devour.(S) 13 You boasted(T) against me and spoke against me without restraint, and I heard it.(U) 14 This is what the Sovereign Lord says: While the whole earth rejoices, I will make you desolate.(V) 15 Because you rejoiced(W) when the inheritance of Israel became desolate, that is how I will treat you. You will be desolate, Mount Seir,(X) you and all of Edom.(Y) Then they will know that I am the Lord.’”

Ìran ti Ọbadiah.

(A)Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.

Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:
    A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,
“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”

“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;
    ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,
Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,
    ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,
    tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,
ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,
    ‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,
    bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”
    ni Olúwa wí.
“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,
    bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,
Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:
    wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?
Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,
    wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,
    tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ
    ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:
Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;
    àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,
    ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”

Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,
    Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,
    àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,
    gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau
    ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,
    ìtìjú yóò bò ọ,
    a ó sì pa ọ run títí láé.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,
    ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,
tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ
    tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,
    ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,
    ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀
ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,
    ní ọjọ́ ìparun wọn
ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀
    ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,
    ní ọjọ́ àjálù wọn.
Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀
    nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.
Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,
    ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà
    láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.
Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú
    wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé
    lórí gbogbo àwọn kèfèrí.
Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;
    ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi
    bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí
Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn
    wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni
    Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́
àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná
    àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná
ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko
    wọn yóò fi iná sí i,
wọn yóò jo run.
    Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”
Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,
    àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni
ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.
    Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;
    Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani
    yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;
àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi
    yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá
    láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.
    Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

Obadiah’s Vision(A)(B)

The vision(C) of Obadiah.

This is what the Sovereign Lord says about Edom(D)

We have heard a message from the Lord:
    An envoy(E) was sent to the nations to say,
“Rise, let us go against her for battle”(F)

“See, I will make you small(G) among the nations;
    you will be utterly despised.
The pride(H) of your heart has deceived you,
    you who live in the clefts of the rocks[a](I)
    and make your home on the heights,
you who say to yourself,
    ‘Who can bring me down to the ground?’(J)
Though you soar like the eagle
    and make your nest(K) among the stars,
    from there I will bring you down,”(L)
declares the Lord.(M)
“If thieves came to you,
    if robbers in the night—
oh, what a disaster awaits you!—
    would they not steal only as much as they wanted?
If grape pickers came to you,
    would they not leave a few grapes?(N)
But how Esau will be ransacked,
    his hidden treasures pillaged!
All your allies(O) will force you to the border;
    your friends will deceive and overpower you;
those who eat your bread(P) will set a trap for you,[b]
    but you will not detect it.

“In that day,” declares the Lord,
    “will I not destroy(Q) the wise men of Edom,
    those of understanding in the mountains of Esau?
Your warriors, Teman,(R) will be terrified,
    and everyone in Esau’s mountains
    will be cut down in the slaughter.
10 Because of the violence(S) against your brother Jacob,(T)
    you will be covered with shame;
    you will be destroyed forever.(U)
11 On the day you stood aloof
    while strangers carried off his wealth
and foreigners entered his gates
    and cast lots(V) for Jerusalem,
    you were like one of them.(W)
12 You should not gloat(X) over your brother
    in the day of his misfortune,(Y)
nor rejoice(Z) over the people of Judah
    in the day of their destruction,(AA)
nor boast(AB) so much
    in the day of their trouble.(AC)
13 You should not march through the gates of my people
    in the day of their disaster,
nor gloat over them in their calamity(AD)
    in the day of their disaster,
nor seize their wealth
    in the day of their disaster.
14 You should not wait at the crossroads
    to cut down their fugitives,(AE)
nor hand over their survivors
    in the day of their trouble.

15 “The day of the Lord is near(AF)
    for all nations.
As you have done, it will be done to you;
    your deeds(AG) will return upon your own head.
16 Just as you drank(AH) on my holy hill,(AI)
    so all the nations will drink(AJ) continually;
they will drink and drink
    and be as if they had never been.(AK)
17 But on Mount Zion will be deliverance;(AL)
    it will be holy,(AM)
    and Jacob will possess his inheritance.(AN)
18 Jacob will be a fire
    and Joseph a flame;
Esau will be stubble,
    and they will set him on fire(AO) and destroy(AP) him.
There will be no survivors(AQ)
    from Esau.”
The Lord has spoken.

19 People from the Negev will occupy
    the mountains of Esau,
and people from the foothills will possess
    the land of the Philistines.(AR)
They will occupy the fields of Ephraim and Samaria,(AS)
    and Benjamin(AT) will possess Gilead.
20 This company of Israelite exiles who are in Canaan
    will possess the land as far as Zarephath;(AU)
the exiles from Jerusalem who are in Sepharad
    will possess the towns of the Negev.(AV)
21 Deliverers(AW) will go up on[c] Mount Zion
    to govern the mountains of Esau.
    And the kingdom will be the Lord’s.(AX)

Footnotes

  1. Obadiah 1:3 Or of Sela
  2. Obadiah 1:7 The meaning of the Hebrew for this clause is uncertain.
  3. Obadiah 1:21 Or from

Ọlọ́run fẹ́ràn Jakọbu, o sì kórìíra Esau

(A)(B) “Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’

“Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu, ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”

Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.”

Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa. Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’

Read full chapter

Israel Doubts God’s Love

“I have loved(A) you,” says the Lord.

“But you ask,(B) ‘How have you loved us?’

“Was not Esau Jacob’s brother?” declares the Lord. “Yet I have loved Jacob,(C) but Esau I have hated,(D) and I have turned his hill country into a wasteland(E) and left his inheritance to the desert jackals.(F)

Edom(G) may say, “Though we have been crushed, we will rebuild(H) the ruins.”

But this is what the Lord Almighty says: “They may build, but I will demolish.(I) They will be called the Wicked Land, a people always under the wrath of the Lord.(J) You will see it with your own eyes and say, ‘Great(K) is the Lord—even beyond the borders of Israel!’(L)

Read full chapter