Isaiah 52:7
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
7 (A)Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè
ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìhìnrere ayọ̀ wá,
tí wọ́n kéde àlàáfíà,
tí ó mú ìhìnrere wá,
tí ó kéde ìgbàlà,
tí ó sọ fún Sioni pé,
“Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!”
Nahumu 1:15
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
15 (A)Wò ó, lórí àwọn òkè,
àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,
ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà,
Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,
kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.
Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;
wọn yóò sì parun pátápátá.
Ìṣe àwọn Aposteli 10:36
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
36 Ẹyin mọ ọrọ̀ tí Ọlọ́run rán sí àwọn ọmọ Israẹli láti kéde ìròyìn ayọ̀ àlàáfíà nípasẹ̀ Jesu Kristi, ẹni ti ṣe Olúwa ohun gbogbo
Read full chapter
Romu 10:15
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
15 (A)Wọ́n ó ha sì ti ṣe wàásù, bí kò ṣe pé a rán wọn? Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹsẹ̀ àwọn tí ń wàásù ìhìnrere àlàáfíà ti dára tó, àwọn tí ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ohun rere!”
Read full chapterCopyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.