Add parallel Print Page Options

52 (A)Jí, jí, Ìwọ Sioni,
    wọ ara rẹ ní agbára.
Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀,
    ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́ n nì.
Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́
    kì yóò wọ inú rẹ mọ́.
Gbọn eruku rẹ kúrò;
    dìde sókè, kí o sì gúnwà, Ìwọ Jerusalẹmu.
Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò,
    ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbèkùn Sioni.

Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí;

    “Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́,
    láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà.”

Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.

“Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi sọ̀kalẹ̀
    lọ sí Ejibiti láti gbé;
    láìpẹ́ ni Asiria pọ́n wọn lójú.

(B)“Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?” ni Olúwa wí.

“Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́,
    àwọn tí ó sì ń jẹ ọba lórí wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,”
    ni Olúwa wí.
“Àti ní ọjọọjọ́
    orúkọ mi ni asọ̀rọ̀-òdì sí nígbà gbogbo.
Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi;
    nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀
pé Èmi ni ó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀.
    Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni.”

(C)Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè
    ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìhìnrere ayọ̀ wá,
tí wọ́n kéde àlàáfíà,
    tí ó mú ìhìnrere wá,
tí ó kéde ìgbàlà,
    tí ó sọ fún Sioni pé,
    “Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!”
Tẹ́tí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn sókè
    wọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀.
Nígbà tí Olúwa padà sí Sioni,
    wọn yóò rí i pẹ̀lú ojú u wọn.
Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀,
    ẹ̀yin ahoro Jerusalẹmu,
nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú,
    ó sì ti ra Jerusalẹmu padà.
10 (D)Olúwa yóò ṣí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀
    ní ojú gbogbo orílẹ̀-èdè,
àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò rí
    ìgbàlà Ọlọ́run wa.

11 (E)Ẹ túká, ẹ túká, ẹ jáde kúrò níhìn-ín-yìí!
    Ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan!
Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ kí ẹ sì di mímọ́,
    ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò Olúwa.
12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò yára kúrò
    tàbí kí ẹ sáré lọ;
nítorí Olúwa ni yóò síwájú yín lọ,
    Ọlọ́run Israẹli ni yóò sì ṣe ààbò lẹ́yìn ín yín.

Ìpọ́njú àti ògo ìránṣẹ́ náà

13 Kíyèsi i, ìránṣẹ́ mi yóò hùwà ọlọ́gbọ́n;
    òun ni a ó gbé sókè tí a ó sì gbéga
    a ó sì gbé e lékè gidigidi.
14 Gẹ́gẹ́ bí a ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń bu ọlá fún un—
    ìwò ojú rẹ ni a ti bàjẹ́ kọjá ti ẹnikẹ́ni àti ìrísí rẹ̀ ní a ti bàjẹ́ kọjá ohun tí ènìyàn ń fẹ́.
15 (F)Bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe bomirin àwọn orílẹ̀-èdè ká,
    àwọn ọba yóò sì pa ẹnu wọn mọ́ nítorí rẹ̀.
Nítorí ohun tí a kò sọ fún wọn, wọn yóò rí i,
    àti ohun tí wọn kò tí ì gbọ́, ni yóò sì yé wọn.

52 Awake, awake,(A) Zion,
    clothe yourself with strength!(B)
Put on your garments of splendor,(C)
    Jerusalem, the holy city.(D)
The uncircumcised(E) and defiled(F)
    will not enter you again.(G)
Shake off your dust;(H)
    rise up,(I) sit enthroned, Jerusalem.
Free yourself from the chains on your neck,(J)
    Daughter Zion,(K) now a captive.

For this is what the Lord says:

“You were sold for nothing,(L)
    and without money(M) you will be redeemed.(N)

For this is what the Sovereign Lord says:

“At first my people went down to Egypt(O) to live;
    lately, Assyria(P) has oppressed them.

“And now what do I have here?” declares the Lord.

“For my people have been taken away for nothing,
    and those who rule them mock,[a]
declares the Lord.
“And all day long
    my name is constantly blasphemed.(Q)
Therefore my people will know(R) my name;(S)
    therefore in that day(T) they will know
that it is I who foretold(U) it.
    Yes, it is I.”

How beautiful on the mountains(V)
    are the feet of those who bring good news,(W)
who proclaim peace,(X)
    who bring good tidings,
    who proclaim salvation,
who say to Zion,
    “Your God reigns!”(Y)
Listen! Your watchmen(Z) lift up their voices;(AA)
    together they shout for joy.(AB)
When the Lord returns(AC) to Zion,(AD)
    they will see it with their own eyes.
Burst into songs of joy(AE) together,
    you ruins(AF) of Jerusalem,
for the Lord has comforted(AG) his people,
    he has redeemed Jerusalem.(AH)
10 The Lord will lay bare his holy arm(AI)
    in the sight of all the nations,(AJ)
and all the ends of the earth(AK) will see
    the salvation(AL) of our God.

11 Depart,(AM) depart, go out from there!
    Touch no unclean thing!(AN)
Come out from it and be pure,(AO)
    you who carry the articles(AP) of the Lord’s house.
12 But you will not leave in haste(AQ)
    or go in flight;
for the Lord will go before you,(AR)
    the God of Israel will be your rear guard.(AS)

The Suffering and Glory of the Servant

13 See, my servant(AT) will act wisely[b];
    he will be raised and lifted up and highly exalted.(AU)
14 Just as there were many who were appalled(AV) at him[c]
    his appearance was so disfigured(AW) beyond that of any human being
    and his form marred beyond human likeness(AX)
15 so he will sprinkle(AY) many nations,[d]
    and kings(AZ) will shut their mouths(BA) because of him.
For what they were not told, they will see,
    and what they have not heard, they will understand.(BB)

Footnotes

  1. Isaiah 52:5 Dead Sea Scrolls and Vulgate; Masoretic Text wail
  2. Isaiah 52:13 Or will prosper
  3. Isaiah 52:14 Hebrew you
  4. Isaiah 52:15 Or so will many nations be amazed at him (see also Septuagint)