Add parallel Print Page Options

53 (A)Ta ni ó ti gba ìròyìn in wa gbọ́
    àti ta ni a ti fi apá Olúwa hàn fún?
Òun dàgbàsókè níwájú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ irúgbìn,
    àti gẹ́gẹ́ bí i gbòǹgbò tí ó jáde láti inú ìyàngbẹ ilẹ̀.
Òun kò ní ẹwà tàbí ògo láti fà wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
    kò sí ohun kankan nínú àbùdá rẹ̀
    tí ó fi yẹ kí a ṣàfẹ́rí i rẹ̀.
A kẹ́gàn rẹ̀ àwọn ènìyàn sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀,
    ẹni ìbànújẹ́, tí ó sì mọ bí ìpọ́njú ti rí.
Gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan tí àwọn ènìyàn ń fojú pamọ́ fún
    a kẹ́gàn rẹ, a kò sì bu ọlá fún un rárá.

(B)Lóòtítọ́ ó ti ru àìlera wa lọ
    ó sì ti ru ìbànújẹ́ wa pẹ̀lú,
síbẹ̀ a kà á sí ẹni tí Ọlọ́run lù,
    tí ó lù, tí a sì pọ́n lójú.
(C)Ṣùgbọ́n a sá a lọ́gbẹ́ nítorí àìṣedéédéé wa
    a pa á lára nítorí àìṣòdodo wa;
ìjìyà tí ó mú àlàáfíà wá fún wa wà lórí i rẹ̀,
    àti nípa ọgbẹ́ rẹ̀ ni a fi mú wa láradá.
Gbogbo wa bí àgùntàn, ti ṣìnà lọ,
    ẹnìkọ̀ọ̀kan wa ti yà sí ọ̀nà ara rẹ̀;
Olúwa sì ti gbé e ka orí ara rẹ̀
    gbogbo àìṣedéédéé wa.

(D)A jẹ ẹ́ ní yà, a sì pọ́n ọn lójú,
    síbẹ̀ kò ya ẹnu rẹ̀;
a mú un wá gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sọ́dọ̀ alápatà,
    àti gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí ó dákẹ́ níwájú olùrẹ́run rẹ̀,
    síbẹ̀ kò ya ẹnu rẹ̀.
Pẹ̀lú ìpọ́nlójú àti ìdánilẹ́jọ́ ni a mú un jáde lọ,
    ta ni ó sì le sọ nípa ìrànlọ́wọ́ rẹ̀?
Nítorí a ké e kúrò ní ilẹ̀ àwọn alààyè;
    nítorí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn mi ni a ṣe lù ú.
(E)A fún un ní ibojì pẹ̀lú àwọn ìkà,
    àti pẹ̀lú àwọn ọlọ́rọ̀ ní ikú rẹ̀,
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò hùwà jàgídíjàgan kan,
    tàbí kí a rí ẹ̀tàn kan ní ẹnu rẹ̀.

10 Síbẹ̀, ó wu Olúwa láti pa á lára
    àti láti mú kí ó jìyà,
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fi ayé rẹ̀
    fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀,
Òun yóò rí àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ àti ọjọ́ ayé
    rẹ̀ yóò pẹ́ títí,
    àti ète Olúwa ni yóò gbèrú ní ọwọ́ rẹ̀.
11 Lẹ́yìn ìpọ́njú ẹ̀mí rẹ̀,
    òun yóò rí ìmọ́lẹ̀, ààyè yóò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn;
nípa ìmọ̀ rẹ̀ ìránṣẹ́ mi olódodo yóò dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ láre,
    Òun ni yóò sì ru àìṣedéédéé wọn.
12 (F)Nítorí náà èmi yóò fún un ní ìpín pẹ̀lú àwọn ẹni ńlá
    òun yóò sì pín ìkógun pẹ̀lú àwọn alágbára,
nítorí pé òun jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ fún ikú,
    tí a sì kà á mọ́ àwọn alárékọjá.
Nítorí ó ru ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀,
    ó sì ṣe ìlàjà fún àwọn alárékọjá.

53 Who has believed our message(A)
    and to whom has the arm(B) of the Lord been revealed?(C)
He grew up before him like a tender shoot,(D)
    and like a root(E) out of dry ground.
He had no beauty or majesty to attract us to him,
    nothing in his appearance(F) that we should desire him.
He was despised and rejected by mankind,
    a man of suffering,(G) and familiar with pain.(H)
Like one from whom people hide(I) their faces
    he was despised,(J) and we held him in low esteem.

Surely he took up our pain
    and bore our suffering,(K)
yet we considered him punished by God,(L)
    stricken by him, and afflicted.(M)
But he was pierced(N) for our transgressions,(O)
    he was crushed(P) for our iniquities;
the punishment(Q) that brought us peace(R) was on him,
    and by his wounds(S) we are healed.(T)
We all, like sheep, have gone astray,(U)
    each of us has turned to our own way;(V)
and the Lord has laid on him
    the iniquity(W) of us all.

He was oppressed(X) and afflicted,
    yet he did not open his mouth;(Y)
he was led like a lamb(Z) to the slaughter,(AA)
    and as a sheep before its shearers is silent,
    so he did not open his mouth.
By oppression[a] and judgment(AB) he was taken away.
    Yet who of his generation protested?
For he was cut off from the land of the living;(AC)
    for the transgression(AD) of my people he was punished.[b]
He was assigned a grave with the wicked,(AE)
    and with the rich(AF) in his death,
though he had done no violence,(AG)
    nor was any deceit in his mouth.(AH)

10 Yet it was the Lord’s will(AI) to crush(AJ) him and cause him to suffer,(AK)
    and though the Lord makes[c] his life an offering for sin,(AL)
he will see his offspring(AM) and prolong his days,
    and the will of the Lord will prosper(AN) in his hand.
11 After he has suffered,(AO)
    he will see the light(AP) of life[d] and be satisfied[e];
by his knowledge[f] my righteous servant(AQ) will justify(AR) many,
    and he will bear their iniquities.(AS)
12 Therefore I will give him a portion among the great,[g](AT)
    and he will divide the spoils(AU) with the strong,[h]
because he poured out his life unto death,(AV)
    and was numbered with the transgressors.(AW)
For he bore(AX) the sin of many,(AY)
    and made intercession(AZ) for the transgressors.

Footnotes

  1. Isaiah 53:8 Or From arrest
  2. Isaiah 53:8 Or generation considered / that he was cut off from the land of the living, / that he was punished for the transgression of my people?
  3. Isaiah 53:10 Hebrew though you make
  4. Isaiah 53:11 Dead Sea Scrolls (see also Septuagint); Masoretic Text does not have the light of life.
  5. Isaiah 53:11 Or (with Masoretic Text) 11 He will see the fruit of his suffering / and will be satisfied
  6. Isaiah 53:11 Or by knowledge of him
  7. Isaiah 53:12 Or many
  8. Isaiah 53:12 Or numerous