Add parallel Print Page Options

Ìpè sí àwọn tí òrùngbẹ n gbẹ

55 (A)“Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ,
    ẹ wá sí ibi omi;
àti ẹ̀yin tí kò ní owó;
    ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ!
Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà
    láìsí owó àti láìdíyelé.
Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà
    àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn?
Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára,
    bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
(B)Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi
    gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè.
Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ,
    ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn,
    olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀
    àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá,
Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ
    Ẹni Mímọ́ Israẹli
    nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”

Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i;
    ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀
    àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀.
Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un,
    àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.

“Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín,
    tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,”
    ni Olúwa wí.
“Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ,
    bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ
    àti èrò mi ju èrò yín lọ.
10 (C)Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín
    ti wálẹ̀ láti ọ̀run
tí kì í sì padà sí ibẹ̀
    láì bomirin ilẹ̀
kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi,
    tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn
    àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
11 bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá;
    kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo,
ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́,
    yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
12 Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀
    a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà;
òkè ńláńlá àti kéékèèkéé
    yóò bú sí orin níwájú yín
àti gbogbo igi inú pápá
    yóò máa pàtẹ́wọ́.
13 Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà,
    àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ.
Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa,
    fún ààmì ayérayé,
    tí a kì yóò lè parun.”

Invitation to the Thirsty

55 “Come, all you who are thirsty,(A)
    come to the waters;(B)
and you who have no money,
    come, buy(C) and eat!
Come, buy wine and milk(D)
    without money and without cost.(E)
Why spend money on what is not bread,
    and your labor on what does not satisfy?(F)
Listen, listen to me, and eat what is good,(G)
    and you will delight in the richest(H) of fare.
Give ear and come to me;
    listen,(I) that you may live.(J)
I will make an everlasting covenant(K) with you,
    my faithful love(L) promised to David.(M)
See, I have made him a witness(N) to the peoples,
    a ruler and commander(O) of the peoples.
Surely you will summon nations(P) you know not,
    and nations you do not know will come running to you,(Q)
because of the Lord your God,
    the Holy One(R) of Israel,
    for he has endowed you with splendor.”(S)

Seek(T) the Lord while he may be found;(U)
    call(V) on him while he is near.
Let the wicked forsake(W) their ways
    and the unrighteous their thoughts.(X)
Let them turn(Y) to the Lord, and he will have mercy(Z) on them,
    and to our God, for he will freely pardon.(AA)

“For my thoughts(AB) are not your thoughts,
    neither are your ways my ways,”(AC)
declares the Lord.
“As the heavens are higher than the earth,(AD)
    so are my ways higher than your ways
    and my thoughts than your thoughts.(AE)
10 As the rain(AF) and the snow
    come down from heaven,
and do not return to it
    without watering the earth
and making it bud and flourish,(AG)
    so that it yields seed(AH) for the sower and bread for the eater,(AI)
11 so is my word(AJ) that goes out from my mouth:
    It will not return to me empty,(AK)
but will accomplish what I desire
    and achieve the purpose(AL) for which I sent it.
12 You will go out in joy(AM)
    and be led forth in peace;(AN)
the mountains and hills
    will burst into song(AO) before you,
and all the trees(AP) of the field
    will clap their hands.(AQ)
13 Instead of the thornbush will grow the juniper,
    and instead of briers(AR) the myrtle(AS) will grow.
This will be for the Lord’s renown,(AT)
    for an everlasting sign,
    that will endure forever.”