Add parallel Print Page Options

Ìgbàlà fún àwọn mìíràn

56 Èyí ni ohun ti Olúwa sọ:

“Ẹ pa ìdájọ́ mọ́
    ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà,
nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí
    àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.
Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí,
    àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin,
tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́,
    tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”

Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀
    mọ́ Olúwa sọ wí pé,
Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”
Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé,
    “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”

Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí:

“Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́,
    tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi
    tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin
fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀
    ìrántí kan àti orúkọ kan
tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin
    Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé
    tí a kì yóò ké kúrò.
Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa
    láti sìn ín,
láti fẹ́ orúkọ Olúwa
    àti láti foríbalẹ̀ fún un
gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́
    àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—
(A)àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi,
    èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi.
Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn,
    ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi;
nítorí a ó máa pe ilé mi ní
    ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè.”
Olúwa Olódùmarè sọ wí pé—
    ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ:
“Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn
    yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ.”

Ẹ̀sùn tí Ọlọ́run fi kan àwọn ìkà

Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá,
    ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!
10 Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú,
    gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀;
Gbogbo wọn jẹ́ adití ajá,
    wọn kò lè gbó;
wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá,
    wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.
11 Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀;
    wọn kì í ní ànító.
Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye;
    olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀,
    ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.
12 “Wá,” ni igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn, “fún mi ní ọtí wáìnì!
    Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó
ọ̀la yóò sì dàbí òní,
    tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”

Salvation for Others

56 This is what the Lord says:

“Maintain justice(A)
    and do what is right,(B)
for my salvation(C) is close at hand
    and my righteousness(D) will soon be revealed.
Blessed(E) is the one who does this—
    the person who holds it fast,
who keeps the Sabbath(F) without desecrating it,
    and keeps their hands from doing any evil.”

Let no foreigner(G) who is bound to the Lord say,
    “The Lord will surely exclude me from his people.”(H)
And let no eunuch(I) complain,
    “I am only a dry tree.”

For this is what the Lord says:

“To the eunuchs(J) who keep my Sabbaths,
    who choose what pleases me
    and hold fast to my covenant(K)
to them I will give within my temple and its walls(L)
    a memorial(M) and a name
    better than sons and daughters;
I will give them an everlasting name(N)
    that will endure forever.(O)
And foreigners(P) who bind themselves to the Lord
    to minister(Q) to him,
to love the name(R) of the Lord,
    and to be his servants,
all who keep the Sabbath(S) without desecrating it
    and who hold fast to my covenant—
these I will bring to my holy mountain(T)
    and give them joy in my house of prayer.
Their burnt offerings and sacrifices(U)
    will be accepted on my altar;
for my house will be called
    a house of prayer for all nations.(V)(W)
The Sovereign Lord declares—
    he who gathers the exiles of Israel:
“I will gather(X) still others to them
    besides those already gathered.”

God’s Accusation Against the Wicked

Come, all you beasts of the field,(Y)
    come and devour, all you beasts of the forest!
10 Israel’s watchmen(Z) are blind,
    they all lack knowledge;(AA)
they are all mute dogs,
    they cannot bark;
they lie around and dream,
    they love to sleep.(AB)
11 They are dogs with mighty appetites;
    they never have enough.
They are shepherds(AC) who lack understanding;(AD)
    they all turn to their own way,(AE)
    they seek their own gain.(AF)
12 “Come,” each one cries, “let me get wine!(AG)
    Let us drink our fill of beer!
And tomorrow will be like today,
    or even far better.”(AH)