Add parallel Print Page Options

57 Olódodo ṣègbé
    kò sí ẹnìkan tí ó rò ó lọ́kàn ara rẹ̀;
a mú àwọn ẹni mímọ́ lọ,
    kò sì ṣí ẹni tó yé
pé a ti mú àwọn olódodo lọ
    láti yọ wọ́n kúrò nínú ibi.
Gbogbo àwọn tí ń rìn déédé
    ń wọ inú àlàáfíà;
    wọ́n rí ìsinmi bí wọ́n ti ń sùn nínú ikú.

“Ṣùgbọ́n ẹ súnmọ́ ìhìn-ín, ẹ̀yin ọmọ aláfọ̀ṣẹ,
    ẹ̀yin irú-ọmọ panṣágà àti àgbèrè!
Ta ni ó fi ń ṣẹlẹ́yà?
    Ta ni o ń yọ ṣùtì sí
tí o sì yọ ahọ́n síta?
    Ẹ̀yin kì í ha ṣe ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn bí,
    àti ìran àwọn òpùrọ́?
Ẹ gbinájẹ fún ìṣekúṣe láàrín igi óákù
    àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀;
ẹ fi àwọn ọmọ yín rú ẹbọ nínú kòtò jíjìn
    àti lábẹ́ àwọn pàlàpálá òkúta.
Àwọn ère tí ó wà ní àárín òkúta dídán
    wọ́n n nì, nínú kòtò jíjìn ni ìpín in yín;
àwọ̀n ni ìpín in yín.
    Bẹ́ẹ̀ ni, sí wọn ni ẹ ti ta ọrẹ ohun mímu yín sílẹ̀
àti láti ta ọrẹ ìyẹ̀fun.
    Nítorí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó yẹ
    kí n dáwọ́ dúró?
Ìwọ ti ṣe ibùsùn rẹ lórí òkè gíga tí ó rẹwà;
    níbẹ̀ ni ẹ lọ láti lọ ṣe ìrúbọ yín.
Lẹ́yìn àwọn ìlẹ̀kùn yín àti òpó ìlẹ̀kùn yín
    níbẹ̀ ni ẹ fi àwọn ààmì òrìṣà yín sí.
Ní kíkọ̀ mí sílẹ̀, ẹ ṣí ibùsùn yín sílẹ̀,
    ẹ gun orí rẹ̀ lọ, ẹ sì ṣí i sílẹ̀ gbagada;
ẹ ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn tí ẹ fẹ́ràn ibùsùn wọn,
    ẹ̀yin sì ń wo ìhòhò wọn.
Ẹ̀yin lọ sí Moleki pẹ̀lú òróró olifi
    ẹ sì fi kún òórùn dídùn yín.
Ẹ rán ikọ̀ yín lọ jìnnà réré;
    ẹ sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú!
10 Àwọn ọ̀nà yín gbogbo ti mú àárẹ̀ ba á yín,
ṣùgbọ́n ẹ kò ní sọ pé, ‘kò sí ìrètí mọ́?’
    Ẹ rí okun kún agbára yín,
    nípa bẹ́ẹ̀ òòyì kò kọ́ ọ yín.

11 “Ta ni ó ń pá yín láyà tí ń bà yín lẹ́rù
    tí ẹ fi ń ṣèké sí mi,
àti tí ẹ̀yin kò fi rántí mi
    tàbí kí ẹ rò yí nínú ọkàn yín?
Ǹjẹ́ kì í ṣe nítorí dídákẹ́ jẹ́ẹ́ mi fún ìgbà pípẹ́
    tí ẹ̀yin kò fi bẹ̀rù mi?
12 Èmi yóò ṣí òdodo yín páyà àti iṣẹ́ yín,
    wọn kì yóò sì ṣe yín ní àǹfààní.
13 Nígbà tí ẹ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́
    ẹ jẹ́ kí àkójọ àwọn ère yín gbà yín!
Atẹ́gùn yóò gbá gbogbo wọn lọ,
    èémí lásán làsàn ni yóò gbá wọn lọ.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá fi mí ṣe ààbò rẹ̀
    ni yóò jogún ilẹ̀ náà
    yóò sì jogún òkè mímọ́ mi.”

Ìtùnú fún àwọn oníròbìnújẹ́

14 A ó sì sọ wí pé:

“Tún mọ, tún mọ, tún ọ̀nà náà ṣe!
    Ẹ mú àwọn ohun ìkọ̀sẹ̀ kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn mi.”
15 (A)Nítorí èyí ni ohun tí Ẹni gíga àti ọlọ́lá jùlọ wí
    ẹni tí ó wà títí láé, tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ mímọ́:
“Mo ń gbé ní ibi gíga àti ibi mímọ́,
    ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹni n nì tí ó ní ìròbìnújẹ́ àti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀,
láti sọ ẹ̀mí onírẹ̀lẹ̀ náà jí
    àti láti sọ ẹ̀mí oníròbìnújẹ́ n nì jí.
16 Èmi kì yóò fẹ̀sùn kan ni títí láé,
    tàbí kí n máa bínú sá á,
nítorí nígbà náà ni ọkàn ènìyàn yóò
    rẹ̀wẹ̀sì níwájú mi
    èémí ènìyàn tí mo ti dá.
17 Inú bí mi nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀kánjúwà rẹ̀;
    mo fìyà jẹ ẹ́, mo sì fojú mi pamọ́ ní ìbínú
    síbẹ̀, ó tẹ̀síwájú nínú tinú-mi-ni n ó ṣe ọ̀nà rẹ̀.
18 Èmi ti rí ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ṣùgbọ́n Èmi yóò wò ó sàn;
    Èmi yóò tọ́ ọ ṣọ́nà n ó sì mú ìtùnú tọ̀ ọ́ wá,
19 (B)ní dídá ìyìn sí ètè àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ní Israẹli.
    Àlàáfíà, àlàáfíà fún àwọn tí ó wà lókèèrè àti nítòsí,”
    ni Olúwa wí, “Àti pé Èmi yóò wo wọ́n sàn.”
20 Ṣùgbọ́n àwọn ìkà dàbí i ríru Òkun
    tí kò le è sinmi,
    tí ìgbì rẹ̀ ń rú pẹ̀tẹ̀pẹ́tẹ̀ àti ẹrọ̀fọ̀ sókè.
21 “Kò sí àlàáfíà,” ni Ọlọ́run mi wí, “fún àwọn ìkà.”

57 The righteous perish,(A)
    and no one takes it to heart;(B)
the devout are taken away,
    and no one understands
that the righteous are taken away
    to be spared from evil.(C)
Those who walk uprightly(D)
    enter into peace;
    they find rest(E) as they lie in death.

“But you—come here, you children of a sorceress,(F)
    you offspring of adulterers(G) and prostitutes!(H)
Who are you mocking?
    At whom do you sneer
    and stick out your tongue?
Are you not a brood of rebels,(I)
    the offspring of liars?
You burn with lust among the oaks(J)
    and under every spreading tree;(K)
you sacrifice your children(L) in the ravines
    and under the overhanging crags.
The idols(M) among the smooth stones of the ravines are your portion;
    indeed, they are your lot.
Yes, to them you have poured out drink offerings(N)
    and offered grain offerings.
    In view of all this, should I relent?(O)
You have made your bed on a high and lofty hill;(P)
    there you went up to offer your sacrifices.(Q)
Behind your doors and your doorposts
    you have put your pagan symbols.
Forsaking me, you uncovered your bed,
    you climbed into it and opened it wide;
you made a pact with those whose beds you love,(R)
    and you looked with lust on their naked bodies.(S)
You went to Molek[a](T) with olive oil
    and increased your perfumes.(U)
You sent your ambassadors[b](V) far away;
    you descended to the very realm of the dead!(W)
10 You wearied(X) yourself by such going about,
    but you would not say, ‘It is hopeless.’(Y)
You found renewal of your strength,(Z)
    and so you did not faint.

11 “Whom have you so dreaded and feared(AA)
    that you have not been true to me,
and have neither remembered(AB) me
    nor taken this to heart?(AC)
Is it not because I have long been silent(AD)
    that you do not fear me?
12 I will expose your righteousness and your works,(AE)
    and they will not benefit you.
13 When you cry out(AF) for help,
    let your collection of idols save(AG) you!
The wind will carry all of them off,
    a mere breath will blow(AH) them away.
But whoever takes refuge(AI) in me
    will inherit the land(AJ)
    and possess my holy mountain.”(AK)

Comfort for the Contrite

14 And it will be said:

“Build up, build up, prepare the road!(AL)
    Remove the obstacles out of the way of my people.”(AM)
15 For this is what the high and exalted(AN) One says—
    he who lives forever,(AO) whose name is holy:
“I live in a high(AP) and holy place,
    but also with the one who is contrite(AQ) and lowly in spirit,(AR)
to revive the spirit of the lowly
    and to revive the heart of the contrite.(AS)
16 I will not accuse(AT) them forever,
    nor will I always be angry,(AU)
for then they would faint away because of me—
    the very people(AV) I have created.
17 I was enraged by their sinful greed;(AW)
    I punished them, and hid(AX) my face in anger,
    yet they kept on in their willful ways.(AY)
18 I have seen their ways, but I will heal(AZ) them;
    I will guide(BA) them and restore comfort(BB) to Israel’s mourners,
19     creating praise on their lips.(BC)
Peace, peace,(BD) to those far and near,”(BE)
    says the Lord. “And I will heal them.”
20 But the wicked(BF) are like the tossing sea,(BG)
    which cannot rest,
    whose waves cast up mire(BH) and mud.
21 “There is no peace,”(BI) says my God, “for the wicked.”(BJ)

Footnotes

  1. Isaiah 57:9 Or to the king
  2. Isaiah 57:9 Or idols