Add parallel Print Page Options

A bí ọmọ kan fún wa

(A)Síbẹ̀síbẹ̀, kò ní sí ìpòrúru kankan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sebuluni sílẹ̀ àti ilẹ̀ Naftali pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Galili ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà Òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jordani.

Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùn
    ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá;
Lórí àwọn tí ń gbé nínú ilẹ̀ òjìji ikú,
    ní ara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.
Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá;
    wọ́n sì yọ̀ níwájú rẹ
gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkórè,
    gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀
    nígbà tí à ń pín ìkógun.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Midiani,
    ìwọ ti fọ́ ọ túútúú
àjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù,
    ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn,
    ọ̀gọ aninilára wọn.
Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogun
    àti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀,
ni yóò wà fún ìjóná,
    àti ohun èlò iná dídá.
Nítorí a bí ọmọ kan fún wa,
    a fi ọmọkùnrin kan fún wa,
ìjọba yóò sì wà ní èjìká rẹ̀.
    A ó sì máa pè é ní: Ìyanu
Olùdámọ̀ràn, Ọlọ́run Alágbára
    Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.
Ní ti ìgbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun.
    Yóò jẹ ọba lórí ìtẹ́ Dafidi
àti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo,
    nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀,
pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodo
    láti ìgbà náà lọ àti títí láéláé.
Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    ni yóò mú èyí ṣẹ.

Ìbínú Olúwa Sí Israẹli

Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jakọbu;
    Yóò sì wá sórí Israẹli.
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n—
    Efraimu àti gbogbo olùgbé Samaria—
tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéraga
    àti gààrù àyà pé.
10 Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀
    ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán,
a ti gé àwọn igi sikamore lulẹ̀
    ṣùgbọ́n igi kedari ní a ó fi dípò wọn.
11 Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀tá Resini ní agbára láti dojúkọ wọ́n
    ó sì ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè.
12 Àwọn ará Aramu láti ìlà-oòrùn àti Filistini láti ìwọ̀-oòrùn.
Wọ́n sì fi gbogbo ẹnu jẹ Israẹli run.

    Ní gbogbo èyí ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò
    Ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde síbẹ̀.

13 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadà
    sí ẹni náà tí ó lù wọ́n
    bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
14 Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrù
    kúrò ní Israẹli,
    àti ọ̀wá ọ̀pẹ àti koríko odò ní ọjọ́ kan ṣoṣo,
15 Àwọn àgbàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ní orí,
    àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.
16 Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣì wọ́n lọ́nà
    Àwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.
17 Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin
    tàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó,
nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ Ọlọ́run,
    ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde.

Síbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò
    ọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

18 Nítòótọ́ ìwà búburú ń jóni bí iná,
    yóò jó ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún run,
yóò sì rán nínú pàǹtí igbó,
    tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi gòkè lọ bí ọ̀wọ́n èéfín ti í gòkè.
19 Nípasẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    ilẹ̀ náà yóò di gbígbẹ
àwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná,
    ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.
20 Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun,
    síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n,
ní apá òsì, wọn yóò jẹ
    ṣùgbọ́n, kò ní tẹ́ wọn lọ́rùn.
    Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara apá rẹ̀.
21 Manase yóò máa jẹ Efraimu, nígbà tí Efraimu yóò jẹ Manase
    wọn yóò parapọ̀ dojúkọ Juda.

Síbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò
    Ọwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

[a]Nevertheless, there will be no more gloom(A) for those who were in distress. In the past he humbled the land of Zebulun and the land of Naphtali,(B) but in the future he will honor Galilee of the nations, by the Way of the Sea, beyond the Jordan—

The people walking in darkness(C)
    have seen a great light;(D)
on those living in the land of deep darkness(E)
    a light has dawned.(F)
You have enlarged the nation(G)
    and increased their joy;(H)
they rejoice before you
    as people rejoice at the harvest,
as warriors rejoice
    when dividing the plunder.(I)
For as in the day of Midian’s defeat,(J)
    you have shattered(K)
the yoke(L) that burdens them,
    the bar across their shoulders,(M)
    the rod of their oppressor.(N)
Every warrior’s boot used in battle
    and every garment rolled in blood
will be destined for burning,(O)
    will be fuel for the fire.
For to us a child is born,(P)
    to us a son is given,(Q)
    and the government(R) will be on his shoulders.(S)
And he will be called
    Wonderful Counselor,(T) Mighty God,(U)
    Everlasting(V) Father,(W) Prince of Peace.(X)
Of the greatness of his government(Y) and peace(Z)
    there will be no end.(AA)
He will reign(AB) on David’s throne
    and over his kingdom,
establishing and upholding it
    with justice(AC) and righteousness(AD)
    from that time on and forever.(AE)
The zeal(AF) of the Lord Almighty
    will accomplish this.

The Lord’s Anger Against Israel

The Lord has sent a message(AG) against Jacob;
    it will fall on Israel.
All the people will know it—
    Ephraim(AH) and the inhabitants of Samaria(AI)
who say with pride
    and arrogance(AJ) of heart,
10 “The bricks have fallen down,
    but we will rebuild with dressed stone;(AK)
the fig(AL) trees have been felled,
    but we will replace them with cedars.(AM)
11 But the Lord has strengthened Rezin’s(AN) foes against them
    and has spurred their enemies on.
12 Arameans(AO) from the east and Philistines(AP) from the west
    have devoured(AQ) Israel with open mouth.

Yet for all this, his anger(AR) is not turned away,
    his hand is still upraised.(AS)

13 But the people have not returned(AT) to him who struck(AU) them,
    nor have they sought(AV) the Lord Almighty.
14 So the Lord will cut off from Israel both head and tail,
    both palm branch and reed(AW) in a single day;(AX)
15 the elders(AY) and dignitaries(AZ) are the head,
    the prophets(BA) who teach lies(BB) are the tail.
16 Those who guide(BC) this people mislead them,
    and those who are guided are led astray.(BD)
17 Therefore the Lord will take no pleasure in the young men,(BE)
    nor will he pity(BF) the fatherless and widows,
for everyone is ungodly(BG) and wicked,(BH)
    every mouth speaks folly.(BI)

Yet for all this, his anger is not turned away,
    his hand is still upraised.(BJ)

18 Surely wickedness burns like a fire;(BK)
    it consumes briers and thorns,(BL)
it sets the forest thickets ablaze,(BM)
    so that it rolls upward in a column of smoke.
19 By the wrath(BN) of the Lord Almighty
    the land will be scorched(BO)
and the people will be fuel for the fire;(BP)
    they will not spare one another.(BQ)
20 On the right they will devour,
    but still be hungry;(BR)
on the left they will eat,(BS)
    but not be satisfied.
Each will feed on the flesh of their own offspring[b]:
21     Manasseh will feed on Ephraim, and Ephraim on Manasseh;(BT)
    together they will turn against Judah.(BU)

Yet for all this, his anger is not turned away,
    his hand is still upraised.(BV)

Footnotes

  1. Isaiah 9:1 In Hebrew texts 9:1 is numbered 8:23, and 9:2-21 is numbered 9:1-20.
  2. Isaiah 9:20 Or arm