Add parallel Print Page Options

Ọlọ́run kọ ìbéèrè Sedekiah sílẹ̀

21 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé: “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”

Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah, ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí. Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle. Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú. Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’

“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀. 10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’

11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. 12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ:

“ ‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀;
    yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára
ẹni tí a ti jà lólè
    bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná.
Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó
    láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu
    ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì
lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí.
    Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá?
    Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀
    ni Olúwa wí.
Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀;
    yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’ ”

God Rejects Zedekiah’s Request

21 The word came to Jeremiah from the Lord when King Zedekiah(A) sent to him Pashhur(B) son of Malkijah and the priest Zephaniah(C) son of Maaseiah. They said: “Inquire(D) now of the Lord for us because Nebuchadnezzar[a](E) king of Babylon(F) is attacking us. Perhaps the Lord will perform wonders(G) for us as in times past so that he will withdraw from us.”

But Jeremiah answered them, “Tell Zedekiah, ‘This is what the Lord, the God of Israel, says: I am about to turn(H) against you the weapons of war that are in your hands, which you are using to fight the king of Babylon and the Babylonians[b] who are outside the wall besieging(I) you. And I will gather them inside this city. I myself will fight(J) against you with an outstretched hand(K) and a mighty arm(L) in furious anger and in great wrath. I will strike(M) down those who live in this city—both man and beast—and they will die of a terrible plague.(N) After that, declares the Lord, I will give Zedekiah(O) king of Judah, his officials and the people in this city who survive the plague,(P) sword and famine, into the hands of Nebuchadnezzar king of Babylon(Q) and to their enemies(R) who want to kill them.(S) He will put them to the sword;(T) he will show them no mercy or pity or compassion.’(U)

“Furthermore, tell the people, ‘This is what the Lord says: See, I am setting before you the way of life(V) and the way of death. Whoever stays in this city will die by the sword, famine or plague.(W) But whoever goes out and surrenders(X) to the Babylonians who are besieging you will live; they will escape with their lives.(Y) 10 I have determined to do this city harm(Z) and not good, declares the Lord. It will be given into the hands(AA) of the king of Babylon, and he will destroy it with fire.’(AB)

11 “Moreover, say to the royal house(AC) of Judah, ‘Hear the word of the Lord. 12 This is what the Lord says to you, house of David:

“‘Administer justice(AD) every morning;
    rescue from the hand of the oppressor(AE)
    the one who has been robbed,
or my wrath will break out and burn like fire(AF)
    because of the evil(AG) you have done—
    burn with no one to quench(AH) it.
13 I am against(AI) you, Jerusalem,
    you who live above this valley(AJ)
    on the rocky plateau, declares the Lord
you who say, “Who can come against us?
    Who can enter our refuge?”(AK)
14 I will punish you as your deeds(AL) deserve,
    declares the Lord.
I will kindle a fire(AM) in your forests(AN)
    that will consume everything around you.’”

Footnotes

  1. Jeremiah 21:2 Hebrew Nebuchadrezzar, of which Nebuchadnezzar is a variant; here and often in Jeremiah and Ezekiel
  2. Jeremiah 21:4 Or Chaldeans; also in verse 9