Add parallel Print Page Options

“Tí ìwọ yóò bá yí padà, Ìwọ Israẹli,
    padà tọ̀ mí wá,”
    ni Olúwa wí.
“Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi,
    ìwọ kí ó sì rìn kiri.
Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra.
    Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè,
nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ,
    àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
    “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí,
    kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.”
Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa
    kọ ọkàn rẹ ní ilà
ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu,
    bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná,
nítorí ibi tí o ti ṣe
    kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.

Àjálù láti ilẹ̀ gúúsù

“Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé:
    ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’
Kí o sì kígbe:
    ‘Kó ara jọ pọ̀!
    Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
Fi ààmì láti sálọ sí Sioni hàn,
    sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró.
Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá,
    àní ìparun tí ó burú jọjọ.”

Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀,
    apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde.
Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀
    láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́.
Ìlú rẹ yóò di ahoro
    láìsí olùgbé.
Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀
    káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún,
nítorí ìbínú ńlá Olúwa
    kò tí ì kúrò lórí wa.

“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé,
    “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn,
àwọn àlùfáà yóò wárìrì,
    àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”

10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”

11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́. 12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”

13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu
    kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle
ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ
    Ègbé ni fún wa àwa parun.
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè
    Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani
    o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè,
    kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé:
‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá
    wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá,
    nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’ ”
    ni Olúwa wí.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ
    ló fa èyí bá ọ
ìjìyà rẹ sì nìyìí,
    Báwo ló ti ṣe korò tó!
    Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”

19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi!
    Mo yí nínú ìrora.
Háà, ìrora ọkàn mi!
    Ọkàn mi lù kìkì nínú mi,
n kò le è dákẹ́.
    Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè,
    mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
20 Ìparun ń gorí ìparun;
    gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun
lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi,
    tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun
    tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?

22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi;
    wọn kò mọ̀ mí.
Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ;
    wọ́n sì jẹ́ aláìlóye.
Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe;
    wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”

23 Mo bojú wo ayé,
    ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo
àti ní ọ̀run,
    ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá,
    wọ́n wárìrì;
    gbogbo òkè kéékèèkéé mì jẹ̀jẹ̀.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan;
    gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀
    gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun
    níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa
    “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro,
    síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún
    àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn
nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀
    mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”

29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà
    gbogbo ìlú yóò sálọ.
Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó;
    ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ.
Gbogbo ìlú náà sì di ahoro;
    kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.

30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán?
    Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo
kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́.
    Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ
wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.

31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí,
    tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ
ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀.
    Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé,
“Kíyèsi i mo gbé,
    Nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”

“If you, Israel, will return,(A)
    then return to me,”
declares the Lord.
“If you put your detestable idols(B) out of my sight
    and no longer go astray,
and if in a truthful, just and righteous way
    you swear,(C) ‘As surely as the Lord lives,’(D)
then the nations will invoke blessings(E) by him
    and in him they will boast.(F)

This is what the Lord says to the people of Judah and to Jerusalem:

“Break up your unplowed ground(G)
    and do not sow among thorns.(H)
Circumcise yourselves to the Lord,
    circumcise your hearts,(I)
    you people of Judah and inhabitants of Jerusalem,
or my wrath(J) will flare up and burn like fire(K)
    because of the evil(L) you have done—
    burn with no one to quench(M) it.

Disaster From the North

“Announce in Judah and proclaim(N) in Jerusalem and say:
    ‘Sound the trumpet(O) throughout the land!’
Cry aloud and say:
    ‘Gather together!
    Let us flee to the fortified cities!’(P)
Raise the signal(Q) to go to Zion!
    Flee for safety without delay!
For I am bringing disaster(R) from the north,(S)
    even terrible destruction.”

A lion(T) has come out of his lair;(U)
    a destroyer(V) of nations has set out.
He has left his place
    to lay waste(W) your land.
Your towns will lie in ruins(X)
    without inhabitant.
So put on sackcloth,(Y)
    lament(Z) and wail,
for the fierce anger(AA) of the Lord
    has not turned away from us.

“In that day,” declares the Lord,
    “the king and the officials will lose heart,(AB)
the priests will be horrified,
    and the prophets will be appalled.”(AC)

10 Then I said, “Alas, Sovereign Lord! How completely you have deceived(AD) this people and Jerusalem by saying, ‘You will have peace,’(AE) when the sword is at our throats!”

11 At that time this people and Jerusalem will be told, “A scorching wind(AF) from the barren heights in the desert blows toward my people, but not to winnow or cleanse; 12 a wind(AG) too strong for that comes from me. Now I pronounce my judgments(AH) against them.”

13 Look! He advances like the clouds,(AI)
    his chariots(AJ) come like a whirlwind,(AK)
his horses(AL) are swifter than eagles.(AM)
    Woe to us! We are ruined!(AN)
14 Jerusalem, wash(AO) the evil from your heart and be saved.(AP)
    How long(AQ) will you harbor wicked thoughts?
15 A voice is announcing from Dan,(AR)
    proclaiming disaster from the hills of Ephraim.(AS)
16 “Tell this to the nations,
    proclaim concerning Jerusalem:
‘A besieging army is coming from a distant land,(AT)
    raising a war cry(AU) against the cities of Judah.(AV)
17 They surround(AW) her like men guarding a field,
    because she has rebelled(AX) against me,’”
declares the Lord.
18 “Your own conduct and actions(AY)
    have brought this on you.(AZ)
This is your punishment.
    How bitter(BA) it is!
    How it pierces to the heart!”

19 Oh, my anguish, my anguish!(BB)
    I writhe in pain.(BC)
Oh, the agony of my heart!
    My heart pounds(BD) within me,
    I cannot keep silent.(BE)
For I have heard the sound of the trumpet;(BF)
    I have heard the battle cry.(BG)
20 Disaster follows disaster;(BH)
    the whole land lies in ruins.(BI)
In an instant my tents(BJ) are destroyed,
    my shelter in a moment.
21 How long must I see the battle standard(BK)
    and hear the sound of the trumpet?(BL)

22 “My people are fools;(BM)
    they do not know me.(BN)
They are senseless children;
    they have no understanding.(BO)
They are skilled in doing evil;(BP)
    they know not how to do good.”(BQ)

23 I looked at the earth,
    and it was formless and empty;(BR)
and at the heavens,
    and their light(BS) was gone.
24 I looked at the mountains,
    and they were quaking;(BT)
    all the hills were swaying.
25 I looked, and there were no people;
    every bird in the sky had flown away.(BU)
26 I looked, and the fruitful land was a desert;(BV)
    all its towns lay in ruins(BW)
    before the Lord, before his fierce anger.(BX)

27 This is what the Lord says:

“The whole land will be ruined,(BY)
    though I will not destroy(BZ) it completely.
28 Therefore the earth will mourn(CA)
    and the heavens above grow dark,(CB)
because I have spoken and will not relent,(CC)
    I have decided and will not turn back.(CD)

29 At the sound of horsemen and archers(CE)
    every town takes to flight.(CF)
Some go into the thickets;
    some climb up among the rocks.(CG)
All the towns are deserted;(CH)
    no one lives in them.

30 What are you doing,(CI) you devastated one?
    Why dress yourself in scarlet
    and put on jewels(CJ) of gold?
Why highlight your eyes with makeup?(CK)
    You adorn yourself in vain.
Your lovers(CL) despise you;
    they want to kill you.(CM)

31 I hear a cry as of a woman in labor,(CN)
    a groan as of one bearing her first child—
the cry of Daughter Zion(CO) gasping for breath,(CP)
    stretching out her hands(CQ) and saying,
“Alas! I am fainting;
    my life is given over to murderers.”(CR)