Add parallel Print Page Options

Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí Ejibiti

46 (A)Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn orílẹ̀-èdè:

Ní ti Ejibiti:

Èyí ni ọ̀rọ̀ nípa àwọn ọmọ-ogun Farao Neko ọba Ejibiti ẹni tí a borí rẹ̀ ní Karkemiṣi, ní odò Eufurate láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:

“Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré,
    kí ẹ sì súnmọ́ ojú ìjà!
Ẹ di ẹṣin ní gàárì,
    kí ẹ sì gùn ún.
Ẹ dúró lẹ́sẹẹsẹ
    pẹ̀lú àṣíborí yín!
Ẹ dán ọ̀kọ̀ yín,
    kí ẹ sì wọ ẹ̀wù irin.
(B)Kí ni nǹkan tí mo tún rí?
    Wọ́n bẹ̀rù,
wọ́n sì ń padà sẹ́yìn,
    wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun.
Wọ́n sá,
    wọn kò sì bojú wẹ̀yìn,
ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,”
    ni Olúwa wí.
“Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ,
    tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà.
Ní àríwá ní ibi odò Eufurate
    wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.

“Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti,
    tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n-ọn-nì?
Ejibiti dìde bí odò náà,
    bí omi odò tí ń ru.
Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’
    Èmi yóò pa ìlú àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.
Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin,
    ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́.
Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú,
    àwọn ará Kuṣi àti àwọn ará Puti tí ń di asà mú;
    àti àwọn ará Lidia tí ń fa ọrun.
10 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn,
    títí yóò fi pa òǹgbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.
Nítorí pé Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò rú ẹbọ
    ní ilẹ̀ gúúsù ní odò Eufurate.

11 “Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra,
    ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Ejibiti.
Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn,
    kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.
12 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ,
    igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé.
Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ,
    àwọn méjèèjì yóò sì jọ ṣubú papọ̀.”

13 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:

14 “Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli,
    sọ ọ́ ní Memfisi àti Tafanesi:
‘Dúró sí ààyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀,
    nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’
15 Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú?
    Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.
16 Wọn yóò máa ṣubú léraléra
    wọn yóò máa ṣubú lu ara wọn.
Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padà
    sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa,
    kúrò níbi idà àwọn aninilára.’
17 Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé,
    ‘Ariwo lásán ni Farao ọba Ejibiti pa,
    ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’

18 “Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba,
    ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé,
“nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tabori láàrín àwọn òkè àti
    gẹ́gẹ́ bi Karmeli lẹ́bàá Òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.
19 Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti
    pèsè ohun èlò ìrìnàjò fún ara rẹ
nítorí Memfisi yóò di ahoro
    a ó sì fi jóná, láìní olùgbé.

20 “Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti
    ṣùgbọ́n eṣinṣin ìparun dé,
    ó dé láti àríwá.
21 Àwọn jagunjagun rẹ̀
    dàbí àbọ́pa akọ màlúù.
Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà,
    wọn ó sì jùmọ̀ sá,
wọn kò ní le dúró,
    Nítorí tí ọjọ́ ibi ń bọ̀ lórí wọn
    àsìkò láti jẹ wọ́n ní ìyà.
22 Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá
    bí ọmọ-ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára.
Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké,
    gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.
23 Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,”
    ni Olúwa wí,
“nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀,
    nítorí pé wọ́n pọ̀ ju ẹlẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.
24 A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti,
    a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”

25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao. 26 Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.

27 “Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi,
    má fòyà, ìwọ Israẹli.
Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jíjìn,
    àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Jakọbu yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò,
    kò sì ṣí ẹni tí yóò dẹ́rùbà á.
28 Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi,
    nítorí pé mo wà pẹ̀lú rẹ,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
“Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run,
    láàrín àwọn tí mo fọ́n yín ká sí.
Èmi kò ní run yín tán.
    Èmi yóò jẹ ọ́ ní ìyà lórí òdodo,
    èmi kí yóò jọ̀wọ́ rẹ lọ́wọ́ lọ láìjẹ ọ́ ní yà.”

A Message About Egypt

46 This is the word of the Lord that came to Jeremiah the prophet concerning the nations:(A)

Concerning Egypt:(B)

This is the message against the army of Pharaoh Necho(C) king of Egypt, which was defeated at Carchemish(D) on the Euphrates(E) River by Nebuchadnezzar king of Babylon in the fourth year of Jehoiakim(F) son of Josiah king of Judah:

“Prepare your shields,(G) both large and small,
    and march out for battle!
Harness the horses,
    mount the steeds!
Take your positions
    with helmets on!
Polish(H) your spears,
    put on your armor!(I)
What do I see?
    They are terrified,
they are retreating,
    their warriors are defeated.
They flee(J) in haste
    without looking back,
    and there is terror(K) on every side,”
declares the Lord.
“The swift cannot flee(L)
    nor the strong escape.
In the north by the River Euphrates(M)
    they stumble and fall.(N)

“Who is this that rises like the Nile,
    like rivers of surging waters?(O)
Egypt rises like the Nile,(P)
    like rivers of surging waters.
She says, ‘I will rise and cover the earth;
    I will destroy cities and their people.’(Q)
Charge, you horses!
    Drive furiously, you charioteers!(R)
March on, you warriors—men of Cush[a](S) and Put who carry shields,
    men of Lydia(T) who draw the bow.
10 But that day(U) belongs to the Lord, the Lord Almighty—
    a day of vengeance(V), for vengeance on his foes.
The sword will devour(W) till it is satisfied,
    till it has quenched its thirst with blood.(X)
For the Lord, the Lord Almighty, will offer sacrifice(Y)
    in the land of the north by the River Euphrates.(Z)

11 “Go up to Gilead and get balm,(AA)
    Virgin(AB) Daughter Egypt.
But you try many medicines in vain;
    there is no healing(AC) for you.
12 The nations will hear of your shame;
    your cries will fill the earth.
One warrior will stumble over another;
    both will fall(AD) down together.”

13 This is the message the Lord spoke to Jeremiah the prophet about the coming of Nebuchadnezzar king of Babylon(AE) to attack Egypt:(AF)

14 “Announce this in Egypt, and proclaim it in Migdol;
    proclaim it also in Memphis(AG) and Tahpanhes:(AH)
‘Take your positions and get ready,
    for the sword devours(AI) those around you.’
15 Why will your warriors be laid low?
    They cannot stand, for the Lord will push them down.(AJ)
16 They will stumble(AK) repeatedly;
    they will fall(AL) over each other.
They will say, ‘Get up, let us go back
    to our own people(AM) and our native lands,
    away from the sword of the oppressor.’(AN)
17 There they will exclaim,
    ‘Pharaoh king of Egypt is only a loud noise;(AO)
    he has missed his opportunity.(AP)

18 “As surely as I live,” declares the King,(AQ)
    whose name is the Lord Almighty,
“one will come who is like Tabor(AR) among the mountains,
    like Carmel(AS) by the sea.
19 Pack your belongings for exile,(AT)
    you who live in Egypt,
for Memphis(AU) will be laid waste(AV)
    and lie in ruins without inhabitant.

20 “Egypt is a beautiful heifer,
    but a gadfly is coming
    against her from the north.(AW)
21 The mercenaries(AX) in her ranks
    are like fattened calves.(AY)
They too will turn and flee(AZ) together,
    they will not stand their ground,
for the day(BA) of disaster is coming upon them,
    the time(BB) for them to be punished.
22 Egypt will hiss like a fleeing serpent
    as the enemy advances in force;
they will come against her with axes,
    like men who cut down trees.(BC)
23 They will chop down her forest,”
declares the Lord,
    “dense though it be.
They are more numerous than locusts,(BD)
    they cannot be counted.
24 Daughter Egypt will be put to shame,
    given into the hands of the people of the north.(BE)

25 The Lord Almighty, the God of Israel, says: “I am about to bring punishment on Amon god of Thebes,(BF) on Pharaoh,(BG) on Egypt and her gods(BH) and her kings, and on those who rely(BI) on Pharaoh. 26 I will give them into the hands(BJ) of those who want to kill them—Nebuchadnezzar king(BK) of Babylon and his officers. Later, however, Egypt will be inhabited(BL) as in times past,” declares the Lord.

27 “Do not be afraid,(BM) Jacob(BN) my servant;(BO)
    do not be dismayed, Israel.
I will surely save you out of a distant place,
    your descendants from the land of their exile.(BP)
Jacob will again have peace and security,
    and no one will make him afraid.
28 Do not be afraid, Jacob my servant,
    for I am with you,”(BQ) declares the Lord.
“Though I completely destroy(BR) all the nations
    among which I scatter you,
    I will not completely destroy you.
I will discipline you but only in due measure;
    I will not let you go entirely unpunished.”

Footnotes

  1. Jeremiah 46:9 That is, the upper Nile region