Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ ní ti Babeli

50 (A)Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:

“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde,
    kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀
    ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé,
‘a kó Babeli,
    ojú tí Beli,
    a fọ́ Merodaki túútúú,
ojú ti àwọn ère rẹ̀,
    a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò
    sì máa gbóguntì wọ́n.
Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò
    sá kúrò ní ìlú yìí.

“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,”
    ni Olúwa wí,
“Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá,
àwọn, àti àwọn ọmọ Juda,
    wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí
    Olúwa Ọlọ́run wọn
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn
    yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a
darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé,
    tí a kì yóò gbàgbé.

“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù,
    àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà,
wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè
    wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré,
    wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ
    àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi
nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé
    òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’

“Jáde kúrò ní Babeli,
    ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀,
    kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Nítorí pé èmi yóò ru,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè
ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀;
    Láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò
    dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo
    àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú
ìfẹ́ wọn ṣẹ,”
    ni Olúwa wí.

11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀,
    ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn
fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù,
    ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ
    yóò sì gba ìtìjú.
Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
    ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé;
    ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀.
Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò
    fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.

14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli
    àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà.
    Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Kígbe mọ-ọn ní gbogbo ọ̀nà!
    Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀,
níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa,
    gbẹ̀san lára rẹ̀.
    Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli,
    àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè!
Nítorí idà àwọn aninilára
    jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀,
    kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.

17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri,
    kìnnìún sì ti lé e lọ.
Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ,
    àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli
    fa egungun rẹ̀ ya.”

18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí;

“Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli
    padà wá pápá oko tútù rẹ̀
òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani,
    a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè
    Efraimu àti ní Gileadi
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,”
    ni Olúwa wí,
“À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli,
ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun;
    àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan
    nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.

21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn
    tí ó ń gbé ní Pekodi.
Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,”
    ni Olúwa
    “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà
    ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó,
    lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé!
    Báwo ní Babeli ti di ahoro
    ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀
    fún ọ ìwọ Babeli,
kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀,
    o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde,
    nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun
    ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo,
    sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀,
    ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà,
Kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun,
    ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ,
    jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n!
    Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé,
    àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá,
    sì sọ ní Sioni,
Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san,
    ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.

29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli,
    ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà.
Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀
    gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe,
ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga
    Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀
    yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn
ológun lẹ́nu mọ́,”
    Olúwa wí.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,”
    ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,
“nítorí ọjọ́ rẹ ti dé,
    àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò
    sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde.
Èmi yóò tan iná ní ìlú náà,
    èyí tí yóò sì jo run.”

33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ:

“A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli
    lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú.
Gbogbo àwọn tí ó kó wọn
    nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin
    wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára,
    Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀.
Yóò sì gbe ìjà wọn jà,
    kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà;
    ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.

35 “Idà lórí àwọn Babeli!”
    ni Olúwa wí,
“lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli,
    àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké
    wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun,
    wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀
    àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀.
Wọn yóò di obìnrin.
    Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ.
    Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère,
    àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.

39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù
    pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀,
abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀,
    a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé,
    bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba
    Sodomu àti Gomorra
pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,”
    ni Olúwa wí,
    “kì yóò sí ẹni tí yóò gbé ibẹ̀.

41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá;
    orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń
    gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun,
    wọ́n burú wọn kò sì ní àánú.
Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ.
    Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,
    ọwọ́ wọn sì rọ,
    ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani
    sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,
    Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.
Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?
    Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?
    Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”

45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí
    Olúwa sọ nípa Babeli
ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì
    sí Babeli; n ó sì pa
    agbo ẹran wọn run.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé;
    a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì,
a sì gbọ́ igbe náà
    láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

A Message About Babylon(A)

50 This is the word the Lord spoke through Jeremiah the prophet concerning Babylon(B) and the land of the Babylonians[a]:

“Announce and proclaim(C) among the nations,
    lift up a banner(D) and proclaim it;
    keep nothing back, but say,
‘Babylon will be captured;(E)
    Bel(F) will be put to shame,(G)
    Marduk(H) filled with terror.
Her images will be put to shame
    and her idols(I) filled with terror.’
A nation from the north(J) will attack her
    and lay waste her land.
No one will live(K) in it;
    both people and animals(L) will flee away.

“In those days, at that time,”
    declares the Lord,
“the people of Israel and the people of Judah together(M)
    will go in tears(N) to seek(O) the Lord their God.
They will ask the way(P) to Zion
    and turn their faces toward it.
They will come(Q) and bind themselves to the Lord
    in an everlasting covenant(R)
    that will not be forgotten.

“My people have been lost sheep;(S)
    their shepherds(T) have led them astray(U)
    and caused them to roam on the mountains.
They wandered over mountain and hill(V)
    and forgot their own resting place.(W)
Whoever found them devoured(X) them;
    their enemies said, ‘We are not guilty,(Y)
for they sinned against the Lord, their verdant pasture,
    the Lord, the hope(Z) of their ancestors.’

“Flee(AA) out of Babylon;(AB)
    leave the land of the Babylonians,
    and be like the goats that lead the flock.
For I will stir(AC) up and bring against Babylon
    an alliance of great nations(AD) from the land of the north.(AE)
They will take up their positions against her,
    and from the north she will be captured.(AF)
Their arrows(AG) will be like skilled warriors
    who do not return empty-handed.
10 So Babylonia[b] will be plundered;(AH)
    all who plunder her will have their fill,”
declares the Lord.

11 “Because you rejoice and are glad,
    you who pillage my inheritance,(AI)
because you frolic like a heifer(AJ) threshing grain
    and neigh like stallions,
12 your mother will be greatly ashamed;
    she who gave you birth will be disgraced.(AK)
She will be the least of the nations—
    a wilderness, a dry land, a desert.(AL)
13 Because of the Lord’s anger she will not be inhabited
    but will be completely desolate.(AM)
All who pass Babylon will be appalled;(AN)
    they will scoff(AO) because of all her wounds.(AP)

14 “Take up your positions around Babylon,
    all you who draw the bow.(AQ)
Shoot at her! Spare no arrows,(AR)
    for she has sinned against the Lord.
15 Shout(AS) against her on every side!
    She surrenders, her towers fall,
    her walls(AT) are torn down.
Since this is the vengeance(AU) of the Lord,
    take vengeance on her;
    do to her(AV) as she has done to others.(AW)
16 Cut off from Babylon the sower,
    and the reaper with his sickle at harvest.
Because of the sword(AX) of the oppressor
    let everyone return to their own people,(AY)
    let everyone flee to their own land.(AZ)

17 “Israel is a scattered flock(BA)
    that lions(BB) have chased away.
The first to devour(BC) them
    was the king(BD) of Assyria;
the last to crush their bones(BE)
    was Nebuchadnezzar(BF) king(BG) of Babylon.”

18 Therefore this is what the Lord Almighty, the God of Israel, says:

“I will punish the king of Babylon and his land
    as I punished the king(BH) of Assyria.(BI)
19 But I will bring(BJ) Israel back to their own pasture,
    and they will graze on Carmel and Bashan;
their appetite will be satisfied(BK)
    on the hills(BL) of Ephraim and Gilead.(BM)
20 In those days, at that time,”
    declares the Lord,
“search will be made for Israel’s guilt,
    but there will be none,(BN)
and for the sins(BO) of Judah,
    but none will be found,
    for I will forgive(BP) the remnant(BQ) I spare.

21 “Attack the land of Merathaim
    and those who live in Pekod.(BR)
Pursue, kill and completely destroy[c] them,”
declares the Lord.
    “Do everything I have commanded you.
22 The noise(BS) of battle is in the land,
    the noise of great destruction!
23 How broken and shattered
    is the hammer(BT) of the whole earth!(BU)
How desolate(BV) is Babylon
    among the nations!
24 I set a trap(BW) for you, Babylon,
    and you were caught before you knew it;
you were found and captured(BX)
    because you opposed(BY) the Lord.
25 The Lord has opened his arsenal
    and brought out the weapons(BZ) of his wrath,
for the Sovereign Lord Almighty has work to do
    in the land of the Babylonians.(CA)
26 Come against her from afar.(CB)
    Break open her granaries;
    pile her up like heaps of grain.(CC)
Completely destroy(CD) her
    and leave her no remnant.
27 Kill all her young bulls;(CE)
    let them go down to the slaughter!(CF)
Woe to them! For their day(CG) has come,
    the time(CH) for them to be punished.
28 Listen to the fugitives(CI) and refugees from Babylon
    declaring in Zion(CJ)
how the Lord our God has taken vengeance,(CK)
    vengeance for his temple.(CL)

29 “Summon archers against Babylon,
    all those who draw the bow.(CM)
Encamp all around her;
    let no one escape.(CN)
Repay(CO) her for her deeds;(CP)
    do to her as she has done.
For she has defied(CQ) the Lord,
    the Holy One(CR) of Israel.
30 Therefore, her young men(CS) will fall in the streets;
    all her soldiers will be silenced in that day,”
declares the Lord.
31 “See, I am against(CT) you, you arrogant one,”
    declares the Lord, the Lord Almighty,
“for your day(CU) has come,
    the time for you to be punished.
32 The arrogant(CV) one will stumble and fall(CW)
    and no one will help her up;(CX)
I will kindle a fire(CY) in her towns
    that will consume all who are around her.”

33 This is what the Lord Almighty says:

“The people of Israel are oppressed,(CZ)
    and the people of Judah as well.
All their captors hold them fast,
    refusing to let them go.(DA)
34 Yet their Redeemer(DB) is strong;
    the Lord Almighty(DC) is his name.
He will vigorously defend their cause(DD)
    so that he may bring rest(DE) to their land,
    but unrest to those who live in Babylon.

35 “A sword(DF) against the Babylonians!”(DG)
    declares the Lord
“against those who live in Babylon
    and against her officials and wise(DH) men!
36 A sword against her false prophets!
    They will become fools.
A sword against her warriors!(DI)
    They will be filled with terror.(DJ)
37 A sword against her horses and chariots(DK)
    and all the foreigners in her ranks!
    They will become weaklings.(DL)
A sword against her treasures!(DM)
    They will be plundered.
38 A drought on[d] her waters!(DN)
    They will dry(DO) up.
For it is a land of idols,(DP)
    idols that will go mad with terror.

39 “So desert creatures(DQ) and hyenas will live there,
    and there the owl will dwell.
It will never again be inhabited
    or lived in from generation to generation.(DR)
40 As I overthrew Sodom and Gomorrah(DS)
    along with their neighboring towns,”
declares the Lord,
“so no one will live there;
    no people will dwell in it.(DT)

41 “Look! An army is coming from the north;(DU)
    a great nation and many kings
    are being stirred(DV) up from the ends of the earth.(DW)
42 They are armed with bows(DX) and spears;
    they are cruel(DY) and without mercy.(DZ)
They sound like the roaring sea(EA)
    as they ride on their horses;
they come like men in battle formation
    to attack you, Daughter Babylon.(EB)
43 The king of Babylon has heard reports about them,
    and his hands hang limp.(EC)
Anguish has gripped him,
    pain like that of a woman in labor.(ED)
44 Like a lion coming up from Jordan’s thickets(EE)
    to a rich pastureland,
I will chase Babylon from its land in an instant.
    Who is the chosen(EF) one I will appoint for this?
Who is like me and who can challenge me?(EG)
    And what shepherd can stand against me?”

45 Therefore, hear what the Lord has planned against Babylon,
    what he has purposed(EH) against the land of the Babylonians:(EI)
The young of the flock will be dragged away;
    their pasture will be appalled at their fate.
46 At the sound of Babylon’s capture the earth will tremble;(EJ)
    its cry(EK) will resound among the nations.

Footnotes

  1. Jeremiah 50:1 Or Chaldeans; also in verses 8, 25, 35 and 45
  2. Jeremiah 50:10 Or Chaldea
  3. Jeremiah 50:21 The Hebrew term refers to the irrevocable giving over of things or persons to the Lord, often by totally destroying them; also in verse 26.
  4. Jeremiah 50:38 Or A sword against