Add parallel Print Page Options

Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbèkùn

“Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò!
    Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu,
Ẹ fọn fèrè ní Tekoa!
    Kí ẹ gbé ààmì sókè lórí Beti-Hakeremu!
Nítorí àjálù farahàn láti àríwá,
    àní ìparun tí ó lágbára.
Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run,
    tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n.
    Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká,
    olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”

“Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun!
    Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán!
Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán,
    ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́
    kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”

Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀
    kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká.
Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò,
    nítorí pé ó kún fún ìninilára.
Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀,
    náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde.
Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀;
    nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀
    kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ,
kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro,
    tí kò ní ní olùgbé.”

Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli
    ní tónítóní bí àjàrà;
na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i
    gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”

10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti
    tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni
yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn
    ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́.
Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn,
    wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
11 Èmi kún fún ìbínú
    Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra.

“Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti
    sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra
wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò
    mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó
    tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn,
    oko wọn àti àwọn aya wọn,
nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi
    sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,”
    ni Olúwa wí.
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí
    ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn
ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè,
    àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀
    sì kún fún ẹ̀tàn.
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn
    mi bí ẹni pé kò tó nǹkan.
Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’
    nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà
    ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò
ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú
    Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín
àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn
    lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,”
    ni Olúwa wí.

16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò,
    ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè
ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ,
    ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín.
    Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín,
    mo sì wí pé:
‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’
    ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè
    kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí
    ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
19 Gbọ́, ìwọ ayé!
    Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,
    èso ìrò inú wọn,
nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi,
    wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá,
    tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré?
Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà,
    ọrẹ yín kò sì wù mí.”

21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú
    àwọn ènìyàn wọ̀nyí, àwọn baba
àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n,
    àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”

22 Báyìí ni Olúwa wí:

“Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá,
    a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde
    láti òpin ayé wá.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀,
    Wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú
wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n
    ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ;
wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò
    jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”

24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,
    ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa
    bí obìnrin tí ń rọbí.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá
    tàbí kí o máa rìn ní àwọn
ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà,
    ìpayà sì wà níbi gbogbo.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀,
    kí ẹ sì sùn nínú eérú,
ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún
    gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo
    nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.

27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́
    irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin
tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí,
    kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn.
    Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì.
Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin,
    wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan,
    kí ó lè yọ́ òjé,
ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán;
    a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀,
    nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”

Jerusalem Under Siege

“Flee for safety, people of Benjamin!
    Flee from Jerusalem!
Sound the trumpet(A) in Tekoa!(B)
    Raise the signal over Beth Hakkerem!(C)
For disaster looms out of the north,(D)
    even terrible destruction.
I will destroy Daughter Zion,(E)
    so beautiful and delicate.(F)
Shepherds(G) with their flocks will come against her;
    they will pitch their tents around(H) her,
    each tending his own portion.”

“Prepare for battle against her!
    Arise, let us attack at noon!(I)
But, alas, the daylight is fading,
    and the shadows of evening grow long.
So arise, let us attack at night
    and destroy her fortresses!”

This is what the Lord Almighty says:

“Cut down the trees(J)
    and build siege ramps(K) against Jerusalem.
This city must be punished;
    it is filled with oppression.(L)
As a well pours out its water,
    so she pours out her wickedness.
Violence(M) and destruction(N) resound in her;
    her sickness and wounds are ever before me.
Take warning, Jerusalem,
    or I will turn away(O) from you
and make your land desolate
    so no one can live in it.”

This is what the Lord Almighty says:

“Let them glean the remnant(P) of Israel
    as thoroughly as a vine;
pass your hand over the branches again,
    like one gathering grapes.”

10 To whom can I speak and give warning?
    Who will listen(Q) to me?
Their ears are closed[a](R)
    so they cannot hear.(S)
The word(T) of the Lord is offensive to them;
    they find no pleasure in it.
11 But I am full of the wrath(U) of the Lord,
    and I cannot hold it in.(V)

“Pour it out on the children in the street
    and on the young men(W) gathered together;
both husband and wife will be caught in it,
    and the old, those weighed down with years.(X)
12 Their houses will be turned over to others,(Y)
    together with their fields and their wives,(Z)
when I stretch out my hand(AA)
    against those who live in the land,”
declares the Lord.
13 “From the least to the greatest,
    all(AB) are greedy for gain;(AC)
prophets and priests alike,
    all practice deceit.(AD)
14 They dress the wound of my people
    as though it were not serious.
‘Peace, peace,’ they say,
    when there is no peace.(AE)
15 Are they ashamed of their detestable conduct?
    No, they have no shame at all;
    they do not even know how to blush.(AF)
So they will fall among the fallen;
    they will be brought down when I punish(AG) them,”
says the Lord.

16 This is what the Lord says:

“Stand at the crossroads and look;
    ask for the ancient paths,(AH)
ask where the good way(AI) is, and walk in it,
    and you will find rest(AJ) for your souls.
    But you said, ‘We will not walk in it.’
17 I appointed watchmen(AK) over you and said,
    ‘Listen to the sound of the trumpet!’(AL)
    But you said, ‘We will not listen.’(AM)
18 Therefore hear, you nations;
    you who are witnesses,
    observe what will happen to them.
19 Hear, you earth:(AN)
    I am bringing disaster(AO) on this people,
    the fruit of their schemes,(AP)
because they have not listened to my words(AQ)
    and have rejected my law.(AR)
20 What do I care about incense from Sheba(AS)
    or sweet calamus(AT) from a distant land?
Your burnt offerings are not acceptable;(AU)
    your sacrifices(AV) do not please me.”(AW)

21 Therefore this is what the Lord says:

“I will put obstacles before this people.
    Parents and children alike will stumble(AX) over them;
    neighbors and friends will perish.”

22 This is what the Lord says:

“Look, an army is coming
    from the land of the north;(AY)
a great nation is being stirred up
    from the ends of the earth.(AZ)
23 They are armed with bow and spear;
    they are cruel and show no mercy.(BA)
They sound like the roaring sea(BB)
    as they ride on their horses;(BC)
they come like men in battle formation
    to attack you, Daughter Zion.(BD)

24 We have heard reports about them,
    and our hands hang limp.(BE)
Anguish(BF) has gripped us,
    pain like that of a woman in labor.(BG)
25 Do not go out to the fields
    or walk on the roads,
for the enemy has a sword,
    and there is terror on every side.(BH)
26 Put on sackcloth,(BI) my people,
    and roll in ashes;(BJ)
mourn with bitter wailing(BK)
    as for an only son,(BL)
for suddenly the destroyer(BM)
    will come upon us.

27 “I have made you a tester(BN) of metals
    and my people the ore,
that you may observe
    and test their ways.
28 They are all hardened rebels,(BO)
    going about to slander.(BP)
They are bronze and iron;(BQ)
    they all act corruptly.
29 The bellows blow fiercely
    to burn away the lead with fire,
but the refining(BR) goes on in vain;
    the wicked are not purged out.
30 They are called rejected silver,(BS)
    because the Lord has rejected them.”(BT)

Footnotes

  1. Jeremiah 6:10 Hebrew uncircumcised