Add parallel Print Page Options

Ẹ̀sìn àìṣòótọ́ kò níláárí

Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa. “Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí:

“ ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa. Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí. Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!” Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́. Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín. Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé. Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.

“ ‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ? 10 Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí? 11 (A)Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.

12 “ ‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi. 13 Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn 14 Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín. 15 Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’

16 “Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ. 17 Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu? 18 Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè. 19 Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?

20 “ ‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.

21 “ ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnrayín. 22 Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán. 23 Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé: Gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín. 24 Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn. 25 Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín. 26 Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’

27 “Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn. 28 Nítorí náà, sọ fún wọn pé ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.

29 “ ‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.

Àfonífojì ìparun

30 “ ‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́. 31 Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní Àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi. 32 Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí Àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ Àfonífojì Ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́ 33 Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n. 34 (B)Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.

False Religion Worthless

This is the word that came to Jeremiah from the Lord: “Stand(A) at the gate of the Lord’s house and there proclaim this message:

“‘Hear the word of the Lord, all you people of Judah who come through these gates to worship the Lord. This is what the Lord Almighty, the God of Israel, says: Reform your ways(B) and your actions, and I will let you live(C) in this place. Do not trust(D) in deceptive(E) words and say, “This is the temple of the Lord, the temple of the Lord, the temple of the Lord!” If you really change(F) your ways and your actions and deal with each other justly,(G) if you do not oppress(H) the foreigner, the fatherless or the widow and do not shed innocent blood(I) in this place, and if you do not follow other gods(J) to your own harm, then I will let you live in this place, in the land(K) I gave your ancestors(L) for ever and ever. But look, you are trusting(M) in deceptive(N) words that are worthless.

“‘Will you steal(O) and murder,(P) commit adultery(Q) and perjury,[a](R) burn incense to Baal(S) and follow other gods(T) you have not known, 10 and then come and stand(U) before me in this house,(V) which bears my Name, and say, “We are safe”—safe to do all these detestable things?(W) 11 Has this house,(X) which bears my Name, become a den of robbers(Y) to you? But I have been watching!(Z) declares the Lord.

12 “‘Go now to the place in Shiloh(AA) where I first made a dwelling(AB) for my Name,(AC) and see what I did(AD) to it because of the wickedness of my people Israel. 13 While you were doing all these things, declares the Lord, I spoke(AE) to you again and again,(AF) but you did not listen;(AG) I called(AH) you, but you did not answer.(AI) 14 Therefore, what I did to Shiloh(AJ) I will now do to the house that bears my Name,(AK) the temple(AL) you trust in, the place I gave to you and your ancestors. 15 I will thrust you from my presence,(AM) just as I did all your fellow Israelites, the people of Ephraim.’(AN)

16 “So do not pray for this people nor offer any plea(AO) or petition for them; do not plead with me, for I will not listen(AP) to you. 17 Do you not see what they are doing in the towns of Judah and in the streets of Jerusalem? 18 The children gather wood, the fathers light the fire, and the women knead the dough and make cakes to offer to the Queen of Heaven.(AQ) They pour out drink offerings(AR) to other gods to arouse(AS) my anger. 19 But am I the one they are provoking?(AT) declares the Lord. Are they not rather harming themselves, to their own shame?(AU)

20 “‘Therefore this is what the Sovereign(AV) Lord says: My anger(AW) and my wrath will be poured(AX) out on this place—on man and beast, on the trees of the field and on the crops of your land—and it will burn and not be quenched.(AY)

21 “‘This is what the Lord Almighty, the God of Israel, says: Go ahead, add your burnt offerings to your other sacrifices(AZ) and eat(BA) the meat yourselves! 22 For when I brought your ancestors out of Egypt and spoke to them, I did not just give them commands(BB) about burnt offerings and sacrifices,(BC) 23 but I gave them this command:(BD) Obey(BE) me, and I will be your God and you will be my people.(BF) Walk in obedience to all(BG) I command you, that it may go well(BH) with you. 24 But they did not listen(BI) or pay attention;(BJ) instead, they followed the stubborn inclinations of their evil hearts.(BK) They went backward(BL) and not forward. 25 From the time your ancestors left Egypt until now, day after day, again and again(BM) I sent you my servants(BN) the prophets.(BO) 26 But they did not listen to me or pay attention.(BP) They were stiff-necked(BQ) and did more evil than their ancestors.’(BR)

27 “When you tell(BS) them all this, they will not listen(BT) to you; when you call to them, they will not answer.(BU) 28 Therefore say to them, ‘This is the nation that has not obeyed the Lord its God or responded to correction.(BV) Truth(BW) has perished; it has vanished from their lips.

29 “‘Cut off(BX) your hair and throw it away; take up a lament(BY) on the barren heights, for the Lord has rejected and abandoned(BZ) this generation that is under his wrath.

The Valley of Slaughter

30 “‘The people of Judah have done evil(CA) in my eyes, declares the Lord. They have set up their detestable idols(CB) in the house that bears my Name and have defiled(CC) it. 31 They have built the high places of Topheth(CD) in the Valley of Ben Hinnom(CE) to burn their sons and daughters(CF) in the fire—something I did not command, nor did it enter my mind.(CG) 32 So beware, the days are coming, declares the Lord, when people will no longer call it Topheth or the Valley of Ben Hinnom, but the Valley of Slaughter,(CH) for they will bury(CI) the dead in Topheth until there is no more room. 33 Then the carcasses(CJ) of this people will become food(CK) for the birds and the wild animals, and there will be no one to frighten them away.(CL) 34 I will bring an end to the sounds(CM) of joy and gladness and to the voices of bride and bridegroom(CN) in the towns of Judah and the streets of Jerusalem,(CO) for the land will become desolate.(CP)

Footnotes

  1. Jeremiah 7:9 Or and swear by false gods