Add parallel Print Page Options

Májẹ̀mú di ọ̀tun ní Ṣekemu

24 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.

Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí: ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà. Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki, àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.

“ ‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde. Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa. Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú Òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.

“ ‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn. Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú. 10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.

11 “ ‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́. 12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín. 13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’

14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa. 15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”

16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà! 17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnrarẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá. 18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”

19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, Kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín. 20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”

21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”

22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.”

Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”

23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”

24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”

25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu. 26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.

27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”

28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.

Ikú Joṣua àti Eleasari

29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún (110) 30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá Òkè Gaaṣi.

31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.

32 (A)Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́ọ̀rún (100) fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.

33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.

The Covenant Renewed at Shechem

24 Then Joshua assembled(A) all the tribes of Israel at Shechem.(B) He summoned(C) the elders,(D) leaders, judges and officials of Israel,(E) and they presented themselves before God.

Joshua said to all the people, “This is what the Lord, the God of Israel, says: ‘Long ago your ancestors, including Terah the father of Abraham and Nahor,(F) lived beyond the Euphrates River and worshiped other gods.(G) But I took your father Abraham from the land beyond the Euphrates and led him throughout Canaan(H) and gave him many descendants.(I) I gave him Isaac,(J) and to Isaac I gave Jacob and Esau.(K) I assigned the hill country of Seir(L) to Esau, but Jacob and his family went down to Egypt.(M)

“‘Then I sent Moses and Aaron,(N) and I afflicted the Egyptians by what I did there, and I brought you out.(O) When I brought your people out of Egypt, you came to the sea,(P) and the Egyptians pursued them with chariots and horsemen[a](Q) as far as the Red Sea.[b](R) But they cried(S) to the Lord for help, and he put darkness(T) between you and the Egyptians; he brought the sea over them and covered them.(U) You saw with your own eyes what I did to the Egyptians.(V) Then you lived in the wilderness for a long time.(W)

“‘I brought you to the land of the Amorites(X) who lived east of the Jordan. They fought against you, but I gave them into your hands. I destroyed them from before you, and you took possession of their land.(Y) When Balak son of Zippor,(Z) the king of Moab, prepared to fight against Israel, he sent for Balaam son of Beor(AA) to put a curse on you.(AB) 10 But I would not listen to Balaam, so he blessed you(AC) again and again, and I delivered you out of his hand.

11 “‘Then you crossed the Jordan(AD) and came to Jericho.(AE) The citizens of Jericho fought against you, as did also the Amorites, Perizzites,(AF) Canaanites, Hittites, Girgashites, Hivites and Jebusites,(AG) but I gave them into your hands.(AH) 12 I sent the hornet(AI) ahead of you, which drove them out(AJ) before you—also the two Amorite kings. You did not do it with your own sword and bow.(AK) 13 So I gave you a land(AL) on which you did not toil and cities you did not build; and you live in them and eat from vineyards and olive groves that you did not plant.’(AM)

14 “Now fear the Lord(AN) and serve him with all faithfulness.(AO) Throw away the gods(AP) your ancestors worshiped beyond the Euphrates River and in Egypt,(AQ) and serve the Lord. 15 But if serving the Lord seems undesirable to you, then choose for yourselves this day whom you will serve, whether the gods your ancestors served beyond the Euphrates, or the gods of the Amorites,(AR) in whose land you are living. But as for me and my household,(AS) we will serve the Lord.”(AT)

16 Then the people answered, “Far be it from us to forsake(AU) the Lord to serve other gods! 17 It was the Lord our God himself who brought us and our parents up out of Egypt, from that land of slavery,(AV) and performed those great signs(AW) before our eyes. He protected us on our entire journey and among all the nations through which we traveled. 18 And the Lord drove out(AX) before us all the nations,(AY) including the Amorites, who lived in the land.(AZ) We too will serve the Lord, because he is our God.(BA)

19 Joshua said to the people, “You are not able to serve the Lord. He is a holy God;(BB) he is a jealous God.(BC) He will not forgive(BD) your rebellion(BE) and your sins. 20 If you forsake the Lord(BF) and serve foreign gods, he will turn(BG) and bring disaster(BH) on you and make an end of you,(BI) after he has been good to you.”

21 But the people said to Joshua, “No! We will serve the Lord.”

22 Then Joshua said, “You are witnesses(BJ) against yourselves that you have chosen(BK) to serve the Lord.”

“Yes, we are witnesses,(BL)” they replied.

23 “Now then,” said Joshua, “throw away the foreign gods(BM) that are among you and yield your hearts(BN) to the Lord, the God of Israel.”

24 And the people said to Joshua, “We will serve the Lord our God and obey him.”(BO)

25 On that day Joshua made a covenant(BP) for the people, and there at Shechem(BQ) he reaffirmed for them decrees and laws.(BR) 26 And Joshua recorded(BS) these things in the Book of the Law of God.(BT) Then he took a large stone(BU) and set it up there under the oak(BV) near the holy place of the Lord.

27 “See!” he said to all the people. “This stone(BW) will be a witness(BX) against us. It has heard all the words the Lord has said to us. It will be a witness against you if you are untrue(BY) to your God.”(BZ)

28 Then Joshua dismissed the people, each to their own inheritance.(CA)

Buried in the Promised Land(CB)

29 After these things, Joshua son of Nun, the servant of the Lord, died(CC) at the age of a hundred and ten.(CD) 30 And they buried him in the land of his inheritance, at Timnath Serah[c](CE) in the hill country of Ephraim, north of Mount Gaash.(CF)

31 Israel served the Lord throughout the lifetime of Joshua and of the elders(CG) who outlived him and who had experienced everything the Lord had done for Israel.

32 And Joseph’s bones,(CH) which the Israelites had brought up from Egypt,(CI) were buried at Shechem in the tract of land(CJ) that Jacob bought for a hundred pieces of silver[d] from the sons of Hamor, the father of Shechem. This became the inheritance of Joseph’s descendants.

33 And Eleazar son of Aaron(CK) died and was buried at Gibeah,(CL) which had been allotted to his son Phinehas(CM) in the hill country(CN) of Ephraim.

Footnotes

  1. Joshua 24:6 Or charioteers
  2. Joshua 24:6 Or the Sea of Reeds
  3. Joshua 24:30 Also known as Timnath Heres (see Judges 2:9)
  4. Joshua 24:32 Hebrew hundred kesitahs; a kesitah was a unit of money of unknown weight and value.