Add parallel Print Page Options

Àwọn jagunjagun eṣú

Ẹ fun ìpè ní Sioni,
    ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi.

Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì,
    nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá,
nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
    Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀,
    ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri,
Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá:
    àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé,
ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí,
    bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.

Iná ń jó níwájú wọ́n;
    ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn:
Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn,
    àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù;
    nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
(A)Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin;
    wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun
Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni
    wọn ń fo ní orí òkè
bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ,
    bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.

Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀:
    gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára;
    wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun;
olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀,
    wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀;
    olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀:
nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà
    wọn kì yóò gbọgbẹ́.
Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú;
    wọn yóò súré lórí odi,
wọn yóò gùn orí ilé;
    wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.

10 (B)Ayé yóò mì níwájú wọn;
    àwọn ọ̀run yóò wárìrì;
oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,
    àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
11 (C)Olúwa yóò sì bú ramúramù
    jáde níwájú ogun rẹ̀:
nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;
    nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ;
nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;
    ara ta ni ó lè gbà á?

Fa ọkàn rẹ ya

12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí,
    “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi,
    àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”

13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya,
    kì í sì í ṣe aṣọ yín,
ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín,
    nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́,
ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú,
    ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà,
    kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀—
àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu
    fún Olúwa Ọlọ́run yín?

15 Ẹ fún ìpè ní Sioni,
    ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́,
    ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ,
    ẹ ya ìjọ sí mímọ́;
ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ,
    ẹ kó àwọn ọmọdé jọ,
    àti àwọn tí ń mú ọmú:
jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀.
    Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa,
    sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ.
Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa.
    Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn,
    tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí.
Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé,
    ‘Ọlọ́run wọn ha da?’ ”
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀,
    yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.

19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn:

“Yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé,
    Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun,
àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn:
    èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.

20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín,
    èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro,
pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn,
    àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun.
Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè,
    òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.”

Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
21     Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀;
    jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀,
nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá,
22     Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó,
    nítorí pápá oko aginjù ń rú,
nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́
    àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni,
    ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín,
nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́,
    Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín,
àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà;
    àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde
    pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.

25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín.
    Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé
    ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ
àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó
    ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín,
ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò;
    ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli,
    àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,
    àti pé kò sí ẹlòmíràn:
Ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.

Ọjọ́ Olúwa

28 (D)“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́,
    èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo;
àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀,
    àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá,
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,
    àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,
    ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun
    àti ní ayé,
    ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
31 (E)A á sọ oòrùn di òkùnkùn,
    àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,
    kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
32 (F)Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè
    orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà:
nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu
    ní ìgbàlà yóò gbé wà,
    Olúwa ti wí,
àti nínú àwọn
    ìyókù tí Olúwa yóò pè.

An Army of Locusts

Blow the trumpet(A) in Zion;(B)
    sound the alarm on my holy hill.(C)

Let all who live in the land tremble,
    for the day of the Lord(D) is coming.
It is close at hand(E)
    a day of darkness(F) and gloom,(G)
    a day of clouds(H) and blackness.(I)
Like dawn spreading across the mountains
    a large and mighty army(J) comes,
such as never was in ancient times(K)
    nor ever will be in ages to come.

Before them fire(L) devours,
    behind them a flame blazes.
Before them the land is like the garden of Eden,(M)
    behind them, a desert waste(N)
    nothing escapes them.
They have the appearance of horses;(O)
    they gallop along like cavalry.
With a noise like that of chariots(P)
    they leap over the mountaintops,
like a crackling fire(Q) consuming stubble,
    like a mighty army drawn up for battle.

At the sight of them, nations are in anguish;(R)
    every face turns pale.(S)
They charge like warriors;(T)
    they scale walls like soldiers.
They all march in line,(U)
    not swerving(V) from their course.
They do not jostle each other;
    each marches straight ahead.
They plunge through defenses
    without breaking ranks.
They rush upon the city;
    they run along the wall.
They climb into the houses;(W)
    like thieves they enter through the windows.(X)

10 Before them the earth shakes,(Y)
    the heavens tremble,(Z)
the sun and moon are darkened,(AA)
    and the stars no longer shine.(AB)
11 The Lord(AC) thunders(AD)
    at the head of his army;(AE)
his forces are beyond number,
    and mighty is the army that obeys his command.
The day of the Lord is great;(AF)
    it is dreadful.
    Who can endure it?(AG)

Rend Your Heart

12 “Even now,” declares the Lord,
    “return(AH) to me with all your heart,(AI)
    with fasting and weeping and mourning.”

13 Rend your heart(AJ)
    and not your garments.(AK)
Return(AL) to the Lord your God,
    for he is gracious and compassionate,(AM)
slow to anger and abounding in love,(AN)
    and he relents from sending calamity.(AO)
14 Who knows? He may turn(AP) and relent(AQ)
    and leave behind a blessing(AR)
grain offerings and drink offerings(AS)
    for the Lord your God.

15 Blow the trumpet(AT) in Zion,(AU)
    declare a holy fast,(AV)
    call a sacred assembly.(AW)
16 Gather the people,
    consecrate(AX) the assembly;
bring together the elders,(AY)
    gather the children,
    those nursing at the breast.
Let the bridegroom(AZ) leave his room
    and the bride her chamber.
17 Let the priests, who minister(BA) before the Lord,
    weep(BB) between the portico and the altar.(BC)
Let them say, “Spare your people, Lord.
    Do not make your inheritance an object of scorn,(BD)
    a byword(BE) among the nations.
Why should they say among the peoples,
    ‘Where is their God?(BF)’”

The Lord’s Answer

18 Then the Lord was jealous(BG) for his land
    and took pity(BH) on his people.

19 The Lord replied[a] to them:

“I am sending you grain, new wine(BI) and olive oil,(BJ)
    enough to satisfy you fully;(BK)
never again will I make you
    an object of scorn(BL) to the nations.

20 “I will drive the northern horde(BM) far from you,
    pushing it into a parched and barren land;
its eastern ranks will drown in the Dead Sea
    and its western ranks in the Mediterranean Sea.
And its stench(BN) will go up;
    its smell will rise.”

Surely he has done great things!
21     Do not be afraid,(BO) land of Judah;
    be glad and rejoice.(BP)
Surely the Lord has done great things!(BQ)
22     Do not be afraid, you wild animals,
    for the pastures in the wilderness are becoming green.(BR)
The trees are bearing their fruit;
    the fig tree(BS) and the vine(BT) yield their riches.(BU)
23 Be glad, people of Zion,
    rejoice(BV) in the Lord your God,
for he has given you the autumn rains
    because he is faithful.(BW)
He sends you abundant showers,(BX)
    both autumn(BY) and spring rains,(BZ) as before.
24 The threshing floors will be filled with grain;
    the vats will overflow(CA) with new wine(CB) and oil.

25 “I will repay you for the years the locusts(CC) have eaten(CD)
    the great locust and the young locust,
    the other locusts and the locust swarm[b]
my great army(CE) that I sent among you.
26 You will have plenty to eat, until you are full,(CF)
    and you will praise(CG) the name of the Lord your God,
    who has worked wonders(CH) for you;
never again will my people be shamed.(CI)
27 Then you will know(CJ) that I am in Israel,
    that I am the Lord(CK) your God,
    and that there is no other;
never again will my people be shamed.(CL)

The Day of the Lord

28 “And afterward,
    I will pour out my Spirit(CM) on all people.(CN)
Your sons and daughters will prophesy,(CO)
    your old men will dream dreams,(CP)
    your young men will see visions.
29 Even on my servants,(CQ) both men and women,
    I will pour out my Spirit in those days.(CR)
30 I will show wonders in the heavens(CS)
    and on the earth,(CT)
    blood and fire and billows of smoke.
31 The sun will be turned to darkness(CU)
    and the moon to blood
    before the coming of the great and dreadful day of the Lord.(CV)
32 And everyone who calls
    on the name of the Lord(CW) will be saved;(CX)
for on Mount Zion(CY) and in Jerusalem
    there will be deliverance,(CZ)
    as the Lord has said,
even among the survivors(DA)
    whom the Lord calls.[c](DB)

Footnotes

  1. Joel 2:19 Or Lord will be jealous … / and take pity … / 19 The Lord will reply
  2. Joel 2:25 The precise meaning of the four Hebrew words used here for locusts is uncertain.
  3. Joel 2:32 In Hebrew texts 2:28-32 is numbered 3:1-5.