Add parallel Print Page Options

Elifasi tako ọrọ̀ Jobu

15 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé:

“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán, kí
    ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní
    èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì,
    ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀
    rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;
    àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.

“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí?
    Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí, tàbí
    ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀?
    Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa,
    tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?
    Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri,
    kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run,
    tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?

14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́,
    àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,
    àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí,
    tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.

17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi;
    Èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti
    ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,
    ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá,
    pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo,
    àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;
    nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn;
    a sì ṣà á sápá kan fún idà.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà?
    Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un
    bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì
    sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
26 Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga,
    àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.

27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀
    lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú,
    àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé
    mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò
    lè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn;
    ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀,
    àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ.
    Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀,
    ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù,
    yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè
    yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀,
    ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”

Eliphaz

15 Then Eliphaz the Temanite(A) replied:

“Would a wise person answer with empty notions
    or fill their belly with the hot east wind?(B)
Would they argue with useless words,
    with speeches that have no value?(C)
But you even undermine piety
    and hinder devotion to God.(D)
Your sin(E) prompts your mouth;(F)
    you adopt the tongue of the crafty.(G)
Your own mouth condemns you, not mine;
    your own lips testify against you.(H)

“Are you the first man ever born?(I)
    Were you brought forth before the hills?(J)
Do you listen in on God’s council?(K)
    Do you have a monopoly on wisdom?(L)
What do you know that we do not know?
    What insights do you have that we do not have?(M)
10 The gray-haired and the aged(N) are on our side,
    men even older than your father.(O)
11 Are God’s consolations(P) not enough for you,
    words(Q) spoken gently to you?(R)
12 Why has your heart(S) carried you away,
    and why do your eyes flash,
13 so that you vent your rage(T) against God
    and pour out such words(U) from your mouth?(V)

14 “What are mortals, that they could be pure,
    or those born of woman,(W) that they could be righteous?(X)
15 If God places no trust in his holy ones,(Y)
    if even the heavens are not pure in his eyes,(Z)
16 how much less mortals, who are vile and corrupt,(AA)
    who drink up evil(AB) like water!(AC)

17 “Listen to me and I will explain to you;
    let me tell you what I have seen,(AD)
18 what the wise have declared,
    hiding nothing received from their ancestors(AE)
19 (to whom alone the land(AF) was given
    when no foreigners moved among them):
20 All his days the wicked man suffers torment,(AG)
    the ruthless man through all the years stored up for him.(AH)
21 Terrifying sounds fill his ears;(AI)
    when all seems well, marauders attack him.(AJ)
22 He despairs of escaping the realm of darkness;(AK)
    he is marked for the sword.(AL)
23 He wanders about(AM) for food like a vulture;(AN)
    he knows the day of darkness(AO) is at hand.(AP)
24 Distress and anguish(AQ) fill him with terror;(AR)
    troubles overwhelm him, like a king(AS) poised to attack,
25 because he shakes his fist(AT) at God
    and vaunts himself against the Almighty,(AU)
26 defiantly charging against him
    with a thick, strong shield.(AV)

27 “Though his face is covered with fat
    and his waist bulges with flesh,(AW)
28 he will inhabit ruined towns
    and houses where no one lives,(AX)
    houses crumbling to rubble.(AY)
29 He will no longer be rich and his wealth will not endure,(AZ)
    nor will his possessions spread over the land.(BA)
30 He will not escape the darkness;(BB)
    a flame(BC) will wither his shoots,(BD)
    and the breath of God’s mouth(BE) will carry him away.(BF)
31 Let him not deceive(BG) himself by trusting what is worthless,(BH)
    for he will get nothing in return.(BI)
32 Before his time(BJ) he will wither,(BK)
    and his branches will not flourish.(BL)
33 He will be like a vine stripped of its unripe grapes,(BM)
    like an olive tree shedding its blossoms.(BN)
34 For the company of the godless(BO) will be barren,
    and fire will consume(BP) the tents of those who love bribes.(BQ)
35 They conceive trouble(BR) and give birth to evil;(BS)
    their womb fashions deceit.”