Add parallel Print Page Options

Ìdáhùn Jobu fún Bilidadi

19 Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:

“Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí,
    tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?
Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí;
    ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.
Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́,
    ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́,
    tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,
Kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú,
    ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.

“Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi;
    mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.
Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá,
    Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.
Ó ti bọ́ ògo mi,
    ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.
10 Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo,
    ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.
11 Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi,
    ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.
12 Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi,
    wọ́n sì mọ odi yí mi ká,
    wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.

13 “Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré,
    àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.
14 Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn,
    àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.
15 Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì;
    èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.
16 Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn;
    mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.
17 Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi
    ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.
18 Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín:
    Mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.
19 Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi,
    àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.
20 Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi,
    mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.

21 “Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi,
    ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.
22 Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí
    Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?

23 “Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi
    nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!
24 Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ
    wọ́n sínú àpáta fún láéláé.
25 Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè
    àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;
26 Àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara
    mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,
27 Ẹni tí èmi ó rí fún ara mi,
    tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn;
    ọkàn mi sì dákú ní inú mi.

28 “Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘àwa ó ti lépa rẹ̀ tó!
    Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’
29 Kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù;
    nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà,
    Kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”

Job

19 Then Job replied:

“How long will you torment(A) me
    and crush(B) me with words?
Ten times(C) now you have reproached(D) me;
    shamelessly you attack me.
If it is true that I have gone astray,
    my error(E) remains my concern alone.
If indeed you would exalt yourselves above me(F)
    and use my humiliation against me,
then know that God has wronged me(G)
    and drawn his net(H) around me.(I)

“Though I cry, ‘Violence!’ I get no response;(J)
    though I call for help,(K) there is no justice.(L)
He has blocked my way so I cannot pass;(M)
    he has shrouded my paths in darkness.(N)
He has stripped(O) me of my honor(P)
    and removed the crown from my head.(Q)
10 He tears me down(R) on every side till I am gone;
    he uproots my hope(S) like a tree.(T)
11 His anger(U) burns against me;
    he counts me among his enemies.(V)
12 His troops advance in force;(W)
    they build a siege ramp(X) against me
    and encamp around my tent.(Y)

13 “He has alienated my family(Z) from me;
    my acquaintances are completely estranged from me.(AA)
14 My relatives have gone away;
    my closest friends(AB) have forgotten me.
15 My guests(AC) and my female servants(AD) count me a foreigner;
    they look on me as on a stranger.
16 I summon my servant, but he does not answer,
    though I beg him with my own mouth.
17 My breath is offensive to my wife;
    I am loathsome(AE) to my own family.
18 Even the little boys(AF) scorn me;
    when I appear, they ridicule me.(AG)
19 All my intimate friends(AH) detest me;(AI)
    those I love have turned against me.(AJ)
20 I am nothing but skin and bones;(AK)
    I have escaped only by the skin of my teeth.[a]

21 “Have pity on me, my friends,(AL) have pity,
    for the hand of God has struck(AM) me.
22 Why do you pursue(AN) me as God does?(AO)
    Will you never get enough of my flesh?(AP)

23 “Oh, that my words were recorded,
    that they were written on a scroll,(AQ)
24 that they were inscribed with an iron tool(AR) on[b] lead,
    or engraved in rock forever!(AS)
25 I know that my redeemer[c](AT) lives,(AU)
    and that in the end he will stand on the earth.[d]
26 And after my skin has been destroyed,
    yet[e] in[f] my flesh I will see God;(AV)
27 I myself will see him
    with my own eyes(AW)—I, and not another.
    How my heart yearns(AX) within me!

28 “If you say, ‘How we will hound(AY) him,
    since the root of the trouble lies in him,[g]
29 you should fear the sword yourselves;
    for wrath will bring punishment by the sword,(AZ)
    and then you will know that there is judgment.[h](BA)

Footnotes

  1. Job 19:20 Or only by my gums
  2. Job 19:24 Or and
  3. Job 19:25 Or vindicator
  4. Job 19:25 Or on my grave
  5. Job 19:26 Or And after I awake, / though this body has been destroyed, / then
  6. Job 19:26 Or destroyed, / apart from
  7. Job 19:28 Many Hebrew manuscripts, Septuagint and Vulgate; most Hebrew manuscripts me
  8. Job 19:29 Or sword, / that you may come to know the Almighty