Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu

28 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,
    àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,
    bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,
    ó sì ṣe àwárí ìṣúra
    láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,
    àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,
    wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,
    àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná
Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Safire,
    o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,
    àti ojú gúnnugún kò rí i rí;
Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,
    bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,
    ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,
    ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,
    ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.

12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,
    níbo sì ni òye ń gbe?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”;
    omi Òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 A kò le è fi wúrà rà á,
    bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òṣùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 A kò le è fi wúrà ofiri,
    tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta Safire díye lé e.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
    bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;
    iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
    bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.

20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?
    Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,
    ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé,
    àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,
    òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,
    ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,
    ó sì fi òṣùwọ̀n wọ́n omi.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,
    tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;
    ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,
    “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,
    àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”

Interlude: Where Wisdom Is Found

28 There is a mine for silver
    and a place where gold is refined.(A)
Iron is taken from the earth,
    and copper is smelted from ore.(B)
Mortals put an end to the darkness;(C)
    they search out the farthest recesses
    for ore in the blackest darkness.(D)
Far from human dwellings they cut a shaft,(E)
    in places untouched by human feet;
    far from other people they dangle and sway.
The earth, from which food comes,(F)
    is transformed below as by fire;
lapis lazuli(G) comes from its rocks,
    and its dust contains nuggets of gold.(H)
No bird of prey knows that hidden path,
    no falcon’s eye has seen it.(I)
Proud beasts(J) do not set foot on it,
    and no lion prowls there.(K)
People assault the flinty rock(L) with their hands
    and lay bare the roots of the mountains.(M)
10 They tunnel through the rock;(N)
    their eyes see all its treasures.(O)
11 They search[a] the sources of the rivers(P)
    and bring hidden things(Q) to light.

12 But where can wisdom be found?(R)
    Where does understanding dwell?(S)
13 No mortal comprehends its worth;(T)
    it cannot be found in the land of the living.(U)
14 The deep(V) says, “It is not in me”;
    the sea(W) says, “It is not with me.”
15 It cannot be bought with the finest gold,
    nor can its price be weighed out in silver.(X)
16 It cannot be bought with the gold of Ophir,(Y)
    with precious onyx or lapis lazuli.(Z)
17 Neither gold nor crystal can compare with it,(AA)
    nor can it be had for jewels of gold.(AB)
18 Coral(AC) and jasper(AD) are not worthy of mention;
    the price of wisdom is beyond rubies.(AE)
19 The topaz(AF) of Cush(AG) cannot compare with it;
    it cannot be bought with pure gold.(AH)

20 Where then does wisdom come from?
    Where does understanding dwell?(AI)
21 It is hidden from the eyes of every living thing,
    concealed even from the birds in the sky.(AJ)
22 Destruction[b](AK) and Death(AL) say,
    “Only a rumor of it has reached our ears.”
23 God understands the way to it
    and he alone(AM) knows where it dwells,(AN)
24 for he views the ends of the earth(AO)
    and sees everything under the heavens.(AP)
25 When he established the force of the wind
    and measured out the waters,(AQ)
26 when he made a decree for the rain(AR)
    and a path for the thunderstorm,(AS)
27 then he looked at wisdom and appraised it;
    he confirmed it and tested it.(AT)
28 And he said to the human race,
    “The fear of the Lord—that is wisdom,
    and to shun evil(AU) is understanding.”(AV)

Footnotes

  1. Job 28:11 Septuagint, Aquila and Vulgate; Hebrew They dam up
  2. Job 28:22 Hebrew Abaddon